Ẹkun Jeremiah 5 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ẹkun Jeremiah 5:1-22

1Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa;

wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.

2Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò,

ilé wa ti di ti àjèjì.

3Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba,

àwọn ìyá wa ti di opó.

4A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu;

igi wa di títà fún wa.

5Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa;

àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.

6Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria

láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.

7Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́,

àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

8Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa,

kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.

9Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa

nítorí idà tí ó wà ní aginjù.

10Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò,

ebi sì yó wa bí àárẹ̀.

11Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni,

àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.

12Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn;

kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.

13Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta;

àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.

14Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú;

àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn

15Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa;

ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.

16Adé ti ṣí kúrò ní orí wa

ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.

17Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa,

nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.

18Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro

lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.

19Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé;

ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.

20Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà?

Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?

21Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà;

mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì

22Àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá

tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.

Nova Versão Internacional

Lamentações 5:1-22

1Lembra-te, Senhor, do que tem acontecido conosco;

olha e vê a nossa desgraça.

2Nossa herança foi entregue aos estranhos,

nossas casas, aos estrangeiros.

3Somos órfãos de pai,

nossas mães são como viúvas.

4Temos que comprar a água que bebemos;

nossa lenha, só conseguimos pagando.

5Aqueles que nos perseguem estão bem próximos;

estamos exaustos e não temos como descansar.

6Submetemo-nos ao Egito e à Assíria

para conseguir pão.

7Nossos pais pecaram e já não existem,

e nós recebemos o castigo pelos seus pecados.

8Escravos dominam sobre nós,

e não há quem possa livrar-nos das suas mãos.

9Conseguimos pão arriscando a vida,

enfrentando a espada do deserto.

10Nossa pele está quente como um forno,

febril de tanta fome.

11As mulheres têm sido violentadas em Sião,

e as virgens, nas cidades de Judá.

12Os líderes foram pendurados por suas mãos;

aos idosos não se mostra nenhum respeito.

13Os jovens trabalham nos moinhos;

os meninos cambaleiam sob o fardo de lenha.

14Os líderes já não se reúnem junto às portas da cidade;

os jovens cessaram a sua música.

15Dos nossos corações fugiu a alegria;

nossas danças se transformaram em lamentos.

16A coroa caiu da nossa cabeça.

Ai de nós, porque temos pecado!

17E por esse motivo o nosso coração desfalece,

e os nossos olhos perdem o brilho.

18Tudo porque o monte Sião está deserto,

e os chacais perambulam por ele.

19Tu, Senhor, reinas para sempre;

teu trono permanece 2 de geração em geração.

20Por que motivo então te esquecerias de nós?

Por que haverias de desamparar-nos por tanto tempo?

21Restaura-nos para ti, Senhor, para que voltemos;

renova os nossos dias como os de antigamente,

22a não ser que já nos tenhas rejeitado completamente

e a tua ira contra nós não tenha limite!