Ẹkun Jeremiah 2 – YCB & CCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ẹkun Jeremiah 2:1-22

1Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni

pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀!

Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀

Láti ọ̀run sí ayé;

kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀

ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.

2Láìní àánú ni Olúwa gbé

ibùgbé Jakọbu mì;

nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó

ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀.

Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin

lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.

3Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké

gbogbo ìwo Israẹli.

Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò

nígbà tí àwọn ọ̀tá dé.

Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná

ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.

4Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá;

ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra

Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun

ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná

sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.

5Olúwa dàbí ọ̀tá;

ó gbé Israẹli mì.

Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì

ó pa ibi gíga rẹ̀ run.

Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀

fún àwọn ọmọbìnrin Juda.

6Ó mú ìparun bá ibi mímọ́,

ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run.

Olúwa ti mú Sioni gbàgbé

àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn;

nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run

ọba àti olórí àlùfáà.

7Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀

ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀.

Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́

àwọn odi ààfin rẹ̀;

wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa

gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.

8Olúwa pinnu láti fa

ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya.

Ó gbé wọn sórí òṣùwọ̀n,

kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn.

Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀

wọ́n ṣòfò papọ̀.

9Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀;

òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́.

Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,

kò sí òfin mọ́,

àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí

ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.

10Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni

jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́;

wọ́n da eruku sí orí wọn

wọ́n sì wọ aṣọ àkísà.

Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu

ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.

11Ojú mi kọ̀ láti sọkún,

mo ń jẹ ìrora nínú mi,

mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀

nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run,

nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú

ní òpópó ìlú.

12Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn,

“Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó

bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe

ní àwọn òpópónà ìlú,

bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò

láti ọwọ́ ìyá wọn.

13Kí ni mo le sọ fún ọ?

Pẹ̀lú kí ni mo lè fi ọ́ wé,

Ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu?

Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé,

kí n lè tù ọ́ nínú,

Ìwọ wúńdíá obìnrin Sioni?

Ọgbẹ́ rẹ jì bí Òkun.

Ta ni yóò wò ọ́ sàn?

14Ìran àwọn wòlíì rẹ

jẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n;

wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn

tí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ.

Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọ

jẹ́ èké àti ìmúniṣìnà.

15Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹ

pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí;

wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọn

sí ọmọbìnrin Jerusalẹmu:

“Èyí ha ni ìlú tí à ń pè ní

àṣepé ẹwà,

ìdùnnú gbogbo ayé?”

16Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọn

gbòòrò sí ọ;

wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payínkeke

wọ́n wí pé, “A ti gbé e mì tán.

Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí;

tí a sì wá láti rí.”

17Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu;

ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ,

tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́.

Ó ti ṣí ọ ní ipò láì láàánú,

ó fún ọ̀tá ní ìṣẹ́gun lórí rẹ,

ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.

18Ọkàn àwọn ènìyàn

kígbe jáde sí Olúwa.

Odi ọmọbìnrin Sioni,

jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ sàn bí odò

ní ọ̀sán àti òru;

má ṣe fi ara rẹ fún ìtura,

ojú rẹ fún ìsinmi.

19Dìde, kígbe sókè ní àṣálẹ́,

bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀

tú ọkàn rẹ̀ jáde bí omi

níwájú Olúwa.

Gbé ọwọ́ yín sókè sí i

nítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀

tí ó ń kú lọ nítorí ebi

ní gbogbo oríta òpópó.

20“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó:

Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyí

Ǹjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn,

àwọn ọmọ tí wọn ń ṣe ìtọ́jú fún?

Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíì

ní ibi mímọ́ Olúwa?

21“Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀

sínú eruku àwọn òpópó;

àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi

ti ṣègbé nípa idà.

Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ;

Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.

22“Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àsè,

bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi.

Ní ọjọ́ ìbínú Olúwa

kò sí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè;

àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn,

ni ọ̀tá mi parun.”

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

耶利米哀歌 2:1-22

耶和华惩罚耶路撒冷

1主的怒气像乌云一样遮盖锡安2:1 ”希伯来文是“女子”,可能是对锡安的昵称,下同2:4104:22

祂使以色列的荣美从天上坠下。

祂发怒的时候并不顾念自己的脚凳。

2主毫不留情地毁灭雅各一切的住处,

祂在烈怒中夷平犹大的堡垒,

以色列及其首领蒙羞。

3祂发烈怒毁灭以色列全军。

敌人袭来时,祂收回大能的手。

祂像烈焰一样吞噬雅各

4祂抬起右手张弓搭箭,

宛若仇敌,

杀戮一切悦人眼目的人,

将祂的怒火撒向锡安城的帐篷。

5主像敌人一样毁灭以色列

吞噬她的宫殿,夷平她的堡垒,

使犹大人哀哭不止。

6祂摧毁自己的居所,

如同摧毁花园;

祂摧毁自己规定的聚会之处,

使锡安的人民忘记安息日和节期。

祂在烈怒中弃绝所有的君王和祭司。

7主撇弃自己的祭坛,

憎恶自己的圣所,

耶路撒冷的殿墙交给敌人。

他们像过节一样,

在耶和华的殿中喧嚷吵闹。

8耶和华决意拆毁锡安的城墙,

祂拉了准线,

定意毁灭,决不停止。

祂使城墙和壁垒一同悲哀哭泣。

9锡安的城门陷入地中,

主摧毁、砍断她的门闩。

她的君王和首领流落异乡,

律法不复存在,

她的先知得不到从耶和华而来的异象。

10锡安城的长老腰束麻布,

头蒙灰尘,坐在地上,

默然不语;

耶路撒冷的少女垂头至地。

11我哭得眼睛失明,

心如刀割,肝胆欲碎,

因为人民惨遭毁灭,

儿童和婴孩昏倒在街头。

12孩子们问母亲:

“哪里有饼和酒呢?”

他们像受伤的勇士,

昏倒在城中的街头,

在母亲怀中奄奄一息。

13耶路撒冷啊,我该说什么呢?

谁能与你的苦难相比呢?

锡安啊,我用什么话语才能安慰你呢?

你的伤口深如海洋,

谁能医治你呢?

14你的先知所见的异象虚假无用。

他们没有揭露你的罪恶,

以致你被掳。

他们给你的预言虚假谬误。

15路人都拍掌嘲笑你。

他们向耶路撒冷城摇头,

嗤笑道:

“这就是那被誉为完美无瑕、

普世喜悦的城吗?”

16敌人都幸灾乐祸地讥讽你,

他们咬牙切齿地说:

“我们吞灭了她!

这是我们期待已久的日子!

我们终于见到这一天了!”

17耶和华实现了祂的计划,

成就了祂很久以前的应许。

祂毫不留情地毁灭了你,

使你的仇敌幸灾乐祸,

耀武扬威。

18锡安的城墙啊,

你要从心里向主呼求!

你的眼泪要像江河一样昼夜涌流,

不歇不眠。

19你要在夜间起来,

在主面前整夜呼求,

向祂倾心吐意;

你要为饿昏街头的孩童向主举手祷告。

20“耶和华啊,求你看看,

你曾这样对付过谁呢?

母亲岂能吃自己的孩子?

祭司和先知岂能在主的圣所中被杀?

21“老人和小孩陈尸街头,

少男少女都丧身刀下。

你在发怒的日子杀了他们,

毫不留情。

22“你从四面八方召人攻击我,

如同召集人过节。

耶和华发怒的日子,

无人得以逃脱,无人得以幸免。

敌人杀光了我养育的孩子。”