Ẹkun Jeremiah 3 – YCB & CCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ẹkun Jeremiah 3:1-66

1Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú

pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.

2Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn

nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀;

3Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ padà sí mi

síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.

4Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó

ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.

5Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká

pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.

6Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn,

bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.

7Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ;

ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.

8Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́,

ó kọ àdúrà mi.

9Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi;

ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.

10Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀,

bí i kìnnìún tí ó sápamọ́.

11Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀

ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.

12Ó fa ọfà rẹ̀ yọ

ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.

13Ó fa ọkàn mí ya

pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.

14Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi;

wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.

15Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò

àti ìdààmú bí omi.

16Ó ti fi òkúta kán eyín mi;

ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.

17Mo ti jìnnà sí àlàáfíà;

mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.

18Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ

àti ìrètí mi nínú Olúwa.”

19Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi,

ìkorò àti ìbànújẹ́.

20Mo ṣèrántí wọn,

ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.

21Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn

àti nítorí náà ní mo nírètí.

22Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé,

nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.

23Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀;

títóbi ni òdodo rẹ̀.

24Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa;

nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.

25Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀,

sí àwọn tí ó ń wá a.

26Ó dára kí a ní sùúrù

fún ìgbàlà Olúwa.

27Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà

nígbà tí ó wà ní èwe.

28Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́,

nítorí Olúwa ti fi fún un.

29Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku—

ìrètí sì lè wà.

30Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a,

sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.

31Ènìyàn kò di ìtanù

lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.

32Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn,

nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.

33Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá

tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.

34Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀

gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.

35Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀

níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ.

36Láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà,

Ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.

37Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀

tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.

38Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ

ni rere àti búburú tí ń wá?

39Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn

nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?

40Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò,

kí a sì tọ Olúwa lọ.

41Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè

sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé:

42“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀

ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.

43“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa;

ìwọ ń parun láìsí àánú.

44Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ

pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.

45Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn

láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.

46“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn

gbòòrò sí wa.

47Àwa ti jìyà àti ìparun,

nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”

48Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò

nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.

49Ojú mi kò dá fún omijé,

láì sinmi,

50títí ìgbà tí Olúwa yóò ṣíjú wolẹ̀

láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.

51Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi

nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.

52Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí

dẹ mí bí ẹyẹ.

53Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò

wọ́n sì ju òkúta lù mí.

54Orí mi kún fún omi,

mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.

55Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa,

láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.

56Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi: “Má ṣe di etí rẹ

sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”

57O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́,

o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”

58Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò,

o ra ẹ̀mí mi padà.

59O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi

Gbé ẹjọ́ mi ró!

60Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn,

gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.

61Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn

àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi—

62Ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ

sí mi ní gbogbo ọjọ́.

63Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde,

wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.

64Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn

fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.

65Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn,

kí o sì fi wọ́n ré.

66Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú,

lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

耶利米哀歌 3:1-66

刑罚、悔改和盼望

1我在耶和华烈怒的杖下受尽痛苦。

2祂把我赶进黑暗,

使我不见光明,

3又屡屡攻击我,终日不断。

4祂使我皮肉枯槁,

祂折断我的骨头。

5祂使我四面受困,

尝尽痛苦艰辛。

6祂使我住在幽暗中,

像久已死去的人。

7祂围困我,使我无法逃脱,

祂给我戴上沉重的铜链。

8即使我哀哭呼求,

祂也掩耳不听。

9祂用凿好的石头阻挡我的去路,

使我的道路曲折难行。

10祂像埋伏的巨熊,

又像伺机突袭的猛狮,

11把我拖离大路,

将我撕成碎片,一片凄凉。

12祂弯弓搭箭,把我当箭靶,

13用箭袋中的箭射穿我的心脏。

14我成了万人的笑柄,

他们终日唱歌讽刺我。

15祂使我饱受苦楚,尝尽苦涩。

16祂用石头打断我的牙齿,

把我践踏在尘土中。

17我失去平安,

忘记了什么是快乐。

18我说:“我精疲力竭,

对耶和华失去盼望。”

19想起我的痛苦和漂泊流离,

就如苦艾和胆汁一样苦涩。

20那情景萦绕心头,

使我心情沉重。

21然而,我想起这事,

便有了盼望,

22就是耶和华的慈爱永不终止,

祂的怜悯永无穷尽。

23祂的慈爱和怜悯每天早晨都是新的,

祂的信实无比伟大!

24我心里知道,

耶和华是我的产业,

我要仰望祂。

25耶和华必赐福给那些等候和寻求祂的人,

26因此,默然等候耶和华的拯救是美好的。

27年轻时负轭受苦是有益的。

28受耶和华管教时,

要默然独坐。

29要谦卑,脸伏于地,

或许还有希望。

30要任人打脸,甘心忍受凌辱。

31因为主不会永远撇弃人。

32主尽管使人忧伤,

祂依然怜悯人,

因为祂有无限的慈爱。

33祂不愿使人忧伤、痛苦。

34将囚犯踩在脚下,

35在至高者面前冤枉他人,

36审理案件时颠倒是非,

都是主所不容许的。

37若非主许可,

谁的话可以兑现呢?

38祸福岂不都出自至高者的口吗?

39世人因自己的罪受罚,

又何必怨天尤人呢?

40我们要省察自己的行为,

重新归向耶和华。

41让我们举起双手,

诚心向天上的上帝祷告说:

42“我们犯罪、背叛,

你没有赦免我们。

43“你满怀愤怒地追赶我们,

毫不留情地杀戮我们。

44你以密云遮盖自己,

以致祷告达不到你那里。

45你使我们在列国中沦为废物、渣滓。

46“我们的仇敌都幸灾乐祸。

47我们充满恐惧,

面临陷阱、残害和毁灭。”

48因同胞被毁灭,我泪流成河。

49我的眼泪涌流不息,

50直到耶和华从天上垂顾。

51目睹城中妇女的遭遇,

我痛苦不已。

52敌人无故地追捕我,

如同捕猎飞鸟。

53他们把我推进坑里,

又用石头砸我。

54水已经漫过我的头,

我想我要灭亡了。

55耶和华啊,

我在深渊呼求你的名。

56你曾垂听我的呼求,

求你现在不要掩耳不听我的祈祷。

57我向你呼求的时候,

你曾走近我身旁,

安慰我说:“不用害怕!”

58主啊,你为我申了冤,

救赎了我的性命。

59耶和华啊,你已明察我的冤情,

求你为我主持公道。

60你看见了他们怎样仇恨我、

谋害我。

61你听见了他们怎样辱骂我、

谋害我。

62他们整天诽谤我,图谋害我。

63你看!他们或坐下或起来,

都唱歌讽刺我。

64耶和华啊,

求你按照他们的所作所为报应他们!

65求你使他们心里顽固,

好让你的咒诅落在他们身上!

66求你发怒追赶他们,

从世上铲除他们!