Òwe 31 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 31:1-31

1Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba,

ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ.

2“Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi!

Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.

3Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin,

okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.

4“Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli

kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì

kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle

5Kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí

kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n

6Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé

wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora;

7Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn

kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.

8“Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnrawọn

fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun

9Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè

jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”

10Ta ni ó le rí aya oníwà rere?

Ó níye lórí ju iyùn lọ

11Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀

kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.

12Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi

ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

13Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀

Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.

14Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò;

ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn

15Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn;

ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀

àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.

16Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á;

nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀

17Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára

apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́

18Ó rí i pé òwò òun pé

fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru

19Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú

ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú

20O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà

ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.

21Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀

nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.

22Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;

ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀

23A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú

níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú

24Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n

ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò

25Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ

ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.

26A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n

ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀

27Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀

kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́

28Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún

ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un

29“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá

ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ”

30Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán

nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn

31Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i

kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.

Akuapem Twi Contemporary Bible

Mmebusɛm 31:1-31

Ɔhene Lemuel Nsɛm

1Ɔhene Lemuel nsɛm a ɛyɛ nkuranhyɛ a ne na kyerɛɛ no:

2Tie, me babarima! Tie, me yafunu ba,

Tie, me bɔhyɛ ba, me mpaebɔ ho mmuae!

3Nsɛe wʼahoɔden wɔ mmea31.3 Saa mmea yi yɛ mmea nguamanfo a wɔwɔ ahemfi a wobetumi atwe ɔhene adwene afi nʼadwuma so. ho,

wɔn a wogu ahemfo asu no.

4Enye mma ahemfo, Lemuel,

asanom nye mma ahemfo,

ɛnsɛ sɛ sodifo pere bobesa ho;

5sɛ wɔnom nsa a wɔn werɛ befi nea mmara no ka,

na wɔn a wɔhyɛ wɔn so no rennya nea ɛyɛ wɔn kyɛfa.

6Fa bobesa ma wɔn a wɔresɛe,

na fa nsa ma wɔn a wɔwɔ amanehunu mu;

7Momma wɔnnom, na wɔn werɛ mfi wɔn hia,

na wɔnnkae wɔn awerɛhow bio.

8Kasa ma wɔn a wontumi nkasa mma wɔn ho,

kasa ma mmɔborɔfo yiyedi.

9Kasa na bu atɛntrenee;

kasa ma ahiafo ne onnibi yiyedi.

Awiei: Ɔyere A Ɔsom Bo

10Ɔyere pa, hena na obenya?

Ɔsom bo pa ara sen nhene pa.

11Ne kunu wɔ ne mu ahotoso pa ara,

na biribiara a ɛwɔ bo nhia no.

12Ɔde nea eye brɛ no, na ɛnyɛ ɔhaw,

ne nkwanna nyinaa mu.

13Ɔhwehwɛ oguannwi ne asaawa

na ɔde ne nsa nwen wɔ fɛw so.

14Ɔte sɛ aguadifo ahyɛn,

ɔde ne nnuan fi akyirikyiri ba.

15Ade nnya nkyee no na wasɔre;

osiesie aduan ma nʼabusuafo

na ɔkyekyɛ nnwuma ma ne mmaawa.

16Osusuw afuw ho na ɔtɔ;

ofi nea onya mu yɛ bobeturo.

17Ɔde nsi yɛ nʼadwuma;

nʼabasa mu wɔ ahoɔden ma nʼadwuma.

18Ɔhwɛ sɛ nʼaguadi so wɔ mfaso,

na ne kanea anum anadwo.

19Daa, na ne nsa kura tadua mu

a ne nsateaa nso retoatoa asaawa.

20Ogow ne nsam ma ahiafo

na ne nsa so ohiani so.

21Sɛ sukyerɛmma tɔ a ne yam nhyehye no wɔ ne fifo ho;

efisɛ wɔn nyinaa wɔ adurade a wɔde ko awɔw.

22Ɔyɛ ne mpasotam;

na ofura nwera ne sirikyi ntama.

23Ne kunu wɔ anuonyam wɔ kuropɔn pon ano,

faako a ɔne asase no so mpanyimfo tena.

24Ɔpempam nwera ntade tontɔn,

na otu nkyekyeremu ma aguadifo.

25Ɔwɔ ahoɔden ne anuonyam;

na onsuro nna a ɛwɔ nʼanim.

26Ɔkasa nyansa mu,

na nokware nkyerɛkyerɛ wɔ ne tɛkrɛma so.

27Ɔhwɛ ne fi mu nnwuma so

na onnyigye anihaw so.

28Ne mma sɔre a wɔfrɛ no nhyira;

ne kunu nso saa ara, na ɔkamfo no se,

29“Mmea pii yɛ nneɛma a ɛwɔ din

na wo de, wosen wɔn nyinaa.”

30Ɔbea kɔnnɔfo yɛ nnaadaa, na ahoɔfɛ twa mu ntɛm so;

nanso ɔbea a osuro Awurade no fata nkamfo.

31Fa abasobɔde a wanya no ma no,

na wɔnkamfo ne nnwuma wɔ kuropɔn pon ano.