Òwe 30 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 30:1-33

Àwọn ọ̀rọ̀ tí Aguri sọ

1Àwọn ọ̀rọ̀ Aguri ọmọ Jake, ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí ọkùnrin yìí sọ fún Itieli.

Sí Itieli àti sí Ukali.

2“Èmi ni aláìmòye ju nínú àwọn ènìyàn;

N kò ní òye ènìyàn.

3Èmi kò tilẹ̀ kọ́ ọgbọ́n

tàbí ní ìmọ̀ ẹni mímọ́ nì

4Ta ni ó ti gòkè lọ sí ọ̀run tí ó sì padà sọ̀kalẹ̀?

Ta ni ó ti kó afẹ́fẹ́ jọ sí ihò àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀?

Ta ni ó ti ta kókó omi sétí aṣọ?

Ta ni ó fi gbogbo ìpìlẹ̀ ayé lélẹ̀?

Kí ni orúkọ rẹ̀, àti orúkọ ọmọ rẹ̀?

Sọ fún mi bí o bá mọ̀.

5“Gbogbo ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ aláìlábùkù;

òun ni ààbò fún gbogbo ẹni fi í ṣe ibi ìpamọ́ wọn

6Má ṣe fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀,

àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò bá ọ wí yóò sì sọ ọ́ di òpùrọ́.

7“Ohun méjì ni mo ń béèrè lọ́wọ́ rẹ, Olúwa;

má ṣe fi wọ́n dù mí kí ń tó kú:

8Mú èké ṣíṣe àti irọ́ jìnnà sí mi;

má ṣe fún mi ní òsì tàbí ọrọ̀,

ṣùgbọ́n fún mi ní oúnjẹ òòjọ́ mi nìkan,

9Àìṣe bẹ́ẹ̀, mo lè ní àníjù kí n sì gbàgbé rẹ

kí ń sì wí pé, ‘Ta ni Olúwa?’

Tàbí kí ń di òtòṣì kí ń sì jalè

kí ń sì ṣe àìbọ̀wọ̀ fún orúkọ Ọlọ́run mi.

10“Má ṣe ba ìránṣẹ́ lórúkọ jẹ́ lọ́dọ̀ ọ̀gá rẹ̀,

kí ó má ba fi ọ́ bú, kí ìwọ má ba jẹ̀bi.

11“Àwọn kan wá ṣépè fún àwọn baba wọn

tí wọn kò sì súre fún àwọn ìyá wọn:

12Àwọn tí ó mọ́ ní ojú ara wọn

síbẹ̀ tí wọn kò sì mọ́ kúrò nínú èérí wọn;

13Àwọn ẹni tí ojú wọn gbéga nígbà gbogbo,

tí ìwolẹ̀ wọn sì kún fún ìgbéraga.

14Àwọn ẹni tí eyín wọn jẹ́ idà

àwọn tí èrìgì wọn kún fún ọ̀bẹ

láti jẹ àwọn tálákà run kúrò ní ilẹ̀ ayé

àwọn aláìní kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.

15“Eṣúṣú ni ọmọbìnrin méjì.

‘Mú wá! Mú wá!’ ní wọn ń ké.

“Àwọn nǹkan mẹ́ta kan wà tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn láéláé,

mẹ́rin tí kò jẹ́ wí láéláé pé, ‘Ó tó!’:

16Ibojì, inú tí ó yàgàn,

ilẹ̀ tí omi kì í tẹ́lọ́rùn láéláé,

àti iná, tí kì í wí láéláé pé, ‘Ó tó!’

17“Ojú tí ń fi baba ṣẹ̀fẹ̀,

tí ó kẹ́gàn ìgbọ́ràn sí ìyá,

ẹyẹ ìwò ẹ̀bá odò ni yóò yọ ọ́,

igún yóò mú un jẹ.

18“Àwọn nǹkan mẹ́ta wà tí ó jẹ́ ìyàlẹ́nu fún mi,

mẹ́rin tí kò yé mi:

19Ipa ẹyẹ idì ní òfúrufú

ipa ejò lórí àpáta

ipa ọkọ̀ ojú omi lójú agbami Òkun

àti ipa ọ̀nà ọkùnrin tí ó mú wúńdíá lọ́wọ́.

20“Èyí ni ọ̀nà alágbèrè obìnrin

ó jẹun ó sì nu ẹnu rẹ̀

ó sì wí pé, N kò ṣe ohunkóhun tí kò tọ́.

21“Lábẹ́ nǹkan mẹ́ta ni ilé ayé ti ń wárìrì

lábẹ́ ohun mẹ́rin ni kò ti lè mí fín ín.

22Ìránṣẹ́ tí ó di ọba

aláìgbọ́n tí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ

23Obìnrin tí gbogbo ènìyàn kórìíra tí ó sì wá lọ́kọ

ìránṣẹ́bìnrin tí ó gbọkọ mọ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.

24“Àwọn ohun mẹ́rin ló kéré láyé

síbẹ̀ wọ́n gbọ́n gidigidi;

25Àwọn èèrà jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá,

síbẹ̀ wọ́n kó oúnjẹ wọn pamọ́ ní àsìkò òjò

26Ehoro jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá;

síbẹ̀ wọ́n ń ṣe ihò wọn sí ibi pálapàla àpáta;

27àwọn eṣú kò ní ọba,

síbẹ̀ gbogbo wọ́n ń jáde lọ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́

28Ọmọnílé fi ọwọ́ rẹ̀ dì mú,

síbẹ̀ a ń rí i ní ààfin ọba.

29“Àwọn ohun mẹ́ta ní ń bẹ tí ń rìn rere,

ohun mẹ́rin ni ó dára púpọ̀ ní ìrìn rírìn:

30Kìnnìún, alágbára láàrín ẹranko tí kì í sá fún ohunkóhun

31Ẹsin tí a dì lẹ́gbẹ̀ẹ́;

àti òbúkọ,

àti ọba láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.

32“Bí ìwọ bá ti hùwà aṣiwèrè nípa gbígbé ara rẹ ga,

tàbí tí o bá ti gbèrò ibi,

da ọwọ́ rẹ bo ẹnu rẹ!

33Nítorí bí fífún omi ọmú tí í mú wàrà wá,

tí fífún imú sì ń mú ẹ̀jẹ̀ jáde,

bẹ́ẹ̀ ni rírú ìbínú sókè í mú ìjà wá.”

Akuapem Twi Contemporary Bible

Mmebusɛm 30:1-33

Agur Nsɛm A Ɔkae

1Yake babarima Agur nsɛm a ɔkae a ɛyɛ nkuranhyɛ:

Saa ɔbarima yi ka kyerɛɛ Itiel ne Ukal se:

2“Me na minnim hwee koraa wɔ nnipa mu,

minni onipa ntease.

3Minsuaa nyansa,

na minni Ɔkronkronni no ho nimdeɛ nso.

4Hena na waforo akɔ ɔsoro na wasian aba fam?

Hena na wabɔ mframa boa wɔ ne nsam?

Hena na ɔde nʼatade abɔ nsu boa?

Hena na ɔbɔɔ asase tamaa yi?

Ne din de dɛn, na ne babarima nso din de dɛn?

Sɛ wunim a ka kyerɛ me!

5“Onyankopɔn asɛm biara yɛ nokware;

ɔyɛ nkatabo ma wɔn a woguan toa no.

6Mfa biribi nka nʼasɛm ho,

anyɛ saa a ɔbɛka wʼanim ama woayɛ ɔtorofo.

7Awurade, nneɛma abien na mehwehwɛ afi wo nkyɛn;

mfa nkame me ansa na mawu:

8ma me ne atoro ne nnaadaasɛm ntam nware koraa;

mma mennyɛ ohiani anaa ɔdefo;

nanso ma me me daa aduan nkutoo.

9Anyɛ saa a, ebia minya me ho pii a ɛbɛma mapa wo

na maka se, ‘Hena ne Awurade?’

Anaa mɛyɛ ohiani na mabɔ korɔn,

na ama magu me Nyankopɔn din ho fi.

10“Nsɛe ɔsomfo din nkyerɛ ne wura;

sɛ woyɛ saa a, ɔbɛdome wo na wubetua so ka.

11“Nnipa bi dome wɔn agyanom,

na wonhyira wɔn nanom nso;

12Wɔn a wɔteɛ wɔ wɔn ankasa ani so

nanso wɔnhohoroo wɔn ho fi no;

13wɔn a wɔn ani tra ntɔn,

na wobu animtiaa;

14wɔn a wɔn se yɛ afoa

na asekan hyehyɛ wɔn abogye mu

wɔn na wɔbɛtɔre ahiafo ase afi asase so,

na wɔayi ahiafo afi adesamma mu.

15“Amemem wɔ mmabea baanu

a wɔteɛ mu se, ‘Fa ma! Fa ma!’ 

“Nneɛma abiɛsa na ɛmmee da

anan na ɛnka da se, ‘Eye!’

16Ɔda,

obonin awotwaa,

asase a ɛyɛ wosee daa,

ne ogya a ɛnka da se, ‘Eye!’ 

17“Ani a eyi agya ahi,

na ebu ɛna animtiaa no,

obon mu kwaakwaadabi betutu,

na apete abedi.

18“Nneɛma abiɛsa na ɛyɛ me nwonwa,

anan na mente ase:

19Ɔkwan a ɔkɔre nam so wɔ wim,

sɛnea ɔwɔ nantew ɔbotan so,

ɔkwan a hyɛn nam so wɔ po tamaa so,

ne sɛnea ɔbarima dɔ ababaa.

20“Ɔbea ɔwaresɛefo kwan ni:

Odidi, ɔpepa nʼano

na ɔka se, ‘Menyɛɛ mfomso biara.’ 

21“Nneɛma abiɛsa na ɛma asase wosow,

anan na asase ntumi nnyina ano:

22akoa a wabɛyɛ ɔhene,

ɔkwasea a wadidi amee,

23ɔbea a wɔmpɛ no na waware,

afenaa a otu nʼawuraa tena nʼanan mu.

24“Nneɛma nketenkete anan na ɛwɔ asase so,

nanso wɔyɛ anyansafo ankasa:

25Ntɛtea yɛ abɔde nketewa a wonni ahoɔden,

nanso wɔboaboa wɔn aduan ano ahuhuru bere mu;

26Nkukuban30.26 Nkukuban yɛ nnanko mu ahorow bi a, wɔtena akuwakuw wɔ mmepɔw mu. yɛ abɔde a wonni ahoɔden,

nanso wɔyɛ wɔn afi wɔ abotan mu,

27mmoadabi nni ɔhene,

nanso wɔsa so akuwakuw, kɔ wɔn anim;

28wotumi de nsa kyere ɔketew,

nanso wohu no abirɛmpɔn ahemfi.

29“Nneɛma abiɛsa na wɔwɔ abirɛmpɔnnantew,

anan na wɔkeka wɔn ho te sɛ abirɛmpɔn:

30gyata, mmoadoma hene a, biribiara mmɔ no hu;

31akokɔnini a ɔretutu taataa,

ɔpapo,

ne ɔhene a nʼasraafo atwa no ho ahyia.

32“Sɛ woayɛ ɔkwasea ama wo ho so,

anaa woadwene bɔne a,

ma wʼani nwu na mua wʼano!

33Sɛnea wɔka nufusu nu mu a srade fi mu ba,

na wokyinkyim hwene a etu mogya no,

saa ara na abufuw de akasakasa ba.”