Oniwaasu 1 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Oniwaasu 1:1-18

Asán ni ohun ayé

1Ọ̀rọ̀ Oniwaasu, ọmọ Dafidi, ọba Jerusalẹmu:

2“Asán inú asán!”

oníwàásù náà wí pé,

“Asán inú asán!

Gbogbo rẹ̀ asán ni.”

3Kí ni ènìyàn rí jẹ ní èrè lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ̀,

lórí èyí tí ó ń ṣe wàhálà sí lábẹ́ oòrùn?

4Bí ìran kan ti wá ni ìran mìíràn ń kọjá lọ,

síbẹ̀ ayé dúró títí láé.

5Oòrùn ń ràn, oòrùn sì ń wọ̀,

ó sì sáré padà sí ibi tí ó ti yọ.

6Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ lọ sí ìhà gúúsù,

Ó sì ń fẹ́ yípo sí ìhà àríwá,

a sì tún padà sí ọ̀nà rẹ̀.

7Gbogbo odò ń sàn sí inú Òkun,

síbẹ̀síbẹ̀ Òkun kò kún.

Níbi tí àwọn odò ti wá,

níbẹ̀ ni wọ́n tún padà sí.

8Ohun gbogbo ni ó ń mú àárẹ̀ wá,

ju èyí tí ẹnu le è sọ.

Ojú kò tí ì rí ìrírí tí ó tẹ́ ẹ lọ́rùn,

bẹ́ẹ̀ ni, etí kò tí ì kún fún gbígbọ́.

9Ohun tí ó ti wà tẹ́lẹ̀ náà ni yóò sì máa wà, ohun tí a ti ṣe sẹ́yìn

òun ni a ó tún máa ṣe padà

kò sí ohun tuntun lábẹ́ oòrùn.

10Ǹjẹ́ ohun kan wà tí ẹnìkan le è sọ wí pé,

“Wò ó! Ohun tuntun ni èyí”?

Ó ti wà tẹ́lẹ̀ rí ní ọjọ́ tó ti pẹ́,

o ti wà ṣáájú tiwa.

11Kò sí ìrántí ohun ìṣáájú

bẹ́ẹ̀ ni ìrántí kì yóò sí fún

ohun ìkẹyìn tí ń bọ̀

lọ́dọ̀ àwọn tí ń bọ̀ ní ìgbà ìkẹyìn.

Asán ni ọgbọ́n ènìyàn

12Èmi, Oniwaasu ti jẹ ọba lórí Israẹli ní Jerusalẹmu rí. 13Mo fi àsìkò mi sílẹ̀ láti kọ́ àti láti ṣe àwárí pẹ̀lú ọgbọ́n, gbogbo ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ ọ̀run. Háà! Ẹrù wúwo tí Ọlọ́run ti gbé lé àwọn ènìyàn: 14Èmi ti rí ohun gbogbo tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn, gbogbo rẹ̀ kò ní ìtumọ̀ bí ẹní gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.

15Ohun tí ó ti wọ́ kò le è ṣe é tọ́ mọ́,

ohun tí kò sí kò le è ṣe é kà.

16Mo rò nínú ara mi, “Wò ó, mo ti dàgbà, ọgbọ́n mi sì ti pọ̀ ju ti ẹnikẹ́ni tí ó ti ṣe alákòóso Jerusalẹmu síwájú mi lọ, mo ti ní ìrírí púpọ̀ nípa ọgbọ́n àti ìmọ̀.” 17Nígbà náà ni mo fi ara jì láti ní ìmọ̀ nípa ọgbọ́n, àti pàápàá àìgbọ́n àti òmùgọ̀, ṣùgbọ́n mo rí, wí pé èyí pẹ̀lú bí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.

18Nítorí pé ọgbọ́n púpọ̀ ìbànújẹ́ púpọ̀ ní ń mú wá,

bí ìmọ̀ bá sì ṣe pọ̀ tó náà ni ìbànújẹ́ ń pọ̀ tó.

Akuapem Twi Contemporary Bible

Ɔsɛnkafo 1:1-18

Biribiara Yɛ Adehuhuw

1Eyinom ne nsɛm a Ɔsɛnkafo, ɔhene Dawid babarima a ɔyɛ ɔhene wɔ Yerusalem se:

2“Ahuhude! Ahuhude!”

Ɔsɛnkafo no na ose.

“Ahuhude mu ahuhude

Biribiara yɛ ahuhude.”

3Dɛn na onipa nya fi nʼadwumayɛ nyinaa mu,

nea okum ne ho yɛ no owia so no?

4Awo ntoatoaso ba na ɛkɔ,

nanso asase tim hɔ daa.

5Owia pue na owia kɔtɔ,

na ɛyɛ ntɛm kɔ nea epue fii hɔ no.

6Mframa bɔ kɔ anafo fam

na ɛdan hwɛ atifi fam;

ekyinkyin kɔ baabiara,

na ɛsan bɔ fa ne kwan so.

7Nsubɔnten nyinaa sen kogu po mu,

nanso po nyɛ ma da.

Faako a nsubɔnten no fi no

hɔ na wɔsan kɔ bio.

8Biribiara yɛ ɔbrɛ

a ɛboro nea obi bɛka so.

Ani nhwɛ ade nwie da

na aso nso ntie nsɛm mma ɛnyɛ mma da.

9Nea aba no bɛba bio,

nea wɔayɛ no, wɔbɛyɛ bio;

ade foforo biara nni owia yi ase.

10Biribi wɔ hɔ a wobetumi aka wɔ ho se:

“Hwɛ! eyi yɛ ade foforo” ana?

Ɛwɔ hɔ dedaw fi tete nteredee;

ɛwɔ hɔ ansa na wɔwoo yɛn.

11Wɔnkae tetefo no,

na wɔn a wonnya nnwoo wɔn no nso,

wɔn a wobedi wɔn akyi no

renkae wɔn.

Nimdeɛ Yɛ Ahuhude

12Me, Ɔsɛnkafo, na meyɛ Israelhene wɔ Yerusalem. 13Mituu me ho sii hɔ sɛ mede nimdeɛ besua ayɛ nhwehwɛmu wɔ biribiara a wɔyɛ no owia yi ase ho. Adesoa duruduru a Onyankopɔn de ato adesamma so! 14Mahu biribiara a wɔyɛ no owia yi ase; ne nyinaa nka hwee, ɛte sɛnea obi tu mmirika taa mframa.

15Nea akyea no wontumi nteɛ;

na nea enni hɔ no wontumi nkan.

16Mekaa wɔ me tirim se, “Hwɛ, manyin na manya nimdeɛ bebree asen obiara a watena Yerusalem ahengua so ansa na merebedi ade. Manya nhumu ne nimdeɛ mu osuahu.” 17Afei meyɛɛ mʼadwene sɛ mɛhwehwɛ na mate nimdeɛ, ne adammɔsɛm ne nkwaseasɛm ase. Nanso mihuu sɛ eyi nso te sɛnea obi tu mmirika taa mframa.

18Nimdeɛ bebree de awerɛhow na ɛba;

nyansa dɔɔso a, awerɛhowdi dɔɔso.