Òwe 2 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 2:1-22

Èrè ìwà rere tí ọgbọ́n ń mú wá

1Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi,

tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,

2tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n

tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,

3àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn,

tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye

4bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà

tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.

5Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa,

ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.

6Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n,

láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá

7Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo,

Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,

8ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́

Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.

9Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́,

àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.

10Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ

ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ

11Ìmòye yóò pa ọ mọ́

òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.

12Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú,

lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,

13ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin

láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,

14ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú,

tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,

15ọ̀nà ẹni tí ó wọ́

tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.

16Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin,

àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,

17ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀

tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.

18Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú

ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.

19Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà

bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.

20Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere

kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.

21Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà

àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.

22Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà

a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.

O Livro

Provérbios 2:1-22

Benefícios morais da sabedoria

1Meu filho, se aceitares as minhas palavras e guardares os meus mandamentos, 2se ouvires atentamente a sabedoria e abrires o teu coração para o entendimento; 3sim, se quiseres melhor compreensão das coisas da vida, 4e discernimento, se buscares essas coisas como se fossem dinheiro, ou um tesouro precioso escondido, 5então entenderás a importância de temer o Senhor e chegarás ao conhecimento de Deus. 6Porque o Senhor dá sabedoria! Das suas palavras vêm o conhecimento e a inteligência. 7Ele garante a verdadeira sabedoria aos retos; é um escudo para os que andam com integridade; 8protege-os para que a sua conduta se conforme com os juízos de Deus.

9Só então saberás distinguir a justiça e a injustiça, o direito e o errado, e poderás tomar as decisões corretas em cada situação. 10Porque a sabedoria penetrará no teu coração e o entendimento da vida será para ti uma fonte de alegria. 11O bom senso te guardará e o entendimento te protegerá, 12mantendo-te afastado de maus caminhos e de gente que fala falsidades. 13São pessoas que se desviam dos caminhos retos de Deus para trilharem os tenebrosos, que só conduzem à maldade. 14Ficam felizes quando praticam o mal; gozam intimamente com os seus pecados. 15Tudo o que fazem é andar por caminhos errados e turtuosos.

16Só a sabedoria pode proteger um homem dos falsos afagos de uma mulher leviana; 17mulher que deixou o companheiro da sua mocidade e desprezou a aliança do seu Deus. 18A sua casa e a sua vida familiar resvalam por um caminho de morte. 19Todos os que a procuram estão condenados e impossibilitados de encontrar os caminhos da vida.

20Portanto segue as pisadas dos que andam nos caminhos do bem; mantém-te nos trilhos da justiça. 21Porque só os retos habitarão a Terra e os íntegros nela permanecerão. 22Os malvados serão removidos da Terra; os infiéis serão tirados dela!