Òwe 3 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 3:1-35

Àwọn àǹfààní ọgbọ́n mìíràn

1Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi.

Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.

2Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà,

ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.

3Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé

so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ,

kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.

43.4: Ro 12.17.Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere

ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.

5Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ

má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ;

6Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ

òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.

73.7: Ro 12.16.Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ

bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.

8Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ

àti okun fún àwọn egungun rẹ.

9Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa,

pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ

10Nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya

àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.

113.11,12: Hb 12.5,6.Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa

má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,

12Nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí

bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.

13Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀,

ẹni tí ó tún ní òye sí i

14Nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ

ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.

15Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ;

kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.

16Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀;

ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.

17Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura,

òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.

18Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á;

àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.

19Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;

20Nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà,

àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.

21Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́,

má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.

22Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ,

àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.

23Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu,

ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀;

24Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù,

nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.

25Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì,

tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.

26Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ,

kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.

27Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ,

nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.

28Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé,

“Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,”

nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.

29Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ,

ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.

30Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí,

nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.

31Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan

tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.

32Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà

ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.

33Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú,

ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.

343.34: (Gk): Jk 4.6; 1Pt 5.5.Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́,

ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.

35Ọlọ́gbọ́n jogún iyì,

ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.

O Livro

Provérbios 3:1-35

Mais benefícios da sabedoria

1Meu filho, não te esqueças do que te ensinei

e guarda no teu coração os meus mandamentos;

2pois eles te darão uma vida longa e de paz.

3Mantém na tua vida a bondade e a fidelidade;

trá-las contigo, como um colar, e grava-as no teu coração.

4Assim acharás o favor de Deus e a consideração dos homens.

5Confia no Senhor de todo o teu coração

e nunca em ti mesmo.

6Em tudo o que fizeres, põe Deus em primeiro lugar,

e ele te dirigirá nos teus caminhos.

7Não te consideres sábio aos teus próprios olhos;

teme o Senhor e volta as costas ao mal.

8Quando assim fizeres, gozarás saúde e vitalidade.

9Honra o Senhor com os teus ganhos,

com a primeira parte dos teus rendimentos;

10e ele encherá, a transbordar, os teus celeiros;

correrão abundantes os teus vinhos, dos mais finos.

11Meu filho, não desprezes a correção do Senhor

e não desanimes quando ele te mostrar que estás errado.

12Porque o Senhor repreende quem ama,

tal como um pai corrige um filho a quem quer muito bem.

13A pessoa que acha a sabedoria,

que adquire a capacidade de avaliar o certo e o errado, essa é feliz.

14Porque isso é melhor do que grandes riquezas;

a sabedoria vale mais do que ouro.

15É mais preciosa do que pérolas;

nada se lhe pode comparar.

16A sabedoria, por um lado, dá-te uma longa vida;

por outro, dá-te riquezas e honra.3.16 Uma tradução literal deste verso seria algo como: O alongar da vida está na tua mão direita; na tua esquerda, riquezas e honra.

17Os seus caminhos dão felicidade e paz.

18É uma árvore de vida, para os que a alcançam;

felizes são os que se apegam a ela.

19Foi com essa sabedoria que o Senhor firmou a Terra;

com a sua inteligência estabeleceu os céus;

20pelo seu conhecimento, as profundas fontes da Terra abrem-se

e as nuvens gotejam.

21Meu filho, nunca deixes de ter estes dois objetivos:

fazer o que é reto e ter bom senso.

22Porque serão para ti fonte de vida,

como joias que adornam o teu pescoço.

23Então andarás com segurança

e sem risco de tropeçares.

24Poderás deitar-te e adormecer sossegadamente.

25Não terás que recear catástrofes repentinas,

nem a desgraça causada pelos malfeitores.

26Porque o Senhor será a tua segurança;

guardará os teus pés de ficarem presos.

27Não te atrases a fazer o bem que deves a alguém,

se nada te impedir disso.

28Não digas: “Olha, fica para outra vez!”,

se puderes pagar-lhe logo na ocasião.

29Não trames o mal contra o teu próximo,

pois confia em ti.

30Não entres em disputas inúteis,

particularmente com pessoas que nunca te fizeram mal.

31Não tenhas inveja de gente violenta nem a imites.

32Porque o Senhor tem horror a pessoas assim,

mas quer na sua intimidade os que andam retamente.

33A casa do perverso está sob a maldição do Senhor,

mas os retos beneficiam da sua bênção.

34Ele rir-se-á dos que fazem troça de tudo,

mas favorecerá os humildes.

35Os que têm sabedoria adquirem honra,

mas os insensatos obtêm para si desonra.