Isaya 43 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Isaya 43:1-28

Mwokozi Pekee Wa Israeli

143:1 Mwa 2:7; 32:28; Isa 45:3-4; Kut 6:6; Isa 42:6; 27:11; Ay 19:25Lakini sasa hili ndilo asemalo Bwana,

yeye aliyekuumba, ee Yakobo,

yeye aliyekuhuluku, ee Israeli:

“Usiogope kwa maana nimekukomboa,

nimekuita wewe kwa jina lako, wewe u wangu.

243:2 Mwa 26:3; Kum 31:6-8; Isa 30:27; 8:7; Dan 3:25-27; Kut 14:22; Isa 29:6Unapopita kwenye maji makuu,

nitakuwa pamoja nawe,

unapopita katika mito ya maji,

hayatakugharikisha.

Utakapopita katika moto,

hutaungua,

miali ya moto haitakuunguza.

343:3 Mit 21:18; Kut 30:2; Isa 20:3; Mwa 10:7; Eze 29:20; Za 68:31; Amu 2:18; Kut 14:30Kwa kuwa Mimi ndimi Bwana, Mungu wako,

yeye Aliye Mtakatifu wa Israeli, Mwokozi wako.

Ninaitoa Misri kuwa fidia yako,

Kushi na Seba badala yako.

443:4 Isa 63:9; Ufu 3:9; Kut 19:5-6; Isa 49:5Kwa kuwa wewe ni wa thamani na wa kuheshimiwa machoni pangu,

nami kwa kuwa ninakupenda,

nitatoa watu badala yako

na mataifa badala ya maisha yako.

543:5 Isa 44:2; Mwa 21:22; Kut 14:22; Mdo 18:10; Yer 30:10-11; Mt 8:11; Zek 8:7; Isa 24:14Usiogope, kwa kuwa mimi nipo pamoja nawe,

nitawaleta watoto wako kutoka mashariki,

na kukukusanya kutoka magharibi.

643:6 Eze 16:61; 2Kor 6:18; Eze 36:24; Yer 23:8; Kum 30:4; Isa 60:4; 11:12Nitaiambia kaskazini, ‘Watoe!’

nayo kusini, ‘Usiwazuie.’

Walete wana wangu kutoka mbali,

na binti zangu kutoka miisho ya dunia:

743:7 Yak 2:7; Isa 29:23; Yer 15:16; Efe 2:10; Isa 56:5; 62:2; 63:19; Za 89:9kila mmoja ambaye ameitwa kwa Jina langu,

niliyemuumba kwa utukufu wangu,

niliyemhuluku na kumfanya.”

843:8 Isa 6:9-10; 42:20; Eze 12:2Uwaongoze wale wenye macho lakini hawaoni,

wenye masikio lakini hawasikii.

943:9 Isa 45:20; 48:14; 41:26Mataifa yote yanakutanika pamoja,

na makabila yanakusanyika.

Ni nani miongoni mwao aliyetangulia kutuambia haya,

na kututangazia mambo yaliyopita?

Walete mashahidi wao ili kuwathibitisha kuwa walikuwa sahihi,

ili wengine waweze kusikia, waseme, “Ni kweli.”

1043:10 Isa 41:8-9; 19:21; Za 86:10; Yer 14:22; Yos 24:22; Kum 4:35; Isa 45:5-6, 14“Ninyi ni mashahidi wangu,” asema Bwana,

“na mtumishi wangu niliyemchagua,

ili mpate kunijua na kuniamini,

na kutambua kwamba Mimi ndiye.

Kabla yangu hakuna mungu aliyefanyizwa,

wala hatakuwepo mwingine baada yangu.

1143:11 Isa 42:8; Za 18:31; Isa 25:9; 63:4; Kut 6:2Mimi, naam mimi, ndimi Bwana,

zaidi yangu hakuna mwokozi.

1243:12 Kum 32:16; Za 81:9; Isa 44:8Nimedhihirisha, kuokoa na kutangaza:

Mimi, wala si mungu mgeni katikati yenu.

Ninyi ni mashahidi wangu,” asema Bwana,

“kwamba Mimi ndimi Mungu.

1343:13 Hes 23:8; Ay 9:12; Za 90:2; Mit 8:23; Kum 32:39; Isa 48:12Naam, tangu siku za kale, Mimi ndiye.

Hakuna hata mmoja awezaye kuokoa

kutoka mkononi wangu.

Mimi ninapotenda,

ni nani awezaye kutangua?”

Huruma Za Mungu, Na Kukosa Uaminifu Kwa Israeli

1443:14 Isa 13:14-15; 23:13; Kut 15:13; Ay 19:25; Isa 41:20Hili ndilo Bwana asemalo,

Mkombozi wako, yeye Aliye Mtakatifu wa Israeli:

“Kwa ajili yenu nitatumana Babeli

na kuwaleta Wakaldayo wote kama wakimbizi,

katika meli walizozionea fahari.

1543:15 Isa 42:8; 27:11; 45:11; 41:21Mimi ndimi Bwana, yeye Aliye Mtakatifu wako,

Muumba wa Israeli, Mfalme wako.”

1643:16 Kut 14:29; Za 77:19; Kut 15:8; Isa 11:15Hili ndilo asemalo Bwana,

yeye aliyefanya njia baharini,

mahali pa kupita kwenye maji mengi,

1743:17 Za 118:12; Kut 14:4-9, 22; Za 76:5-6; Ay 13:25; Yer 51:21; Eze 38:4aliyeyakokota magari ya vita na farasi,

jeshi pamoja na askari wa msaada,

nao wakalala huko, wala hawatainuka tena kamwe,

wakakomeshwa, na wakazimika kama utambi:

1843:18 Isa 41:22“Msiyakumbuke mambo yaliyopita,

wala msiyatafakari mambo ya zamani.

1943:19 Hes 20:11; Yer 23:8-9; Ufu 21:5; Isa 40:3; 41:22; Yer 16:14-15; 2Kor 5:17; Isa 35:7Tazama, nitafanya jambo jipya!

Sasa litachipuka, je, hamtalitambua?

Nitafanya njia jangwani

na vijito vya maji katika nchi kame.

2043:20 Hes 20:8; Isa 48:21; 41:17; Za 148:10; Isa 13:22Wanyama wa mwituni wataniheshimu,

mbweha na bundi,

kwa sababu ninawapatia maji jangwani,

na vijito katika nchi kame,

ili kuwapa watu wangu maji, wale niliowachagua,

2143:21 Za 66:2; 1Pet 2:9; Mwa 2:7; Mal 3:17; Za 102:18watu wale niliowaumba kwa ajili yangu,

ili wapate kutangaza sifa zangu.

22“Hata hivyo hukuniita mimi, ee Yakobo,

hujajitaabisha kwa ajili yangu, ee Israeli.

2343:23 Zek 7:5-6; Kut 30:35; Yer 7:22; Amo 5:25; Kut 29:41; Mik 6:3; Mal 1:12-13Hujaniletea kondoo kwa ajili ya sadaka za kuteketezwa,

wala kuniheshimu kwa dhabihu zako.

Sikukulemea kwa sadaka za nafaka

wala kukuchosha kwa kuhitaji uvumba.

2443:24 Kut 30:23; Mal 2:17; Isa 7:13; Yer 8:21; Law 3:9; Yer 44:22Hukuninunulia uvumba wowote wenye manukato,

wala hukunipa kwa ukarimu

mafuta ya wanyama wa dhabihu zako.

Lakini umenilemea kwa dhambi zako,

na kunitaabisha kwa makosa yako.

2543:25 2Sam 12:13; Lk 5:21; Eze 20:44; Yer 31:34; Ay 7:21; 2Nya 6:21; Isa 64:9“Mimi, naam mimi, ndimi nizifutaye dhambi zako,

kwa ajili yangu mwenyewe,

wala sizikumbuki dhambi zako tena.

2643:26 Isa 1:18; 41:1; 49:25; 50:8Tafakari mambo yaliyopita,

njoo na tuhojiane,

leta shauri lako uweze kupewa haki yako.

2743:27 Rum 5:12; Isa 28:7; Yer 5:31; Mwa 12:18; Isa 9:15; 24:20Baba yako wa kwanza alitenda dhambi,

wasemaji wako wameasi dhidi yangu.

2843:28 Eze 5:15; Za 39:8; Hes 5:27; Kum 13:15; Isa 42:24; Zek 5:3; Yer 24:9Kwa hiyo nitawaaibisha wakuu wa Hekalu lako,

nami nitamtoa Yakobo aangamizwe,

na Israeli adhihakiwe.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 43:1-28

Olùgbàlà Israẹli kan ṣoṣo

1Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, ohun tí Olúwa wí nìyìí

ẹni tí ó dá ọ, ìwọ Jakọbu

ẹni tí ó mọ ọ́, Ìwọ Israẹli:

“Má bẹ̀rù, nítorí Èmi ti dá ọ nídè;

Èmi ti pè ọ́ ní orúkọ; tèmi ni ìwọ ṣe.

2Nígbà tí ìwọ bá ń la omi kọjá,

Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ;

àti nígbà tí ìwọ bá ń la odò kọjá

wọn kì yóò bò ọ́ mọ́lẹ̀.

Nígbà tí ìwọ bá la iná kọjá,

kò ní jó ọ;

ahọ́n iná kò ní jó ọ lára.

3Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,

Ẹni Mímọ́ Israẹli Olùgbàlà rẹ;

Èmi fi Ejibiti ṣe ìràpadà rẹ,

Kuṣi àti Seba dípò rẹ.

4Nítorí pé o ṣe iyebíye àti ọ̀wọ́n níwájú mi,

àti nítorí pé mo fẹ́ràn rẹ,

Èmi yóò fi ènìyàn rọ́pò fún ọ,

àti ènìyàn dípò ẹ̀mí rẹ.

5Má bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ;

Èmi yóò mú àwọn ọmọ rẹ láti ìlà-oòrùn wá

èmi ó sì kó ọ jọ láti ìwọ̀-oòrùn.

6Èmi yóò sọ fún àríwá pé, ‘Fi wọ́n sílẹ̀!’

Àti fún gúúsù, ‘Má ṣe dá wọn dúró.’

Mú àwọn ọmọkùnrin mi láti ọ̀nà jíjìn wá

àti àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin mi láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé—

7ẹnikẹ́ni tí a ń pe orúkọ mi mọ́,

tí mo dá fún ògo mi,

tí mo mọ̀ àti tí mo ṣe.”

8Sin àwọn tí ó ní ojú ṣùgbọ́n tí wọ́n fọ́jú jáde,

tí wọ́n ní etí ṣùgbọ́n tí wọn dití.

9Gbogbo orílẹ̀-èdè kó ra wọn jọ

àwọn ènìyàn sì kó ra wọn papọ̀.

Ta ni nínú wọn tó sọ àsọtẹ́lẹ̀ yìí

tí ó sì kéde fún wa àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀?

Jẹ́ kí wọ́n mú àwọn ẹlẹ́rìí wọn wọlé wá

láti fihàn pé wọ́n tọ̀nà

tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn mìíràn yóò gbọ́, tí

wọn yóò sọ pé, “Òtítọ́ ni.”

10“Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí,

“Àti ìránṣẹ́ mi tí èmi ti yàn,

tó bẹ́ẹ̀ tí ẹ̀yin yóò fi mọ̀ àti tí ẹ̀yin ó fi gbà mí gbọ́

tí yóò sì yé e yín pé èmi ni ẹni náà.

Ṣáájú mi kò sí ọlọ́run tí a dá,

tàbí a ó wa rí òmíràn lẹ́yìn mi.

11Èmi, àní Èmi, Èmi ni Olúwa,

yàtọ̀ sí èmi, kò sí olùgbàlà mìíràn.

12Èmi ti fihàn, mo gbàlà mo sì ti kéde

Èmi, kì í sì í ṣe àwọn àjèjì òrìṣà láàrín yín.

Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Pé Èmi ni Ọlọ́run.

13Bẹ́ẹ̀ ni, àti láti ayérayé Èmi ni ẹni náà.

Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ mi.

Nígbà tí mo bá ṣe nǹkan, ta ni ó lè yí i padà?”

Àánú Ọlọ́run àti àìṣòdodo Israẹli

14Èyí ni ohun tí Olúwa

olùràpadà rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli;

“Nítorí rẹ Èmi yóò ránṣẹ́ sí Babeli

láti mú wọn sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá,

gbogbo ará Babeli

nínú ọkọ̀ ojú omi nínú èyí tí wọ́n fi ń ṣe ìgbéraga.

15Èmi ni Olúwa, Ẹni Mímọ́ rẹ,

Ẹlẹ́dàá Israẹli, ọba rẹ.”

16Èyí ni ohun tí Olúwa

Ẹni náà tí ó la ọ̀nà nínú Òkun,

ipa ọ̀nà láàrín alagbalúgbú omi,

17ẹni tí ó wọ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jáde,

àwọn jagunjagun àti ohun ìjà papọ̀,

wọ́n sì sùn síbẹ̀, láìní lè dìde mọ́,

wọ́n kú pirá bí òwú-fìtílà:

18“Gbàgbé àwọn ohun àtẹ̀yìnwá;

má ṣe gbé nínú ohun àtijọ́.

19Wò ó, Èmi ń ṣe ohun tuntun!

Nísinsin yìí ó ti yọ sókè; àbí o kò rí i bí?

Èmi ń ṣe ọ̀nà kan nínú aṣálẹ̀

àti odò nínú ilẹ̀ ṣíṣá.

20Àwọn ẹhànnà ẹranko bọ̀wọ̀ fún mi,

àwọn ajáko àti àwọn òwìwí,

nítorí pé mo pèsè omi nínú aṣálẹ̀

àti odò nínú ilẹ̀ sísá,

láti fi ohun mímu fún àwọn ènìyàn mi, àyànfẹ́ mi,

21àwọn ènìyàn tí mo dá fún ara mi

kí wọn kí ó lè kéde ìyìn mi.

22“Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò tí ì ké pè mí,

ìwọ Jakọbu,

àárẹ̀ kò tí ì mú ọ nítorí mi

ìwọ Israẹli.

23Ìwọ kò tí ì mú àgùntàn wá fún mi fún ẹbọ sísun,

tàbí kí o bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ẹbọ rẹ.

Èmi kò tí ì wàhálà rẹ pẹ̀lú ọrẹ ìyẹ̀fun

tàbí kí n dààmú rẹ pẹ̀lú ìbéèrè fún tùràrí.

24Ìwọ kò tí ì ra kalamusi olóòórùn dídùn fún mi,

tàbí kí o da ọ̀rá ẹbọ rẹ bò mí.

Ṣùgbọ́n ẹ ti wàhálà mi pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀ yín

ẹ sì ti dààmú mi pẹ̀lú àìṣedéédéé yín.

25“Èmi, àní Èmi, Èmi ni ẹni tí ó wẹ

àwọn àìṣedéédéé rẹ nù, nítorí èmi fún ara mi,

tí n kò sì rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ mọ́.

26Bojú wo ẹ̀yìn rẹ fún mi,

jẹ́ kí a jọ ṣe àríyànjiyàn ọ̀rọ̀ náà papọ̀;

ro ẹjọ́ láti fihàn pé o kò lẹ́sẹ̀ lọ́rùn.

27Baba yín àkọ́kọ́ dẹ́ṣẹ̀;

àwọn agbẹnusọ yín ṣọ̀tẹ̀ sí mi.

28Nítorí náà, èmi ti sọ àwọn olórí ibi mímọ́ náà di àìmọ́,

bẹ́ẹ̀ ni èmi ti fi Jakọbu fún ègún

àti Israẹli fún ẹ̀gàn.