Isaya 42 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Isaya 42:1-25

Mtumishi Wa Bwana

142:1 Isa 49:3-6; 14:1; Yn 3:34; Lk 9:35; Mwa 49:10; Mt 3:16-17; 20:28“Huyu hapa mtumishi wangu, ninayemtegemeza,

mteule wangu, ambaye ninapendezwa naye;

nitaweka Roho yangu juu yake,

naye ataleta haki kwa mataifa.

242:2 Za 8:1-4Hatapaza sauti wala kupiga kelele,

wala hataiinua sauti yake barabarani.

342:3 Za 72:2; Mt 12:17-21; Za 96:13; Isa 36:6; Ay 30:24; 13:25Mwanzi uliopondeka hatauvunja,

na utambi unaofuka moshi hatauzima.

Kwa uaminifu ataleta haki,

442:4 Mwa 49:10; Ebr 12:2; Rum 8:22-25; Kut 34:29; Isa 51:4; 11:11hatazimia roho wala kukata tamaa,

mpaka atakaposimamisha haki juu ya dunia.

Visiwa vitaweka tumaini lao katika sheria yake.”

542:5 Za 24:2; Mdo 17:24-25; Isa 44:24; 48:13; Za 102:25Hili ndilo asemalo Mungu, Bwana,

yeye aliyeziumba mbingu na kuzitanda,

aliyeitandaza dunia na vyote vitokavyo humo,

awapaye watu wake pumzi,

na uzima kwa wale waendao humo:

642:6 Kut 31:2; Amu 4:10; Yer 23:6; Mdo 13:47; Dan 9:7; Isa 26:18; Lk 22:20“Mimi, Bwana, nimekuita katika haki;

nitakushika mkono wako.

Nitakulinda na kukufanya

kuwa Agano kwa ajili ya watu

na nuru kwa Mataifa,

742:7 Zek 9:11; 2:7; 2Tim 2:26; Lk 4:19; Mt 11:5; Isa 32:3; 51:14; Za 146:8kuwafungua macho wale wasioona,

kuwaacha huru kutoka kifungoni waliofungwa jela,

na kuwafungua kutoka gerezani

wale wanaokaa gizani.

842:8 Kut 3:14-15; 6:3; Isa 48:11; Za 81:10; Ebr 2:14-15; Kut 8:10; Isa 46:9“Mimi ndimi Bwana; hilo ndilo Jina langu!

Sitampa mwingine utukufu wangu

wala sanamu sifa zangu.

942:9 Isa 41:22; 40:21; Eze 2:4Tazama, mambo ya kwanza yametokea,

nami natangaza mambo mapya;

kabla hayajatokea

nawatangazia habari zake.”

Wimbo Wa Kumsifu Bwana

1042:10 Za 98:1; Kum 30:4; Za 96:11; 1Fal 10:9; 1Nya 16:32; Za 48:10; Isa 11:11Mwimbieni Bwana wimbo mpya,

sifa zake toka miisho ya dunia,

ninyi mshukao chini baharini,

na vyote vilivyomo ndani yake,

enyi visiwa na wote wakaao ndani yake.

1142:11 Mwa 25:13; Isa 32:16; 52:7; Nah 1:15; Isa 60:7; Amu 1:36Jangwa na miji yake na vipaze sauti zao;

makao anamoishi Kedari na yashangilie.

Watu wa Sela waimbe kwa furaha,

na wapige kelele kutoka vilele vya milima.

1242:12 Isa 24:15; 1Nya 16:24; 1Pet 2:9; Za 26:7; 66:2Wampe Bwana utukufu,

na kutangaza sifa zake katika visiwa.

1342:13 Isa 9:6; Yos 6:5; Yoe 3:16; Isa 66:14; 26:11; Kut 14:14; Hos 11:10Bwana ataenda kama mtu mwenye nguvu,

kama shujaa atachochea shauku yake,

kwa kelele ataamsha kilio cha vita,

naye atashinda adui zake.

1442:14 Es 4:14; Yer 4:31; Mwa 43:31; Lk 18:7“Kwa muda mrefu nimenyamaza kimya,

nimekaa kimya na kujizuia.

Lakini sasa, kama mwanamke wakati wa kujifungua,

ninapiga kelele, ninatweta na kushusha pumzi.

1542:15 Eze 38:20; Za 107:33; Isa 11:15; 50:2; Nah 1:4-6Nitaharibu milima na vilima

na kukausha mimea yako yote;

nitafanya mito kuwa visiwa

na kukausha mabwawa.

1642:16 Kum 4:31; Ebr 13:5; Yer 31:8-9; Isa 26:7; 29:24; 57:18; Mdo 26:18; Ebr 13:5Nitawaongoza vipofu kwenye njia ambayo hawajaijua,

kwenye mapito wasiyoyazoea nitawaongoza;

nitafanya giza kuwa nuru mbele yao,

na kufanya mahali palipoparuza kuwa laini.

Haya ndiyo mambo nitakayofanya;

mimi sitawaacha.

1742:17 Kut 32:4; Za 97:7; Isa 1:26Lakini wale wanaotumaini sanamu,

wanaoviambia vinyago, ‘Ninyi ndio miungu yetu,’

watarudishwa nyuma kwa aibu kubwa.

Israeli Kipofu Na Kiziwi

18“Sikieni, enyi viziwi;

tazameni, enyi vipofu, mpate kuona!

1942:19 Isa 43:8; Eze 12:2; Isa 41:8-9; Hag 1:13; Isa 26:3Ni nani aliye kipofu isipokuwa mtumishi wangu,

na kiziwi kama mjumbe ninayemtuma?

Ni nani aliye kipofu kama yeye aliyejitoa kwangu,

aliye kipofu kama mtumishi wa Bwana?

2042:20 Isa 6:9-10; Yer 5:21; Rum 2:21; Yer 6:10; Isa 48:21; 41:17Mmeona vitu vingi, lakini hamkuzingatia;

masikio yenu yako wazi, lakini hamsikii chochote.”

2142:21 2Kor 3:7; Isa 43:25Ilimpendeza Bwana

kwa ajili ya haki yake

kufanya sheria yake kuwa kuu na tukufu.

2242:22 Isa 24:18-22; Lk 19:41-44; Amu 6:4; 2Fal 24:13; Isa 5:29; Za 66:11; Yos 22:5; Isa 1:14; 30:11Lakini hili ni taifa lililoibwa na kutekwa nyara,

wote wamenaswa katika mashimo,

au wamefichwa katika magereza.

Wamekuwa nyara,

wala hapana yeyote awaokoaye.

Wamefanywa mateka,

wala hapana yeyote asemaye, “Warudishe.”

2342:23 Kum 32:29; Za 81:13; Isa 47:7; 48:18; 57:11Ni nani miongoni mwenu atakayesikiliza hili,

au atakayezingatia kwa makini katika wakati ujao?

2442:24 2Fal 17:6; Isa 43:28; 10:5-6Ni nani aliyemtoa Yakobo kuwa mateka,

na Israeli kwa wateka nyara?

Je, hakuwa yeye, Bwana,

ambaye tumetenda dhambi dhidi yake?

Kwa kuwa hawakufuata njia zake,

hawakutii sheria zake.

2542:25 Hos 7:9; Nah 1:6; 2Fal 22:13; Ay 40:11; Eze 7:19; 2Fal 25:9; Isa 29:13Hivyo akawamwagia hasira yake inayowaka,

ukali wa vita.

Iliwazunguka kwa miali ya moto, lakini hata hivyo hawakuelewa;

iliwateketeza, lakini hawakuyatia moyoni.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 42:1-25

Ìránṣẹ́ Olúwa náà

142.1-4: Mt 12.18-21.“Ìránṣẹ́ mi nìyìí, ẹni tí mo gbéró,

àyànfẹ́ mi nínú ẹni tí mo láyọ̀;

Èmi yóò fi Ẹ̀mí mi sínú rẹ̀

òun yóò sì mú ìdájọ́ wá sórí àwọn orílẹ̀-èdè.

2Òun kì yóò pariwo tàbí kígbe sókè,

tàbí kí ó gbóhùn rẹ̀ sókè ní òpópónà.

3Koríko odò títẹ̀ kan ni òun kì yóò fọ́,

àti òwú-fìtílà tí ń jó tan an lọ lòun kì yóò fẹ́ pa.

Ní òdodo ni yóò mú ìdájọ́ wá;

4òun kì yóò kọsẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò ní rẹ̀wẹ̀sì

títí tí yóò fi fi ìdájọ́ múlẹ̀ ní ayé.

Nínú òfin rẹ̀ ni àwọn erékùṣù yóò fi ìrètí wọn sí.”

542.5: Ap 17.24-25.Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wí

Ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run tí ó sì tẹ́ wọ́n sóde,

tí ó tẹ́ ilẹ̀ ayé àti ohun gbogbo tí ó jáde nínú wọn,

Ẹni tí ó fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ní èémí

àti ẹ̀mí fún gbogbo àwọn tí ń rìn nínú rẹ̀:

642.6: Isa 49.6; Lk 2.32; Ap 13.47; 26.23.“Èmi, Olúwa, ti pè ọ́ ní òdodo;

Èmi yóò di ọwọ́ rẹ mú.

Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́

láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn

àti ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà

742.7,16: Ap 26.18.láti la àwọn ojú tí ó fọ́,

láti tú àwọn òǹdè kúrò nínú túbú

àti láti tú sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n

àwọn tí ó jókòó nínú òkùnkùn.

8“Èmi ni Olúwa; orúkọ mi nìyìí!

Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn

tàbí ìyìn mi fún ère òrìṣà.

9Kíyèsi i, àwọn nǹkan àtijọ́ ti wáyé,

àti àwọn nǹkan tuntun ni mo ti wí pé;

kí wọn tó hù jáde

mo ti kéde rẹ̀ fún ọ.”

Orin ìyìn sí Olúwa

10Kọ orin tuntun sí Olúwa

ìyìn rẹ̀ láti òpin ilẹ̀ ayé wá,

ẹ̀yin tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú Òkun, àti

ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀

ẹ̀yin erékùṣù, àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú wọn.

11Jẹ́ kí aginjù àti àwọn ìlú rẹ̀ kí ó gbé ohùn wọn sókè;

jẹ́ kí ibùdó ti àwọn igi Kedari ń gbé máa yọ̀.

Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Sela kọrin fún ayọ̀;

jẹ́ kí wọn pariwo láti orí òkè.

12Jẹ́ kí wọn fi ògo fún Olúwa

àti kí wọn sì kéde ìyìn rẹ̀ ní erékùṣù.

13Olúwa yóò rìn jáde gẹ́gẹ́ bí i ọkùnrin alágbára,

yóò ru owú sókè bí ológun;

yóò kígbe nítòótọ́, òun yóò ké igbe ogun,

òun yóò sì ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá rẹ̀.

14“Fún ìgbà pípẹ́ ni mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́,

mo ti wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, mo sì kó ara ró.

Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí,

mo sọkún, mo sì ń mí hẹlẹ hẹlẹ.

15Èmi yóò sọ òkè ńlá àti kékeré di ahoro

tí n ó sì gbẹ gbogbo ewéko rẹ̀ dànù;

Èmi yóò sọ àwọn odò di erékùṣù

n ó sì gbẹ àwọn adágún.

16Èmi yóò tọ àwọn afọ́jú ní ọ̀nà tí wọn kò tí ì mọ̀,

ní ipa ọ̀nà tí ó ṣàjèjì sí wọn ni èmi yóò tọ́ wọn lọ;

Èmi yóò sọ òkùnkùn di ìmọ́lẹ̀ níwájú wọn

àti ibi pálapàla ni èmi ó sọ di kíkúnná.

Àwọn nǹkan tí máa ṣe nìyìí;

Èmi kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.

17Ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé òrìṣà,

tí wọ́n wí fún ère pé, ‘Ẹ̀yin ni Ọlọ́run wa,’

ni a ó dá padà pẹ̀lú ìtìjú.

Israẹli fọ́jú ó dití

18“Gbọ́, ìwọ adití,

wò ó, ìwọ afọ́jú, o sì rí!

19Ta ló fọ́jú bí kò ṣe ìránṣẹ́ mi,

àti odi gẹ́gẹ́ bí oníṣẹ́ tí mo rán?

Ta ni ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ẹni tí a fi jìnmí,

ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ Olúwa?

20Ẹ̀yin ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan, ṣùgbọ́n ẹ kò ṣe àkíyèsí;

etí yín yà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́ nǹkan kan.”

21Ó dùn mọ́ Olúwa

nítorí òdodo rẹ̀

láti mú òfin rẹ lágbára àti ògo.

22Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn kan nìyìí tí a jà lógun

tí a sì kó lẹ́rú,

gbogbo wọn ni ó wà nínú ọ̀gbun,

tàbí tí a fi pamọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.

Wọ́n ti di ìkógun,

láìsí ẹnìkan tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀;

wọ́n ti di ìkógun,

láìsí ẹni tí yóò sọ pé, “Dá wọn padà.”

23Ta ni nínú yín tí yóò tẹ́tí sí èyí

tàbí kí ó ṣe àkíyèsí gidi ní àsìkò tí ó ń bọ̀?

24Ta ni ó fi Jakọbu lélẹ̀ fún ìkógun,

àti Israẹli sílẹ̀ fún onísùnmọ̀mí?

Kì í ha ṣe Olúwa ni,

ẹni tí àwa ti ṣẹ̀ sí?

Nítorí pé wọn kò ní tẹ̀lé ọ̀nà rẹ̀;

wọn kò mú òfin rẹ̀ ṣẹ.

25Nítorí náà ni ó ṣe rọ̀jò ìbínú un rẹ̀ lé wọn lórí,

rògbòdìyàn ogun.

Èyí tí ó fi ahọ́n iná yí wọn po, síbẹ̀

èdè kò yé wọn;

ó jó wọn run, síbẹ̀ wọn kò fi sọ́kàn wọn rárá.