ኢሳይያስ 57 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢሳይያስ 57:1-21

1ጻድቅ ይሞታል፤

ይህን ግን ማንም ልብ አይልም፤

ለእግዚአብሔር ያደሩ ሰዎች ይወሰዳሉ፤

ጻድቃን ከክፉ ይድኑ ዘንድ፣

መወሰዳቸውን፣

ማንም አያስተውልም።

2በቅንነት የሚሄዱ፣

ሰላም ይሆንላቸዋል፤

መኝታቸው ላይ ያርፋሉ።

3“እናንት የአስማተኛዪቱ ልጆች ግን፣

እናንት የአመንዝራውና የጋለሞታዪቱ ዘር፤ እናንት፣ ወዲህ ኑ፤

4የምትሣለቁት በማን ላይ ነው?

የምታሽሟጥጡት ማንን ነው?

ምላሳችሁንስ አውጥታችሁ የምታሾፉት በማን ላይ ነው?

እናንት የዐመፀኞች ልጆች፣

የሐሰተኞች ዘር አይደላችሁምን?

5በባሉጥ ዛፎች መካከል፣

ቅጠሉ በተንዠረገገ ዛፍ ሥር በዝሙት የምትቃጠሉ፣

በሸለቆዎች፣ በዐለት ስንጣቂዎችም ውስጥ

ልጆቻችሁን የምትሠዉ አይደላችሁምን?

6በሸለቆው በሚገኙት ለስላሳ ድንጋዮች

ውስጥ ያሉት ጣዖቶች የአንቺ ናቸው፤

እነርሱም ዕጣ ፈንታዎችሽ ናቸው፤

ርግጥ ነው፣ በእነርሱ ላይ የመጠጥ ቍርባን አፍስሰሻል፤

የእህል ቍርባንም አቅርበሻል፤

ታዲያ፣ ስለ እነዚህ ነገሮች ዝም እላለሁን?

7ዐልጋሽን ከፍ ባለውና በረጅሙ ኰረብታ ላይ አነጠፍሽ፤

በዚያም መሥዋዕትሽን ልታቀርቢ ወጣሽ።

8ከመዝጊያሽና ከመቃንሽ ጀርባ፣

የጣዖት ምስሎችሽን ሰቀልሽ፤

እኔን ትተሽ መኝታሽን ገላለጥሽ፤

በላይም ወጥተሽ በጣም ገለጥሽው፤

መኝታቸውን ከወደድሽላቸው ጋር ስምምነት አደረግሽ፤

ዕርቃናቸውንም አየሽ።

9የወይራ ዘይት ይዘሽ፣

ሽቶ በላዩ ጨምረሽ ወደ ሞሎክ57፥9 ወይም ወደ ንጉሡ ሄድሽ፤

መልእክተኞችሽን57፥9 ወይም፣ ጣዖቶችሽን ወደ ሩቅ አገር ላክሽ፤

እስከ ራሱ እስከ ሲኦልም ዘለቅሽ።

10በመንገድ ብዛት ደከምሽ፤

ነገር ግን ‘ተስፋ የለውም’ አላልሽም፤

የጕልበት መታደስ አገኘሽ፤

ስለዚህም አልዛልሽም።

11“እኔን የዋሸሽኝ፤

ማንን ፈርተሽ፣ ማንንስ ሠግተሽ ነው?

እኔን ያላስታወስሽው፣

ይህንም በልብሽ ያላኖርሽው፣

እኔን ያልፈራሽው፣

ዝም ስላልሁ አይደለምን?

12ጽድቅሽንና ሥራሽን አጋልጣለሁ፤

እነርሱም አይጠቅሙሽም።

13ለርዳታ በምትጮኺበት ጊዜ፣

የሰበሰብሻቸው ጣዖቶች እስቲ ያድኑሽ!

ነፋስ ጠራርጎ ይወስዳቸዋል፤

ሽውሽውታም ይበትናቸዋል።

እኔን መጠጊያው ያደረገ ሰው ግን፣

ምድሪቱን ይወርሳል፤

የተቀደሰ ተራራዬንም ገንዘቡ ያደርገዋል።”

ልባቸው ለተሰበረ መጽናናት

14እንዲህ ይባላል፤

“አብጁ፤ አብጁ፤ መንገድ አዘጋጁ፤

ከሕዝቤ መንገድ ዕንቅፋት አስወግዱ።”

15ከፍ ከፍ ያለውና ልዕልና ያለው እርሱ፣

ስሙም ቅዱስ የሆነው፣ ለዘላለም የሚኖረው እንዲህ ይላል፤

“የተዋረዱትን መንፈሳቸውን ለማነሣሣት፣

የተሰበረ ልብ ያላቸውን ለማነቃቃት፣

ከፍ ባለውና በቅዱሱ ስፍራ እኖራለሁ፤

የተሰበረ ልብ ካለውና በመንፈሱ ከተዋረደው ጋር እሆናለሁ።

16የሰው መንፈስ በፊቴ እንዳይዝል፣

የፈጠርሁትም ሰው እስትንፋስ እንዳይቆም፣

ለዘላለም አልወቅሥም፤

ሁልጊዜም አልቈጣም።

17ኀጢአት ስለ ሞላበት ስግብግብነቱ ተቈጣሁት፤

ቀጣሁት፤ ፊቴንም በቍጣ ከእርሱ ሸሸግሁ፤

ያም ሆኖ በገዛ መንገዱ ገፋበት።

18መንገዶቹን አይቻለሁ፤ ቢሆንም እፈውሰዋለሁ፤

እመራዋለሁ፤ ለእርሱና ስለ እርሱ ለሚያለቅሱትም

መጽናናትን እመልሳለሁ፤

19በእስራኤል አልቃሾች ከንፈር ላይ ምስጋና እፈጥራለሁ።

በቅርብና በሩቅ ላሉት ሰላም፣ ሰላም ይሁን፤

እኔ እፈውሳቸዋለሁ” ይላል እግዚአብሔር

20ክፉዎች ግን ማዕበሉ ጭቃና ጕድፍ እንደሚያወጣ፣

ጸጥ ማለት እንደማይችል፣

እንደሚናወጥ ባሕር ናቸው።

21አምላኬ፣ “ለክፉዎች ሰላም የላቸውም” ይላል።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 57:1-21

1Olódodo ṣègbé

kò sí ẹnìkan tí ó rò ó lọ́kàn ara rẹ̀;

a mú àwọn ẹni mímọ́ lọ,

kò sì ṣí ẹni tó yé

pé a ti mú àwọn olódodo lọ

láti yọ wọ́n kúrò nínú ibi.

2Gbogbo àwọn tí ń rìn déédé

ń wọ inú àlàáfíà;

wọ́n rí ìsinmi bí wọ́n ti ń sùn nínú ikú.

3“Ṣùgbọ́n ẹ súnmọ́ ìhìn-ín, ẹ̀yin ọmọ aláfọ̀ṣẹ,

ẹ̀yin irú-ọmọ panṣágà àti àgbèrè!

4Ta ni ó fi ń ṣẹlẹ́yà?

Ta ni o ń yọ ṣùtì sí

tí o sì yọ ahọ́n síta?

Ẹ̀yin kì í ha ṣe ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn bí,

àti ìran àwọn òpùrọ́?

5Ẹ gbinájẹ fún ìṣekúṣe láàrín igi óákù

àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀;

ẹ fi àwọn ọmọ yín rú ẹbọ nínú kòtò jíjìn

àti lábẹ́ àwọn pàlàpálá òkúta.

6Àwọn ère tí ó wà ní àárín òkúta dídán

wọ́n n nì, nínú kòtò jíjìn ni ìpín in yín;

àwọ̀n ni ìpín in yín.

Bẹ́ẹ̀ ni, sí wọn ni ẹ ti ta ọrẹ ohun mímu yín sílẹ̀

àti láti ta ọrẹ ìyẹ̀fun.

Nítorí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó yẹ

kí n dáwọ́ dúró?

7Ìwọ ti ṣe ibùsùn rẹ lórí òkè gíga tí ó rẹwà;

níbẹ̀ ni ẹ lọ láti lọ ṣe ìrúbọ yín.

8Lẹ́yìn àwọn ìlẹ̀kùn yín àti òpó ìlẹ̀kùn yín

níbẹ̀ ni ẹ fi àwọn ààmì òrìṣà yín sí.

Ní kíkọ̀ mí sílẹ̀, ẹ ṣí ibùsùn yín sílẹ̀,

ẹ gun orí rẹ̀ lọ, ẹ sì ṣí i sílẹ̀ gbagada;

ẹ ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn tí ẹ fẹ́ràn ibùsùn wọn,

ẹ̀yin sì ń wo ìhòhò wọn.

9Ẹ̀yin lọ sí Moleki pẹ̀lú òróró olifi

ẹ sì fi kún òórùn dídùn yín.

Ẹ rán ikọ̀ yín lọ jìnnà réré;

ẹ sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú!

10Àwọn ọ̀nà yín gbogbo ti mú àárẹ̀ ba á yín,

ṣùgbọ́n ẹ kò ní sọ pé, ‘kò sí ìrètí mọ́?’

Ẹ rí okun kún agbára yín,

nípa bẹ́ẹ̀ òòyì kò kọ́ ọ yín.

11“Ta ni ó ń pá yín láyà tí ń bà yín lẹ́rù

tí ẹ fi ń ṣèké sí mi,

àti tí ẹ̀yin kò fi rántí mi

tàbí kí ẹ rò yí nínú ọkàn yín?

Ǹjẹ́ kì í ṣe nítorí dídákẹ́ jẹ́ẹ́ mi fún ìgbà pípẹ́

tí ẹ̀yin kò fi bẹ̀rù mi?

12Èmi yóò ṣí òdodo yín páyà àti iṣẹ́ yín,

wọn kì yóò sì ṣe yín ní àǹfààní.

13Nígbà tí ẹ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́

ẹ jẹ́ kí àkójọ àwọn ère yín gbà yín!

Atẹ́gùn yóò gbá gbogbo wọn lọ,

èémí lásán làsàn ni yóò gbá wọn lọ.

Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá fi mí ṣe ààbò rẹ̀

ni yóò jogún ilẹ̀ náà

yóò sì jogún òkè mímọ́ mi.”

Ìtùnú fún àwọn oníròbìnújẹ́

14A ó sì sọ wí pé:

“Tún mọ, tún mọ, tún ọ̀nà náà ṣe!

Ẹ mú àwọn ohun ìkọ̀sẹ̀ kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn mi.”

1557.15: Mt 5.3.Nítorí èyí ni ohun tí Ẹni gíga àti ọlọ́lá jùlọ wí

ẹni tí ó wà títí láé, tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ mímọ́:

“Mo ń gbé ní ibi gíga àti ibi mímọ́,

ṣùgbọ́n pẹ̀lú ẹni n nì tí ó ní ìròbìnújẹ́ àti ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀,

láti sọ ẹ̀mí onírẹ̀lẹ̀ náà jí

àti láti sọ ẹ̀mí oníròbìnújẹ́ n nì jí.

16Èmi kì yóò fẹ̀sùn kan ni títí láé,

tàbí kí n máa bínú sá á,

nítorí nígbà náà ni ọkàn ènìyàn yóò

rẹ̀wẹ̀sì níwájú mi

èémí ènìyàn tí mo ti dá.

17Inú bí mi nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ọ̀kánjúwà rẹ̀;

mo fìyà jẹ ẹ́, mo sì fojú mi pamọ́ ní ìbínú

síbẹ̀, ó tẹ̀síwájú nínú tinú-mi-ni n ó ṣe ọ̀nà rẹ̀.

18Èmi ti rí ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, ṣùgbọ́n Èmi yóò wò ó sàn;

Èmi yóò tọ́ ọ ṣọ́nà n ó sì mú ìtùnú tọ̀ ọ́ wá,

1957.19: Ap 2.39; Ef 2.13,17.ní dídá ìyìn sí ètè àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ní Israẹli.

Àlàáfíà, àlàáfíà fún àwọn tí ó wà lókèèrè àti nítòsí,”

ni Olúwa wí, “Àti pé Èmi yóò wo wọ́n sàn.”

20Ṣùgbọ́n àwọn ìkà dàbí i ríru Òkun

tí kò le è sinmi,

tí ìgbì rẹ̀ ń rú pẹ̀tẹ̀pẹ́tẹ̀ àti ẹrọ̀fọ̀ sókè.

21“Kò sí àlàáfíà,” ni Ọlọ́run mi wí, “fún àwọn ìkà.”