ኢሳይያስ 58 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢሳይያስ 58:1-14

እውነተኛ ጾም

1“በኀይል ጩኽ፤ ምንም አታስቀር፤

ድምፅህን እንደ መለከት አሰማ፤

ለሕዝቤ ዐመፃቸውን፣

ለያዕቆብም ቤት ኀጢአታቸውን ተናገር።

2ዕለት በዕለት ይፈልጉኛል፤

መንገዴን ለማወቅ የሚጓጉ ይመስላሉ፤

ትክክለኛውን ነገር እንደሚያደርግ፣

የአምላኩንም ትእዛዝ እንዳልተወ ሕዝብ ሁሉ፣

ተገቢ የሆነ ፍትሕ ይለምኑኛል፤

እግዚአብሔር ወደ እነርሱ እንዲቀርብ የሚወድዱም ይመስላሉ።

3‘አንተ ካልተቀበልኸው፣

ስለ ምን ብለን ጾምን?

አንተ ከጕዳይ ካልቈጠርኸው፣

ስለ ምን ራሳችንን አዋረድን?’ ይላሉ።

“ሆኖም በጾማችሁ ቀን የልባችሁን ታደርጋላችሁ፤

ሠራተኞቻችሁንም ትበዘብዛላችሁ።

4ጾማችሁ በጥልና በክርክር፣

በግፍ ጡጫና በመደባደብ ይፈጸማል፤

ከእንግዲህ ዛሬ እንደምትጾሙት ጾማችሁ፣

ድምፃችሁ ወደ ላይ እንደሚሰማ ተስፋ አታድርጉ።

5እኔ የመረጥሁት ጾም እንዲህ ዐይነቱን ነውን?

ሰውስ ራሱን የሚያዋርደው በእንዲህ ያለው ቀን ብቻ ነውን?

እንደ ደንገል ራስን ዝቅ ማድረግ ነውን?

ወይስ ማቅ ለብሶ በዐመድ ላይ መንከባለል ነውን?

ታዲያ ጾም ብለህ የምትጠራው ይህን ነውን?

እግዚአብሔርስ የሚቀበለው እንዲህ ያለውን ቀን ነውን?

6“እንግዲህ እኔ የመረጥሁት ጾም፣

የጭቈናን ሰንሰለት እንድትበጥሱ፣

የቀንበርን ገመድ እንድትፈቱ፣

የተጨቈኑትን ነጻ እንድታወጡ፣

ቀንበርን ሁሉ እንድትሰብሩ አይደለምን?

7ምግብህን ለተራበ እንድታካፍለው፣

ተንከራታቹን ድኻ ወደ ቤትህ እንድታስገባው፣

የተራቈተውን ስታይ እንድታለብሰው፣

የሥጋ ዘመድህንም ፊት እንዳትነሣው አይደለምን?

8ይህ ከሆነ ብርሃንህ እንደ ንጋት ጮራ ይፈነጥቃል፤

ፈውስህ ፈጥኖ ይደርሳል፤

ጽድቅህ58፥8 ወይም የአንተ ጻድቁ ቀድሞህ ይሄዳል፤

የእግዚአብሔር ክብር ደጀን ይሆንልሃል።

9የዚያን ጊዜ ትጣራለህ፤ እግዚአብሔርም ይመልስልሃል፤

ለርዳታ ትጮኻለህ፤ እርሱም፣ ‘አለሁልህ’ ይልሃል።

“የጭቈና ቀንበር፣

የክፋትን ንግግርና ጣት መቀሰርን ከአንተ ብታርቅ፣

10ለተራበው ብትራራለት፣

የተገፉት እንዲጠግቡ ብታደርግ፣

ብርሃንህ በጨለማ ያበራል፤

ሌሊትህም እንደ ቀትር ፀሓይ ይሆናል።

11እግዚአብሔር ሁልጊዜ ይመራሃል፤

ፀሓይ ባቃጠለው ምድር ፍላጎትህን ያሟላል፤

ዐጥንትህን ያበረታል፤

በውሃ እንደ ረካ የአትክልት ቦታ፣

እንደማይቋርጥም ምንጭ ትሆናለህ።

12ወገኖችህ የቀድሞ ፍርስራሾችን መልሰው ይሠራሉ፤

የጥንቱንም መሠረት ያቆማሉ፤

አንተም፣ የተናዱ ቅጥሮችን አዳሽ፣

ባለ አውራ መንገድ ከተሞችን ጠጋኝ ትባላለህ።

13“እግሮችህ ሰንበትን እንዳይሽሩ ብታሳርፍ፣

በተቀደሰው ቀኔ የልብህን ባታደርግ፣

ሰንበትን ደስታ፣

የእግዚአብሔርን ቅዱስ ቀን የተከበረ ብለህ ብትጠራው፣

በገዛ መንገድህ ከመሄድ፣

እንደ ፈቃድህ ከማድረግና ከከንቱ ንግግር ብትቈጠብ፣

14በዚያን ጊዜ በእግዚአብሔር ደስ ይልሃል፤

በምድር ከፍታዎች ላይ እንድትጋልብ፣

የአባትህን የያዕቆብን ርስት ጠግበህ እንድትበላ አደርግሃለሁ”

የእግዚአብሔር አፍ ይህን ተናግሯልና።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 58:1-14

Àwẹ̀ tòótọ́

1“Kígbe rẹ̀ sókè, má ṣe fàsẹ́yìn.

Gbé ohùn rẹ sókè bí i ti fèrè.

Jẹ́ kí ó di mí mọ̀ fún àwọn ènìyàn mi, ọ̀tẹ̀ wọn

àti fún ilé Jakọbu ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

2Nítorí ọjọ́ dé ọjọ́ ni wọ́n ń wá mi kiri;

wọ́n ṣe bí ẹni ní ìtara láti mọ ọ̀nà mi,

àfi bí ẹni pé wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè kan tí ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà

tí òun kò sì tí ì kọ àṣẹ Ọlọ́run rẹ̀.

Wọ́n ń béèrè lọ́wọ́ mi fún ìpinnu nìkan

wọ́n sì ṣe bí ẹni ń tara fún Ọlọ́run láti súnmọ́ ọ̀dọ̀ wọn.

3‘Èéṣe tí àwa fi ń gbààwẹ̀,’ ni wọ́n wí,

‘tí ìwọ kò sì tí ì rí?

Èéṣe tí àwa fi rẹra wa sílẹ̀,

tí ìwọ kò sì tí ì ṣe àkíyèsí?’

“Síbẹ̀síbẹ̀ ní ọjọ́ àwẹ̀ yín, ẹ̀yin ń ṣe bí ó ti wù yín

ẹ sì ń pọ́n àwọn òṣìṣẹ́ yín gbogbo lójú.

4Àwẹ̀ yín sì parí nínú ìjà àti asọ̀,

àti lílu ọmọnìkejì ẹni pa pẹ̀lú ìkùùkuu.

Ẹ̀yin kò le è gbààwẹ̀ bí ẹ ti ń ṣe lónìí

kí ẹ sì retí kí a gbọ́ ohùn un yín ní ibi gíga.

5Ǹjẹ́ èyí ha ni irú àwẹ̀ tí mo yàn bí,

ọjọ́ kan ṣoṣo fún ènìyàn láti rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀?

Ó ha jẹ pe kí ènìyàn tẹ orí rẹ̀ ba bí i koríko lásán ni bí

àti sísùn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú?

Ṣé ohun tí ẹ̀ ń pè ní àwẹ̀ nìyí,

ọjọ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa?

658.6: Ap 8.23.“Ǹjẹ́ irú àwẹ̀ tí mo ti yàn kọ́ ni èyí:

láti já gbogbo ẹ̀wọ̀n àìṣòdodo

àti láti tú gbogbo okùn àjàgà,

láti tú gbogbo àwọn ti à ń ni lára sílẹ̀

àti láti fọ́ gbogbo àjàgà?

7Kì í ha á ṣe láti pín oúnjẹ yín fún àwọn tí ebi ń pa

àti láti pèsè ibùgbé fún àwọn òtòṣì tí ń rìn káàkiri.

Nígbà tí ẹ bá rí ẹni tí ó wà níhòhò, láti daṣọ bò ó,

àti láti má ṣe lé àwọn ìbátan yín sẹ́yìn?

8Nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ rẹ yóò tàn jáde bí òwúrọ̀

àti ìmúláradá rẹ yóò farahàn kíákíá;

nígbà náà ni òdodo rẹ yóò sì lọ níwájú rẹ,

ògo Olúwa yóò sì jẹ́ ààbò lẹ́yìn rẹ.

9Nígbà yìí ni ẹ̀yin yóò pè, tí Olúwa yóò sì dáhùn;

ẹ̀yin yóò kígbe fún ìrànlọ́wọ́, òun yóò sì wí pé: Èmi nìyí.

“Bí ìwọ bá mú àjàgà aninilára,

nínà ìka àlébù àti sísọ ọ̀rọ̀ asán kúrò láàrín rẹ,

10àti bí ẹ̀yin bá ná ara yín bí owó nítorí àwọn tí ebi ń pa

tí ẹ sì tẹ́ ìfẹ́ àwọn tí à ń ni lára lọ́rùn,

nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ yín yóò ràn nínú òkùnkùn,

àti òru yín yóò dàbí ọ̀sán gangan.

11Olúwa yóò máa tọ́ ọ yín nígbà gbogbo;

òun yóò tẹ́ gbogbo àìní yín lọ́rùn ní ilẹ̀ tí oòrùn ń tan ìmọ́lẹ̀

yóò sì fún egungun rẹ lókun.

Ìwọ yóò sì dàbí ọgbà tí a bomirin dáradára,

àti bí orísun tí omi rẹ̀ kì í gbẹ.

12Àwọn ènìyàn rẹ yóò tún ahoro àtijọ́ kọ́

wọn yóò sì gbé ìpìlẹ̀ àtijọ́-tijọ́ ró

a ó sì pè ọ́ ní alátúnṣe ògiri tí ó ti wó

àti olùmúbọ̀sípò àwọn òpópónà tí ènìyàn gbé inú rẹ̀.

13“Bí ìwọ bá pa ẹsẹ̀ rẹ mọ́ kúrò nínú bíba ọjọ́ ìsinmi jẹ́,

àti ṣíṣe bí ó ti wù ọ́ ni ọjọ́ mímọ́ mi,

bí ìwọ bá pe ọjọ-ìsinmi ní ohun dídùn

àti ọjọ́ mímọ́ Olúwa ní ohun ọ̀wọ̀

àti bí ìwọ bá bu ọlá fún un láti máa bá ọ̀nà tìrẹ lọ

àti láti má ṣe bí ó ti wù ọ́ tàbí

kí o máa sọ̀rọ̀ aláìníláárí,

14nígbà náà ni ìwọ yóò ní ayọ̀ nínú Olúwa rẹ,

èmi yóò sì jẹ́ kí ìwọ kí ó máa gun ibi gíga ilẹ̀ ayé,

àti láti máa jàdídùn ìní ti

Jakọbu baba rẹ.”

Ẹnu Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.