ኢሳይያስ 56 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢሳይያስ 56:1-12

ለሌሎች የተሰጠ ድነት

1እግዚአብሔር እንዲህ ይላል፤

“ፍትሕን ጠብቁ፤

መልካሙን አድርጉ፤

ማዳኔ በቅርብ ነው፤

ጽድቄም ፈጥኖ ይገለጣልና።

2ሰንበትን ሳያረክስ የሚያከብር፣

ክፉን ከማድረግ እጁን የሚሰበስብ፣ የሚገታ፣

እነዚህን የሚፈጽም ሰው የተባረከ ነው።”

3ወደ እግዚአብሔር የተጠጋ መጻተኛ፣

“እግዚአብሔር በርግጥ ከሕዝቡ ይለየኛል” አይበል፤

ጃንደረባም፣

“እኔ ደረቅ ዛፍ ነኝ” አይበል።

4እግዚአብሔር እንዲህ ይላል፤

“ሰንበቶቼን ለሚያከብሩ ጃንደረቦች፣

ደስ የሚያሰኘኝን ለሚመርጡ፣

ቃል ኪዳኔን፣ ለሚጠብቁ

5በቤተ መቅደሴና በቅጥሮቼ ውስጥ፣

ከወንዶችና ከሴቶች ልጆች የበለጠ፣

መታሰቢያና ስም እሰጣቸዋለሁ፤

ለዘላለም፣

የማይጠፋ ስም እሰጣቸዋለሁ።

6እርሱን ለማገልገል፣

ራሳቸውን ከእግዚአብሔር ጋር ያቈራኙ መጻተኞች፣

የእግዚአብሔርን ስም በመውደድ፣

እርሱንም በማምለክ፣

ሰንበትን ሳያረክሱ የሚያከብሩትን ሁሉ፣

ቃል ኪዳኔንም የሚጠብቁትን፣

7ወደ ተቀደሰው ተራራዬ አመጣቸዋለሁ፤

በጸሎት ቤቴም ውስጥ ደስ አሰኛቸዋለሁ።

የሚቃጠል መሥዋዕታቸውንና ሌሎች መሥዋዕቶቻቸውን፣

በመሠዊያዬ ቢሠዉ እቀበላቸዋለሁ፤

ቤቴ፣ ለሕዝቦች ሁሉ

የጸሎት ቤት ተብሎ ይጠራልና።”

8የተበተኑትን እስራኤል የሚሰበስብ፣

ጌታ እግዚአብሔር እንዲህ ይላል፤

“ከተሰበሰቡት በተጨማሪ፣

ሌሎችን እንደ ገና እሰበስባለሁ።”

በክፉዎች ላይ የእግዚአብሔር ወቀሣ

9እናንት የምድር አራዊት ሁሉ ኑ፤

እናንት የዱር አራዊት ሁሉ ኑና በጥርሳቸሁ ቦጫጭቁ።

10የእስራኤል ጠባቂዎች ዕውሮች ናቸው፤

ዕውቀት የላቸውም፤

ሁሉም ድምፅ የለሽ ውሾች ናቸው፤

መጮኽ አይችሉም፤

ተጋድመው ያልማሉ፤

እንቅልፋሞች ናቸው።

11እጅግ ሲበዛ ሆዳም ውሾች ናቸው፤

ጠገብሁን አያውቁም፤

የማያስተውሉ እረኞች ናቸው፤

ሁሉም በየራሳቸው መንገድ ሄዱ፤

እያንዳንዳቸውም የግል ጥቅማቸውን ፈለጉ።

12እርስ በርሳቸውም፣ “ኑና የወይን ጠጅ እንገባበዝ፤

እስክንሰክር እንጠጣ፤

ነገም ያው እንደ ዛሬ፣

ምናልባትም የተሻለ ቀን ይሆንልናል” ይባባላሉ።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 56:1-12

Ìgbàlà fún àwọn mìíràn

1Èyí ni ohun ti Olúwa sọ:

“Ẹ pa ìdájọ́ mọ́

ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ̀nà,

nítorí ìgbàlà mi súnmọ́ tòsí

àti òdodo mi ni a ó fihàn láìpẹ́ jọjọ.

2Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣe èyí,

àti fún ọmọ ènìyàn tí ó dìímú ṣinṣin,

tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́,

tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi ṣíṣe.”

3Má ṣe jẹ́ kí àjèjì kan tí ó ti di ara rẹ̀

mọ́ Olúwa sọ wí pé,

Olúwa yóò yà mí sọ́tọ̀ kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.”

Àti kí ìwẹ̀fà kan ṣe àròyé pé,

“Igi gbígbẹ lásán ni mí.”

4Nítorí pé báyìí ni Olúwa wí:

“Sí àwọn ìwẹ̀fà yìí tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́,

tí wọ́n yan ohun tí ó dùn mọ́ mi

tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin

5fún wọn ni Èmi yóò fún nínú tẹmpili àti àgbàlá rẹ̀

ìrántí kan àti orúkọ kan

tí ó sàn ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin

Èmi yóò fún wọn ní orúkọ ayérayé

tí a kì yóò ké kúrò.

6Àti àwọn àjèjì tí ó so ara wọn mọ́ Olúwa

láti sìn ín,

láti fẹ́ orúkọ Olúwa

àti láti foríbalẹ̀ fún un

gbogbo àwọn tí ń pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́

àti tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin—

756.7: Mt 21.13; Mk 11.17; Lk 19.46.àwọn wọ̀nyí ni èmi yóò mú wá òkè mímọ́ mi,

èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀ nínú ilé àdúrà mi.

Ẹbọ sísun wọn àti ìrúbọ wọn,

ni a ó tẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi;

nítorí a ó máa pe ilé mi ní

ilé àdúrà fún gbogbo orílẹ̀-èdè.”

8Olúwa Olódùmarè sọ wí pé—

ẹni tí ó kó àwọn àtìpó Israẹli jọ:

“Èmi yóò kó àwọn mìíràn jọ pẹ̀lú wọn

yàtọ̀ sí àwọn tí a ti kójọ.”

Ẹ̀sùn tí Ọlọ́run fi kan àwọn ìkà

9Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin ẹranko inú pápá,

ẹ wá jẹ àwọn ẹranko inú igbó run!

10Àwọn olùṣọ́ Israẹli fọ́jú,

gbogbo wọn ṣe aláìní ìmọ̀;

Gbogbo wọn jẹ́ adití ajá,

wọn kò lè gbó;

wọ́n sùn sílẹ̀ wọ́n ń lálàá,

wọ́n fẹ́ràn láti máa sùn.

11Wọ́n jẹ́ àwọn ajá tí ó kúndùn púpọ̀;

wọn kì í ní ànító.

Wọ́n jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn tí kò ní òye;

olúkúlùkù ń yà ṣọ́nà ara rẹ̀,

ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sì wá ère tirẹ̀.

12“Wá,” ni igbe ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn, “fún mi ní ọtí wáìnì!

Jẹ́ kí a mu ọtí líle wa lámu yó

ọ̀la yóò sì dàbí òní,

tàbí kí ó dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.”