Titu 3 – YCB & CRO

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Titu 3:1-15

Ṣíṣe ohun tí o tọ̀nà

1Rán àwọn ènìyàn náà létí láti máa tẹríba fún ìjọba àti àwọn aláṣẹ. Kí wọn ṣe ìgbọ́ràn nígbà gbogbo, kí wọn sì múra fún iṣẹ́ rere gbogbo. 2Wọn kò gbọdọ̀ sọ̀rọ̀ ẹnikẹ́ni ní ibi, kí wọn jẹ́ ẹni àlàáfíà àti ẹni pẹ̀lẹ́, kí wọn sì máa fi ìwà tútù gbogbo hàn sí gbogbo ènìyàn.

3Nígbà kan rí, àwa pàápàá jẹ́ òpè àti aláìgbọ́ràn, àti tàn wá jẹ, a sì ti sọ wá di ẹrú fún onírúurú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti adùn ayé. À ń gbé ìgbé ayé àrankàn àti owú kíkorò, a jẹ́ ẹni ìríra, a sì ń kórìíra ọmọ ẹnìkejì wa pẹ̀lú. 4Ṣùgbọ́n nígbà tí inú rere àti ìfẹ́ Ọlọ́run Olùgbàlà wa farahàn, 5o gbà wá là. Kì í ṣe nípa iṣẹ́ tí àwa ṣe nínú òdodo bí kò ṣe nítorí àánú rẹ̀. Ó gbà wá là, nípasẹ̀ ìwẹ̀nù àtúnbí àti ìsọdọ̀tun ti Ẹ̀mí Mímọ́, 6èyí tí tú lé wa lórí ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ nípasẹ̀ Jesu Kristi Olùgbàlà wá. 7Tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ tí ó jẹ́ wí pé lẹ́hìn tí a tí dá wa láre nípasẹ̀ oore-ọ̀fẹ́, kí a lè jẹ́ àjùmọ̀jogún ìrètí ìyè àìnípẹ̀kun. 8Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ wọ̀nyí. Mo sì fẹ́ kí ó ṣe ìtẹnumọ́ rẹ̀ gidigidi, kí àwọn tí wọ́n ti gbàgbọ́ nínú Ọlọ́run le kíyèsi láti máa fi ara wọn jì fún iṣẹ́ rere. Nǹkan wọ̀nyí dára, wọ́n sì jẹ́ èrè fún gbogbo ènìyàn.

9Ṣùgbọ́n yẹra kúrò nínú àwọn ìbéèrè òmùgọ̀, àti ìtàn ìran, àti àríyànjiyàn àti ìjà nípa ti òfin, nítorí pé àwọn nǹkan báyìí jẹ́ aláìlérè àti asán. 10Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ dá ìyapa sílẹ̀ láàrín yín, ẹ bá a wí lẹ́ẹ̀kínní àti lẹ́ẹ̀kejì. Lẹ́yìn náà, ẹ má ṣe ní ohunkóhun í ṣe pẹ̀lú rẹ̀. 11Kí ó dá ọ lójú wí pé irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti yapa, ó jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀, ó sì dá ara rẹ̀ lẹ́bi.

Àwọn ìkíni ìkẹyìn

12Ní kété tí mo bá ti rán Artema tàbí Tikiku sí ọ, sa gbogbo ipá rẹ láti tọ̀ mí wá ní Nikopoli, nítorí mo ti pinnu láti lo ìgbà òtútù mi níbẹ̀. 13Sa gbogbo agbára rẹ láti ran Senasi amòfin àti Apollo lọ́wọ́ nínú ìrìnàjò wọn. Rí i dájú pé wọ́n ní ohun gbogbo tí wọn nílò.

14Àwọn ènìyàn nílò láti kọ́ bí a tí ń fi ara ẹni jì sí iṣẹ́ rere kí wọn ba à le pèsè ohun kòsémánìí fún ara wọn, nípa èyí, wọn kì yóò jẹ́ aláìléso.

15Gbogbo àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ mi kí ọ.

Bá mi kí àwọn tí ó fẹ́ wa nínú ìgbàgbọ́.

Kí oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú gbogbo yín.

Knijga O Kristu

Titu 3:1-15

Činiti dobro

1Podsjećaj ih da se pokoravaju poglavarima i vlastima, da budu poslušni i spremni na svako dobro djelo. 2Neka ni o komu ružno ne govore, neka se ne svađaju i neka budu popustljivi, vrlo blagi prema svima.

3I mi smo nekoć bili nerazumni, nepokorni, zalutali u ropstvo raznih požuda i grešnih naslada. Živjeli smo u zlu i zavisti. Mrzili smo druge i oni su mrzili nas.

4Ali tada nam je Bog, naš Spasitelj, iskazao svoju dobrotu i ljubav. 5Spasio nas je, ali ne zbog dobrih djela koja smo činili, nego zbog svojega milosrđa. Oprao nas je od grijeha i dao nam da se rodimo u novi život po Svetome Duhu 6kojega je na nas obilno izlio zbog onoga što je za nas učinio Isus Krist, Spasitelj naš. 7Opravdao nas je svojom milošću i učinio baštinicima vječnoga života kojemu se nadamo. 8Sve što sam ti rekao je istina. Hoću da to uporno tvrdiš da se oni koji su povjerovali Bogu posvete vršenju djela ljubavi. To je svima dobro i korisno.

Pavlove završne napomene i pozdravi

9Kloni se budalastih prepirki oko rodoslovlja, svađa i ispraznih rasprava o židovskim zakonima jer je to posve nekorisno i nevrijedno. 10Izaziva li tko među vama razdor, dvaput ga opomeni. Ako ne posluša, nemojte više ništa s njim imati 11jer je pokvaren i griješi te tako sam sebe osuđuje.

12Kanim k tebi poslati Artemu ili Tihika. Čim stigne, požuri k meni u Nikopol jer sam ondje odlučio zimovati. 13Učini sve što možeš za pravnika Zenu i Apolona na putu. Pobrini se da imaju sve što im treba. 14Jer naši ljudi ne bi smjeli živjeti neplodnim životom. Moraju naučiti prednjačiti djelima ljubavi prema ljudima u potrebi.

15Svi koji su sa mnom pozdravljaju vas. Pozdravi vjernike koji nas vole.

Neka je Božja milost sa svima vama.