Ọjọ́ iwájú Jerusalẹmu
1Ègbé ni fún ìlú aninilára,
ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
2Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni,
òun kò gba ìtọ́ni,
òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa,
bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
3Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù,
àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn,
wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
4Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga,
wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn.
Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́,
wọ́n sì rú òfin.
5Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo;
kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà.
Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀,
kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun,
síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
6“Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò,
ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́.
Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo
tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀.
Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí
ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù,
kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
7Èmi wí fún ìlú náà wí pé
‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi,
ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’
Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò
bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó.
Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara
láti ṣe ìbàjẹ́.
8Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí,
“títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin;
nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ
kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ
àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn,
àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi.
Nítorí, gbogbo ayé
ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
9“Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́,
nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa,
láti fi ọkàn kan sìn ín.
10Láti òkè odò Etiopia,
àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká,
yóò mú ọrẹ wá fún mi.
11Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì
nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi,
nígbà náà ni èmi yóò mu
kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn.
Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́
ní òkè mímọ́ mi.
12Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù
àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀,
wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
13Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà
ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké,
bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní
ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
14Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni,
kígbe sókè, ìwọ Israẹli!
Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn,
ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
15Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì
kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn.
Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ,
Ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
16Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé,
“Má ṣe bẹ̀rù Sioni;
má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
17Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ,
Ó ní agbára láti gbà ọ là.
Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀;
Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀,
Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
18“Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ,
àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀;
àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
19Ní àkókò náà
ni èmi yóò dojúkọ àwọn
tí ń ni yín lára,
èmi yóò gba àtiro là,
èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ,
èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní
gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
20Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ;
Nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé.
Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín
láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé,
nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín
padà bọ sípò ní ojú ara yín,”
ni Olúwa wí.
Mehia ma Jerusalemu
13:1 Jer 6:6; Gũcook 21:18Kaĩ itũũra rĩĩrĩ inene rĩa andũ aremi, na rĩgwatĩtio thaahu,
o na rĩiyũrĩte maũndũ ma kũhinyanĩrĩria rĩrĩ na haaro-ĩ!
23:2 Jer 22:21; Thab 73:28Rĩtirĩ mũndũ rĩathĩkagĩra, rĩtiĩtĩkagĩra gũtaarwo.
Rĩtiĩhokaga Jehova, na rĩtikuhagĩrĩria Ngai warĩo.
3Anene aarĩo mahaana ta mĩrũũthi ĩkũrarama,
aathani aarĩo mahaana ta njũũi iria icangacangaga hwaĩ-inĩ,
gũtirĩ kĩndũ matigagia gĩkinyie rũciinĩ.
43:4 Ezek 22:26Anabii aarĩo nĩ etĩĩi;
nĩ andũ a ungumania.
Athĩnjĩri-Ngai aarĩo mathaahĩtie handũ-harĩa-haamũre,
na magathũkia watho.
53:5 Thab 25:3; Gũcook 32:4Jehova ũrĩa ũrĩ thĩinĩ warĩo nĩ mũthingu;
we ndeekaga ũũru.
Rũciinĩ o rũciinĩ nĩatuanagĩra ciira na kĩhooto,
mũthenya o mũthenya ndagaga gwĩka ũguo,
no arĩa matarĩ athingu matirĩ thoni.
6“Nĩniinĩte ndũrĩrĩ;
ciĩgitĩro ciao cia hinya nĩ momore.
Nacio barabara ciao ndũmĩte itiganĩrio,
gũtirĩ mũndũ ũracigerera.
Matũũra mao manene nĩmanange;
gũtirĩ mũndũ o na ũmwe ũtigarĩte, gũtirĩ o na ũmwe.
73:7 Jer 7:28; Hos 9:9Ndeerire itũũra rĩu inene atĩrĩ,
‘Ti-itherũ nĩũkanjĩtigĩra,
na wĩtĩkĩre gũtaarwo!’
Hĩndĩ ĩyo itũũro ciake itikaniinwo,
o na kana maherithia makwa mamũkore.”
No o meeriragĩria o gwĩka ũũru
maũndũ-inĩ mao mothe.
8Nĩ ũndũ ũcio Jehova ekuuga atĩrĩ,
“Ikarai mũnjetereire,
mweterere mũthenya ũrĩa ngaarũgama ndute ũira.
Nĩnduĩte atĩ nĩngacookanĩrĩria ndũrĩrĩ hamwe,
na nyũnganie mothamaki,
nĩguo ndĩmaitĩrĩrie mangʼũrĩ makwa,
nĩmo marakara makwa mahiũ.
Thĩ yothe nĩĩkaniinwo
nĩ mwaki wa marakara ma ũiru wakwa.
93:9 Isa 19:18; Kĩam 4:16“Hĩndĩ ĩyo nĩngatheria mĩromo ya ndũrĩrĩ,
nĩguo othe makayagĩre rĩĩtwa rĩa Jehova,
na mamũtungatagĩre marĩ na ũrũmwe.
103:10 Thab 68:31; 2Maũ 32:23Andũ akwa arĩa mahurunjũkĩire
mũrĩmo ũrĩa ũngĩ wa njũũĩ cia Kushi,
o acio maahooyaga,
nĩmakandehera maruta.
113:11 Isa 29:22; Thaam 15:17Mũthenya ũcio wee ndũgaconorithio
nĩ ũndũ wa maũndũ mothe marĩa mooru wananjĩka,
tondũ nĩngeheria arĩa othe makenagĩra mwĩtĩĩo wao,
ndĩmarute kuuma itũũra-inĩ rĩĩrĩ inene.
Ndũgacooka gwĩtũũgĩria
ũrĩ kĩrĩma-inĩ gĩakwa gĩtheru.
123:12 Isa 14:32; Nahu 1:7No rĩrĩ, nĩngatigia gatagatĩ-inĩ kanyu
andũ arĩa ahooreri na enyiihia,
arĩa mehokete rĩĩtwa rĩa Jehova.
133:13 Kũg 14:5; Alaw 26:6Matigari ma Isiraeli matigekaga ũũru;
matikaheenanagia,
kana ũhinga woneke tũnua-inĩ twao.
Makaarĩĩaga na magakoma,
na gũtirĩ mũndũ ũkaamamakia.”
14Atĩrĩrĩ, wee Mwarĩ wa Zayuni, ina rwĩmbo;
o nawe, Isiraeli anĩrĩra!
Nawe Mwarĩ wa Jerusalemu
kena na ũcanjamũke na ngoro yaku yothe!
153:15 Ezek 37:26-28; Zek 9:9Jehova nĩeheretie ihũũra rĩaku,
nacio thũ ciaku nĩacingatĩte.
Jehova mũthamaki wa Isiraeli arĩ hamwe nawe;
ndũgacooka gwĩtigĩra mwanangĩko rĩngĩ.
163:16 Isa 35:3-4; Ahib 12:12Mũthenya ũcio nĩmakeera Jerusalemu atĩrĩ,
“Wee Zayuni, ndũgacooke gwĩtigĩra
na ndũkaregerie moko maku.
173:17 Isa 63:1; Gũcook 28:63; Hos 14:4Jehova Ngai waku arĩ hamwe nawe,
o we ũrĩa ũrĩ hinya wa kũhonokania.
Nĩarĩgũkenagĩra mũno,
na nĩarĩkũhooragĩria na wendo wake,
agũkũngũĩre akĩinaga nyĩmbo.”
18“Kĩeha gĩa ciathĩ iria njathane nĩngamwehereria;
icio ikoretwo irĩ mũrigo na cia thoni harĩ inyuĩ.
193:19 Ezek 34:16; Mik 4:6Hĩndĩ ĩyo nĩngaherithia
arĩa othe maamũhinyagĩrĩria;
nĩngahonokia arĩa ithua,
na njookererie arĩa mahurunjĩtwo.
Nĩngatũma magĩe igweta na ndĩmagoocithie
mabũrũri-inĩ mothe kũrĩa manaconorithio.
203:20 Ezek 37:12; Isa 56:5Ihinda rĩu nĩngamũcookanĩrĩria;
hĩndĩ ĩyo nĩngamũcookia mũciĩ.
Nĩngatũma mũgĩe igweta na ndĩmũgoocithie
gatagatĩ-inĩ ka ndũrĩrĩ ciothe cia thĩ,
hĩndĩ ĩrĩa ngaatũma mũgaacĩre rĩngĩ,
o mũkĩĩonagĩra na maitho manyu,”
ũguo nĩguo Jehova ekuuga.