Sefaniah 2 – YCB & GKY

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sefaniah 2:1-15

Ìpè si Ìrònúpìwàdà

1Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀

orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,

2kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà,

kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín,

kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.

3Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà,

ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ.

Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú,

bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.

Ìlòdì sí Filistia

42.4-7: Isa 14.29-31; Jr 47; El 25.15-17; Jl 3.4-8; Am 1.6-8; Sk 9.5-7.Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀,

Aṣkeloni yóò sì dahoro.

Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde,

a ó sì fa Ekroni tu kúrò.

5Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun,

ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti;

Ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani,

ilẹ̀ àwọn ara Filistini.

“Èmi yóò pa yín run,

ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”

6Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti,

ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.

7Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda,

níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran,

Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò

dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́.

Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò,

yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.

Ìlòdì sí Moabu àti Ammoni

82.8-11: Isa 15–16; 25.10-12; Jr 48; El 25.8-11; Am 2.1-3.“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu,

àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni,

àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi,

tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.

9Nítorí náà, bí Èmi tí wà,”

ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí,

“nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu

àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra,

ibi tí ó kún fún yèrèpè

àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé.

Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn;

àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni

yóò jogún ilẹ̀ wọn.”

10Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn,

nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.

11Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn;

nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run.

Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn,

olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.

12“Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú,

a ó fi idà mi pa yín.”

Asiria

13Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá,

yóò sì pa Asiria run,

yóò sì sọ Ninefe di ahoro,

àti di gbígbẹ bí aginjù.

14Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀,

àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè.

Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí

yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ́n rẹ̀.

Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé,

ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà,

òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.

15Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu.

Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé,

“Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.”

Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́,

ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó!

Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀

yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà,

wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.

Holy Bible in Gĩkũyũ

Zefania 2:1-15

12:1 Joel 1:14; Jer 3:3Mwĩcookanĩrĩriei hamwe, mwĩcookanĩrĩriei hamwe

inyuĩ rũrĩrĩ rũrũ rũtarĩ thoni.

22:2 Isa 17:13; Jer 4:4Mwĩcookanĩrĩriei mbere ya ihinda rĩrĩa rĩtuĩtwo gũkinya,

mũthenya ũcio ũmũkorerere ta ũrĩa mũũngũ ũmbũragwo nĩ rũhuho,

mbere ya marakara mahiũ ma Jehova mamũkore,

mbere ya mũthenya ũcio wa mangʼũrĩ ma Jehova kũmũkora.

32:3 Amos 5:6; Isa 1:17Cariai Jehova, inyuĩ andũ othe arĩa enyiihia a bũrũri,

inyuĩ arĩa mwĩkaga ũrĩa aathanĩte.

Mwĩcarĩriei ũthingu, mwĩcarĩriei kwĩnyiihia;

no gũkorwo nĩmũkagitĩrwo

mũthenya ũcio wa marakara ma Jehova.

Ũrathi wa Gũũkĩrĩra Filistia

42:4 Amos 1:6-8; Zek 9:5-7Itũũra rĩa Gaza nĩrĩgatiganĩrio,

narĩo itũũra rĩa Ashikeloni rĩanangwo.

Andũ a Ashidodi makaarutũrũrwo mũthenya barigici,

narĩo itũũra rĩa Ekironi rĩthario ta mũtĩ ũkũmunywo.

52:5 1Sam 30:14; Amos 3:1Inyuĩ arĩa mũtũũraga ndwere-inĩ cia iria,

o inyuĩ Akerethi, kaĩ mũrĩ na haaro-ĩ!

Ndũmĩrĩri ya Jehova nĩ ĩgũũkĩrĩire,

wee Kaanani, bũrũri wa Afilisti.

“Nĩngakũniina,

na gũtirĩ mũndũ o na ũmwe ũgaatigara.”

6Bũrũri ũcio ũrĩ ndwere-inĩ cia iria, o kũu Akerethi matũũraga,

gũgaatuĩka kũndũ gwa gwakwo ithũnũ cia arĩithi, na ciugũ cia ngʼondu.

7Bũrũri ũcio ũgaatuĩka wa matigari ma nyũmba ya Juda;

kũu nĩkuo makoona ũrĩithio.

Hwaĩ-inĩ magaakomaga nyũmba cia Ashikeloni.

Nake Jehova Ngai wao nĩakamamenyerera, na atũme magaacĩre rĩngĩ.

Ũrathi wa Gũũkĩrĩra Moabi na Amoni

82:8 Ezek 25:3; Maca 3:61“Nĩnjiguĩte irumi cia Moabi

na inyũrũri cia Aamoni,

acio maarumire andũ akwa

na makĩĩhĩta gũũkĩrĩra bũrũri wao.”

92:9 Gũcook 29:23; Jer 49:1-6; 2Ath 19:31Jehova Mwene-Hinya-Wothe, Ngai wa Isiraeli, ekuuga atĩrĩ,

“Ti-itherũ o ta ũrĩa niĩ ndũũraga muoyo-rĩ,

Moabi gũgaatuĩka o ta Sodomu,

naguo bũrũri wa Aamoni ũtuĩke ta Gomora,

kũndũ kwa riya, na marima ma cumbĩ,

kũndũ gũtakũraga kĩndũ kuuma tene.

Matigari ma andũ akwa nĩmakaamataha;

nao andũ a rũrĩrĩ rwakwa arĩa makaahonoka nĩmakagaya bũrũri wao.”

10Maũndũ macio nĩmakamakora nĩ ũndũ wa mwĩtĩĩo wao,

na nĩ ũndũ wa kũruma na kũnyũrũria andũ a Jehova Mwene-Hinya-Wothe.

112:11 Joel 2:11; Zef 3:9Jehova nĩagetigĩrwo nĩo

rĩrĩa akaananga ngai ciothe cia bũrũri ũcio.

Ndũrĩrĩ iria irĩ hũgũrũrũ-inĩ ciothe cia iria nĩikamũhooya,

o rũrĩrĩ rũrĩ bũrũri waruo kĩũmbe.

Ũrathi wa Gũũkĩrĩra Kushi

12“O na inyuĩ, andũ a Kushi,

nĩmũkooragwo na rũhiũ rwakwa rwa njora.”

Ũrathi wa Gũũkĩrĩra Ashuri

132:13 Nahu 1:1; Mik 5:6Nĩagatambũrũkia guoko gwake okĩrĩre andũ a gathigathini

na aniine Ashuri,

atige Nineve gũkirĩte ihooru,

na kũũmagarĩte o ta werũ.

142:14 Kũg 18:2Ndũũru cia mbũri na ngʼombe igaakoma kuo,

hamwe na ciũmbe cia mĩthemba yothe.

Ndundu cia werũ na ndundu iria ngʼambi

nĩikomba itugĩ-inĩ ciakuo.

Kayũ ka mĩgambo yacio gakaiguuagwo ndirica-inĩ,

hĩba cia mahiga igaakorwo mĩrango-inĩ,

nayo mĩgamba ya mĩtarakwa ĩtigwo ũtheri.

152:15 Isa 47:8; Ezek 27:36Rĩĩrĩ nĩrĩo itũũra rĩrĩa rĩratũire na gĩkeno,

o na rĩtarĩ na ũgwati.

Rĩrĩa rĩeĩĩraga atĩrĩ,

“Niĩ no niĩ, na gũtirĩ ũngĩ tiga niĩ.”

Kaĩ nĩrĩkĩanangĩtwo,

rĩgatuĩka o kĩmamo kĩa nyamũ cia gĩthaka-ĩ!

Arĩa othe mahĩtũkagĩra harĩ rĩo

no kũrĩnyũrũria na kũrĩorota.