Sefaniah 2 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sefaniah 2:1-15

Ìpè si Ìrònúpìwàdà

1Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀

orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,

2kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà,

kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín,

kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.

3Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà,

ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ.

Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú,

bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.

Ìlòdì sí Filistia

42.4-7: Isa 14.29-31; Jr 47; El 25.15-17; Jl 3.4-8; Am 1.6-8; Sk 9.5-7.Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀,

Aṣkeloni yóò sì dahoro.

Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde,

a ó sì fa Ekroni tu kúrò.

5Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun,

ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti;

Ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani,

ilẹ̀ àwọn ara Filistini.

“Èmi yóò pa yín run,

ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”

6Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti,

ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.

7Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda,

níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran,

Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò

dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́.

Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò,

yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.

Ìlòdì sí Moabu àti Ammoni

82.8-11: Isa 15–16; 25.10-12; Jr 48; El 25.8-11; Am 2.1-3.“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu,

àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni,

àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi,

tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.

9Nítorí náà, bí Èmi tí wà,”

ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí,

“nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu

àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra,

ibi tí ó kún fún yèrèpè

àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé.

Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn;

àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni

yóò jogún ilẹ̀ wọn.”

10Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn,

nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.

11Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn;

nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run.

Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn,

olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.

12“Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú,

a ó fi idà mi pa yín.”

Asiria

13Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá,

yóò sì pa Asiria run,

yóò sì sọ Ninefe di ahoro,

àti di gbígbẹ bí aginjù.

14Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀,

àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè.

Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí

yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ́n rẹ̀.

Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé,

ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà,

òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.

15Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu.

Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé,

“Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.”

Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́,

ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó!

Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀

yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà,

wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.

Nova Versão Internacional

Sofonias 2:1-15

1Reúna-se e ajunte-se,

nação sem pudor,

2antes que chegue o tempo determinado

e aquele dia passe como a palha,

antes que venha sobre vocês a ira impetuosa do Senhor,

antes que o dia da ira do Senhor os alcance.

3Busquem o Senhor, todos vocês, os humildes da terra,

vocês que fazem o que ele ordena.

Busquem a justiça, busquem a humildade;

talvez vocês tenham abrigo no dia da ira do Senhor.

O Castigo da Filístia

4Gaza será abandonada,

e Ascalom ficará arruinada.

Ao meio-dia Asdode será banida,

e Ecrom será desarraigada.

5Ai de vocês que vivem junto ao mar,

nação dos queretitas;

a palavra do Senhor está contra você,

ó Canaã, terra dos filisteus.

“Eu a destruirei,

e não sobrará ninguém.”

6Essa terra junto ao mar,

onde habitam os queretitas,

será morada de pastores

e curral de ovelhas.

7Pertencerá ao remanescente da tribo de Judá.

Ali encontrarão pastagem;

e, ao entardecer, eles se deitarão

nas casas de Ascalom.

O Senhor, o seu Deus, cuidará deles,

e lhes restaurará a sorte2.7 Ou trará de volta seus cativos.

O Castigo de Moabe e de Amom

8“Ouvi os insultos de Moabe

e as zombarias dos amonitas,

que insultaram o meu povo

e fizeram ameaças contra o seu território.

9Por isso, juro pela minha vida”,

declara o Senhor dos Exércitos,

o Deus de Israel,

“Moabe se tornará como Sodoma

e os amonitas como Gomorra:

um lugar tomado por ervas daninhas e poços de sal,

uma desolação perpétua.

O remanescente do meu povo os saqueará;

os sobreviventes da minha nação herdarão a terra deles.”

10É isso que eles receberão

como recompensa pelo seu orgulho,

por insultarem e ridicularizarem

o povo do Senhor dos Exércitos.

11O Senhor será terrível contra eles

quando destruir todos os deuses da terra.

As nações de todo o mundo o adorarão,

cada uma em sua própria terra.

O Castigo da Etiópia

12“Vocês também, ó etíopes,2.12 Hebraico: cuxitas

serão mortos pela minha espada.”

O Castigo da Assíria

13Ele estenderá a mão contra o norte

e destruirá a Assíria,

deixando Nínive totalmente em ruínas,

tão seca como o deserto.

14No meio dela se deitarão rebanhos

e todo tipo de animais selvagens.

Até a coruja-do-deserto e o mocho

se empoleirarão no topo de suas colunas.

Seus gritos ecoarão pelas janelas.

Haverá entulho nas entradas,

e as vigas de cedro ficarão expostas.

15Essa é a cidade que exultava,

vivendo despreocupada,

e dizia para si mesma:

“Eu, e mais ninguém!”

Que ruínas sobraram!

Uma toca de animais selvagens!

Todos os que passam por ela zombam

e sacodem os punhos.