Sefaniah 1 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sefaniah 1:1-18

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Sefaniah ọmọ Kuṣi, ọmọ Gedaliah, ọmọ Amariah, ọmọ Hesekiah, ní ìgbà Josiah ọmọ Amoni ọba Juda.

Ìkìlọ̀ fún ìparun tí ń bọ̀

2“Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúrò

lórí ilẹ̀ náà pátápátá,”

ni Olúwa wí.

3“Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹranko

kúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojú

ọ̀run kúrò àti ẹja inú Òkun, àti

ohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọn

ènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,”

ni Olúwa wí.

Ìlòdì sí Juda

4“Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Juda

àti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.

Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín-yìí ìyókù àwọn Baali, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣà

pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,

5àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ lórí òrùlé,

àwọn tí ń sin ogun ọ̀run,

àwọn tó ń foríbalẹ̀, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra,

tí wọ́n sì ń fi Moleki búra.

6Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa;

Àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.”

71.7: Hk 2.20; Sk 2.13.Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Olódùmarè,

nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀.

Olúwa ti pèsè ẹbọ kan sílẹ̀,

ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.

8“Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa,

Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọn

ọmọ ọba ọkùnrin,

pẹ̀lú gbogbo

àwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.

9Ní ọjọ́ náà, èmi yóò fi ìyà jẹ

gbogbo àwọn tí ó yẹra láti rìn lórí ìloro ẹnu-ọ̀nà,

tí wọ́n sì kún tẹmpili àwọn ọlọ́run wọn

pẹ̀lú ìwà ipá àti ẹ̀tàn.

10“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,

“Ohùn ẹkún yóò wà láti ìhà Ibodè ẹja,

híhu láti ìhà kejì wá àti

ariwo ńlá láti òkè kékeré wá.

11Ẹ hu, ẹ̀yin tí ń gbé ní (Maktẹsi) agbègbè ọjà,

gbogbo àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni a ó mú kúrò,

gbogbo àwọn ẹni tí ó ń ra fàdákà ni a ó sì parun.

12Ní àkókò wọ̀n-ọn-nì, èmi yóò wá Jerusalẹmu kiri pẹ̀lú fìtílà,

èmi ó sì fi ìyà jẹ àwọn tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn,

tí wọn sì dàbí àwọn ènìyàn tí ó sinmi sínú gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ wọn,

àwọn tí wọn sì ń wí ní ọkàn wọn pé, ‘Olúwa kì yóò ṣe nǹkan kan

tí ó jẹ́ rere tàbí tí ó jẹ́ búburú.’

13Nítorí náà, ọrọ̀ wọn yóò di ìkógun,

àti ilé wọn yóò sì run.

Àwọn yóò sì kọ́ ilé pẹ̀lú, ṣùgbọ́n

wọn kì yóò gbé nínú ilé náà,

wọn yóò gbin ọgbà àjàrà,

ṣùgbọ́n wọn kì yóò mu ọtí

wáìnì láti inú rẹ̀.”

Ọjọ́ ńlá Olúwa

14“Ọjọ́ ńlá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,

ó kù sí dẹ̀dẹ̀ ó sì ń yára bọ̀

kánkán. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ohùn ẹkún

àwọn alágbára ní ọjọ́ Olúwa yóò korò púpọ̀,

15Ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú,

ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú,

ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro

ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba,

ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,

16ọjọ́ ìpè àti ìpè ogun

sí àwọn ìlú olódi

àti sí àwọn ilé ìṣọ́ gíga.

17“Èmi yóò sì mú ìpọ́njú wá sórí

ènìyàn, wọn yóò sì máa rìn gẹ́gẹ́ bí afọ́jú,

nítorí àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa.

Ẹ̀jẹ̀ wọn ni a ó sì tú jáde bí eruku

àti ẹran-ara wọn bí ìgbẹ́.

18Bẹ́ẹ̀ ni fàdákà tàbí wúrà wọn

kì yóò sì le gbà wọ́n là

ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.”

Ṣùgbọ́n gbogbo ayé ni a ó fi iná

ìjowú rẹ̀ parun,

nítorí òun yóò fi ìyára fi òpin sí

gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ ayé.

Nova Versão Internacional

Sofonias 1:1-18

1Palavra do Senhor que veio a Sofonias, filho de Cuchi, neto de Gedalias, bisneto de Amarias e trineto de Ezequias, durante o reinado de Josias, filho de Amom, rei de Judá:

A Destruição Vindoura

2“Destruirei1.2 Ou Tornarei a destruir todas as coisas

na face da terra”;

palavra do Senhor.

3“Destruirei tanto os homens quanto os animais;

destruirei as aves do céu e os peixes do mar

e os que causam tropeço

junto com os ímpios1.3 Ou os ímpios terão apenas montões de destroços.

Farei isso quando eu ceifar o homem da face da terra”,

declara o Senhor.

O Castigo de Judá

4“Estenderei a mão contra Judá

e contra todos os habitantes de Jerusalém.

Eliminarei deste lugar o remanescente de Baal,

os nomes dos ministros idólatras e dos sacerdotes,

5aqueles que no alto dos terraços

adoram o exército de estrelas

e aqueles que se prostram jurando pelo Senhor

e também por Moloque;

6aqueles que se desviam

e deixam de seguir o Senhor,

não o buscam nem o consultam”.

7Calem-se diante do Soberano, o Senhor,

pois o dia do Senhor está próximo.

O Senhor preparou um sacrifício;

consagrou seus convidados.

8No dia do sacrifício do Senhor

castigarei os líderes e os filhos do rei

e todos os que estão vestidos

com roupas estrangeiras.

9Naquele dia, castigarei

todos os que evitam pisar a soleira dos ídolos1.9 Ver 1Sm 5.5.

e que enchem o templo de seus deuses1.9 Ou de seu senhor

com violência e engano.

10“Naquele dia”, declara o Senhor,

“haverá gritos perto da porta dos Peixes,

lamentos no novo distrito

e estrondos nas colinas.

11Lamentem-se, vocês que moram na cidade baixa1.11 Ou moram no lugar onde se faz argamassa;

todos os seus comerciantes serão completamente destruídos,

todos os que negociam com prata serão arruinados.

12Nessa época vasculharei Jerusalém com lamparinas

e castigarei os complacentes,

que são como vinho envelhecido

deixado com os seus resíduos,

que pensam: ‘O Senhor nada fará,

nem bem nem mal’.

13A riqueza deles será saqueada,

suas casas serão demolidas.

Embora construam novas casas,

nelas não morarão;

plantarão vinhas,

mas o vinho não beberão.

O Grande Dia do Senhor

14“O grande dia do Senhor está próximo;

está próximo e logo vem.

Ouçam! O dia do Senhor será amargo;

até os guerreiros gritarão.

15Aquele dia será um dia de ira,

dia de aflição e angústia,

dia de sofrimento e ruína,

dia de trevas e escuridão,

dia de nuvens e negridão,

16dia de toques de trombeta e gritos de guerra

contra as cidades fortificadas

e contra as torres elevadas.

17Trarei aflição aos homens;

andarão como se fossem cegos,

porque pecaram contra o Senhor.

O sangue deles será derramado como poeira,

e suas entranhas como lixo.

18Nem a sua prata nem o seu ouro poderão livrá-los

no dia da ira do Senhor.

No fogo do seu zelo

o mundo inteiro será consumido,

pois ele dará fim repentino

a todos os que vivem na terra.”