Ìpè si Ìrònúpìwàdà
1Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀
orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,
2kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà,
kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín,
kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.
3Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà,
ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ.
Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú,
bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.
Ìlòdì sí Filistia
42.4-7: Isa 14.29-31; Jr 47; El 25.15-17; Jl 3.4-8; Am 1.6-8; Sk 9.5-7.Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀,
Aṣkeloni yóò sì dahoro.
Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde,
a ó sì fa Ekroni tu kúrò.
5Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun,
ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti;
Ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani,
ilẹ̀ àwọn ara Filistini.
“Èmi yóò pa yín run,
ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”
6Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti,
ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.
7Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda,
níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran,
Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò
dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́.
Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò,
yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.
Ìlòdì sí Moabu àti Ammoni
82.8-11: Isa 15–16; 25.10-12; Jr 48; El 25.8-11; Am 2.1-3.“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu,
àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni,
àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi,
tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
9Nítorí náà, bí Èmi tí wà,”
ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí,
“nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu
àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra,
ibi tí ó kún fún yèrèpè
àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé.
Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn;
àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni
yóò jogún ilẹ̀ wọn.”
10Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn,
nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
11Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn;
nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run.
Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn,
olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.
12“Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú,
a ó fi idà mi pa yín.”
Asiria
13Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá,
yóò sì pa Asiria run,
yóò sì sọ Ninefe di ahoro,
àti di gbígbẹ bí aginjù.
14Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀,
àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè.
Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí
yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ́n rẹ̀.
Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé,
ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà,
òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.
15Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu.
Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé,
“Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.”
Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́,
ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó!
Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀
yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà,
wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.
The Lord Will Judge Judah and Jerusalem Along With the Nations
God Calls Judah to Turn Away From Their Sins
1Gather together,
you shameful nation of Judah!
Gather yourselves together!
2Come together before the Lord’s judgment arrives.
The day of the Lord’s judgment will sweep in
like straw blown by the wind.
Soon the Lord’s great anger will come against you.
The day of his wrath will come against you.
3So look to him, all you people in the land
who worship him faithfully.
You always do what he commands you to do.
Continue to do what is right.
Don’t be proud.
Then perhaps the Lord will keep you safe
on the day he pours out his anger on the world.
A Message About Philistia
4Gaza will be deserted.
Ashkelon will be destroyed.
Ashdod will be emptied out at noon.
Ekron will be pulled up by its roots.
5How terrible it will be for you Kerethites
who live by the Mediterranean Sea!
Philistia, the Lord has spoken against you.
What happened to Canaan will happen to you.
The Lord says, “I will destroy you.
No one will be left.”
6The land by the sea will become grasslands.
It will have wells for shepherds and pens for flocks.
7That land will belong to those who are still left alive
among the people of Judah.
They will find grasslands there.
They will take over
the houses in Ashkelon and live in them.
The Lord their God will take care of them.
He will bless them with great success again.
A Message About Moab and Ammon
8The Lord says,
“I have heard Moab make fun of my people.
The Ammonites also laughed at them.
They told them that bad things
would happen to their land.
9So Moab will become like Sodom,”
announces the Lord who rules over all.
“Ammon will be like Gomorrah.
Weeds and salt pits will cover those countries.
They will be dry and empty deserts forever.
Those who are still left alive among my people
will take all their valuable things.
So they will receive those lands as their own.
And that is just as sure as I am alive.”
The Lord is the God of Israel.
10Moab and Ammon will be judged
because they are so proud.
They made fun of the Lord’s people.
They laughed at them.
11The Lord who rules over all will terrify Moab and Ammon.
He will destroy all the gods on earth.
Then distant nations will bow down to him.
All of them will serve him in their own lands.
A Message About Cush
12The Lord says, “People of Cush,
you too will die by my sword.”
A Message About Assyria
13The Lord will reach out his powerful hand against the north.
He will destroy Assyria.
He’ll leave Nineveh totally empty.
It will be as dry as a desert.
14Flocks and herds will lie down there.
So will creatures of every kind.
Desert owls and screech owls
will rest on its pillars.
The sound of their hooting will echo through the windows.
The doorways will be full of trash.
The cedar beams will be showing.
15Nineveh was a carefree city.
It lived in safety.
It said to itself,
“I am the one!
No one is greater than I am.”
But it has been destroyed.
Wild animals make their home there.
All those who pass by laugh
and shake their fists at it.