1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Sefaniah ọmọ Kuṣi, ọmọ Gedaliah, ọmọ Amariah, ọmọ Hesekiah, ní ìgbà Josiah ọmọ Amoni ọba Juda.
Ìkìlọ̀ fún ìparun tí ń bọ̀
2“Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúrò
lórí ilẹ̀ náà pátápátá,”
ni Olúwa wí.
3“Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹranko
kúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojú
ọ̀run kúrò àti ẹja inú Òkun, àti
ohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọn
ènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,”
ni Olúwa wí.
Ìlòdì sí Juda
4“Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Juda
àti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín-yìí ìyókù àwọn Baali, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣà
pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,
5àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ lórí òrùlé,
àwọn tí ń sin ogun ọ̀run,
àwọn tó ń foríbalẹ̀, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra,
tí wọ́n sì ń fi Moleki búra.
6Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa;
Àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.”
71.7: Hk 2.20; Sk 2.13.Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Olódùmarè,
nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀.
Olúwa ti pèsè ẹbọ kan sílẹ̀,
ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.
8“Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa,
Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọn
ọmọ ọba ọkùnrin,
pẹ̀lú gbogbo
àwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.
9Ní ọjọ́ náà, èmi yóò fi ìyà jẹ
gbogbo àwọn tí ó yẹra láti rìn lórí ìloro ẹnu-ọ̀nà,
tí wọ́n sì kún tẹmpili àwọn ọlọ́run wọn
pẹ̀lú ìwà ipá àti ẹ̀tàn.
10“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,
“Ohùn ẹkún yóò wà láti ìhà Ibodè ẹja,
híhu láti ìhà kejì wá àti
ariwo ńlá láti òkè kékeré wá.
11Ẹ hu, ẹ̀yin tí ń gbé ní (Maktẹsi) agbègbè ọjà,
gbogbo àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni a ó mú kúrò,
gbogbo àwọn ẹni tí ó ń ra fàdákà ni a ó sì parun.
12Ní àkókò wọ̀n-ọn-nì, èmi yóò wá Jerusalẹmu kiri pẹ̀lú fìtílà,
èmi ó sì fi ìyà jẹ àwọn tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn,
tí wọn sì dàbí àwọn ènìyàn tí ó sinmi sínú gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ wọn,
àwọn tí wọn sì ń wí ní ọkàn wọn pé, ‘Olúwa kì yóò ṣe nǹkan kan
tí ó jẹ́ rere tàbí tí ó jẹ́ búburú.’
13Nítorí náà, ọrọ̀ wọn yóò di ìkógun,
àti ilé wọn yóò sì run.
Àwọn yóò sì kọ́ ilé pẹ̀lú, ṣùgbọ́n
wọn kì yóò gbé nínú ilé náà,
wọn yóò gbin ọgbà àjàrà,
ṣùgbọ́n wọn kì yóò mu ọtí
wáìnì láti inú rẹ̀.”
Ọjọ́ ńlá Olúwa
14“Ọjọ́ ńlá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,
ó kù sí dẹ̀dẹ̀ ó sì ń yára bọ̀
kánkán. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ohùn ẹkún
àwọn alágbára ní ọjọ́ Olúwa yóò korò púpọ̀,
15Ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú,
ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú,
ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro
ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba,
ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,
16ọjọ́ ìpè àti ìpè ogun
sí àwọn ìlú olódi
àti sí àwọn ilé ìṣọ́ gíga.
17“Èmi yóò sì mú ìpọ́njú wá sórí
ènìyàn, wọn yóò sì máa rìn gẹ́gẹ́ bí afọ́jú,
nítorí àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa.
Ẹ̀jẹ̀ wọn ni a ó sì tú jáde bí eruku
àti ẹran-ara wọn bí ìgbẹ́.
18Bẹ́ẹ̀ ni fàdákà tàbí wúrà wọn
kì yóò sì le gbà wọ́n là
ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.”
Ṣùgbọ́n gbogbo ayé ni a ó fi iná
ìjowú rẹ̀ parun,
nítorí òun yóò fi ìyára fi òpin sí
gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ ayé.
1A message from the Lord came to Zephaniah, the son of Cushi. Cushi was the son of Gedaliah. Gedaliah was the son of Amariah. Amariah was the son of King Hezekiah. The Lord spoke to Zephaniah during the rule of Josiah. He was king of Judah and the son of Amon.
The Lord Will Judge the Whole World
2“I will sweep away everything
from the face of the earth,”
announces the Lord.
3“I will destroy people and animals alike.
I will wipe out the birds in the sky
and the fish in the waters.
I will destroy the statues of gods that cause evil people to sin.
That will happen when I destroy all human beings on the face of the earth,”
announces the Lord.
4“I will reach out my powerful hand against Judah.
I will punish all those who live in Jerusalem.
I will destroy from this place
what is left of Baal worship.
The priests who serve other gods
will be removed.
5I will destroy those who bow down on their roofs
to worship all the stars.
I will destroy those who make promises
not only in my name but also in the name of Molek.
6I will destroy those who stop following the Lord.
They no longer look to him or ask him for advice.
7Be silent in front of him.
He is the Lord and King.
The day of the Lord is near.
The Lord has prepared a sacrifice.
He has set apart for himself
the people he has invited.
8When the Lord’s sacrifice is ready to be offered,
I will punish the officials and the king’s sons.
I will also judge all those who follow
the practices of other nations.
9At that time I will punish
all those who worship other gods.
They fill the temples of their gods
with lies and other harmful things.
10“At that time people at the Fish Gate in Jerusalem
will cry out,” announces the Lord.
“So will those at the New Quarter.
The buildings on the hills will come crashing down
with a loud noise.
11Cry out, you who live in the market places.
All your merchants will be wiped out.
Those who trade in silver will be destroyed.
12At that time I will search Jerusalem with lamps.
I will punish those who are so contented.
They are like wine that has not been shaken up.
They think, ‘The Lord won’t do anything.
He won’t do anything good or bad.’
13Their wealth will be stolen.
Their houses will be destroyed.
They will build houses.
But they will not live in them.
They will plant vineyards.
But they will not drink the wine they produce.
14The great day of the Lord is near.
In fact, it is coming quickly.
The cries on that day are bitter.
The Mighty Warrior shouts his battle cry.
15At that time I will pour out my anger.
There will be great suffering and pain.
It will be a day of horrible trouble.
It will be a time of darkness and gloom.
It will be filled with the blackest clouds.
16Trumpet blasts and battle cries will be heard.
Soldiers will attack cities
that have forts and corner towers.
17I will bring great trouble on all people.
So they will feel their way around like blind people.
They have sinned against the Lord.
Their blood will be poured out like dust.
Their bodies will lie rotting on the ground.
18Their silver and gold
won’t save them
on the day the Lord pours out his anger.
The whole earth will be burned up
when his jealous anger blazes out.
Everyone who lives on earth
will come to a sudden end.”