Saamu 85 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 85:1-13

Saamu 85

Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu.

1Ìwọ fi ojúrere hàn fún ilé rẹ, Olúwa;

ìwọ mú ohun ìní Jakọbu bọ̀ sí ipò.

2Ìwọ dárí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn rẹ jì

ìwọ sì bó ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀. Sela.

3Ìwọ fi àwọn ìbínú rẹ sápá kan

ìwọ sì yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ.

4Yí wa padà, Ọlọ́run ìgbàlà wa,

kí o sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ wa.

5Ìwọ yóò ha máa bínú sí wa títí láé?

Ìwọ yóò ha mú ìbínú rẹ pẹ́ yí gbogbo ìran ká?

6Ìwọ kì yóò ha sọ wá jí padà mọ́,

pé kí àwọn ènìyàn rẹ lè yọ nínú rẹ?

7Fi ìfẹ́ rẹ tí kò le è kùnà hàn wá, Olúwa,

Kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.

8Èmi ó gbọ́ ohun tí Olúwa Ọlọ́run yóò wí;

ó ṣèlérí àlàáfíà fún àwọn ènìyàn rẹ̀, àní ẹni mímọ́ rẹ̀:

Ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí wọn padà sí àìmoye.

9Nítòótọ́ ìgbàlà rẹ̀ súnmọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,

pé kí ògo rẹ̀ kí ó lè gbé ní ilẹ̀ wa.

10Ìfẹ́ àti òtítọ́ parapọ̀;

òdodo àti àlàáfíà fẹnu ko ara wọn.

11Òtítọ́ ń sun jáde láti ilẹ̀ wá

òdodo sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run.

12Olúwa yóò fi ohun dídára fún ni nítòótọ́,

ilẹ̀ wa yóò sì mú ìkórè rẹ̀ jáde.

13Òdodo síwájú rẹ lọ

o sì pèsè ọ̀nà fún ìgbésẹ̀ rẹ̀.