Saamu 72 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 72:1-20

Saamu 72

Ti Solomoni

1Fi ìdájọ́ fún àwọn ọba, Ọlọ́run,

ọmọ-aládé ni ìwọ fi òdodo rẹ fún

2Yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú òdodo,

yóò sì máa fi ẹ̀tọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn tálákà rẹ̀.

3Àwọn òkè ńlá yóò máa mú àlàáfíà fún àwọn ènìyàn

àti òkè kéékèèkéé nípa òdodo

4Yóò dáàbò bo àwọn tí a pọ́n lójú láàrín àwọn ènìyàn

yóò gba àwọn ọmọ aláìní;

yóò sì fa àwọn aninilára ya.

5Àwọn òtòṣì àti aláìní

yóò máa fi ọ̀wọ̀ ńlá fún ọ nígbà gbogbo,

níwọ̀n ìgbà tí oòrùn àti òṣùpá bá ń ràn,

yóò ti pẹ́ tó, láti ìrandíran.

6Yóò dàbí òjò tí ó ń rọ̀ sórí pápá ìrẹ́mọ́lẹ̀

Bí ọwọ́ òjò tó ń rin ilẹ̀

7Àwọn olódodo yóò gbilẹ̀ ni ọjọ́ rẹ̀

ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà yóò sì wà;

títí tí òṣùpá kò fi ní sí mọ́.

8Yóò máa jẹ ọba láti Òkun dé Òkun

àti láti odò Eufurate títí dé òpin ayé.

9Àwọn tí ó wà ní aginjù yóò tẹríba fún un

àwọn ọ̀tá rẹ̀ yóò máa lá erùpẹ̀ ilẹ̀.

10Àwọn ọba Tarṣiṣi àti ti erékùṣù

wọn yóò mú ọrẹ wá fún un;

àwọn ọba Ṣeba àti Seba

wọn ó mú ẹ̀bùn wá fún un.

11Gbogbo ọba yóò tẹríba fún un

àti gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sìn ín.

12Nítorí yóò gba àwọn aláìní

nígbà tí ó bá ń ké,

tálákà àti ẹni tí kò ní olùrànlọ́wọ́.

13Yóò káàánú àwọn aláìlera àti aláìní

yóò pa aláìní mọ́ kúrò nínú ikú.

14Yóò ra ọkàn wọn padà lọ́wọ́ ẹ̀tàn àti ipá

nítorí ẹ̀jẹ̀ wọn ṣọ̀wọ́n níwájú rẹ̀.

15Yóò sì pẹ́ ní ayé!

A ó sì fún un ní wúrà Ṣeba.

Àwọn ènìyàn yóò sì máa gbàdúrà fún un nígbà gbogbo

kí a sì bùkún fún un lójoojúmọ́.

16Kí ìkúnwọ́ ọkà wà lórí ilẹ̀;

ní orí òkè ni kí ó máa dàgbà

kí èso rẹ̀ kí o gbilẹ̀ bí ti Lebanoni

yóò máa gbá yìn bí i koríko ilẹ̀.

17Kí orúkọ rẹ̀ kí ó wà títí láé;

orúkọ rẹ̀ yóò máa gbilẹ̀ níwọ̀n bí oòrùn yóò ti pẹ́ tó.

Wọn ó sì máa bùkún fún ara wọn nípasẹ̀ rẹ.

Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ní yóò máa pè mí ní alábùkún fún.

18Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli,

ẹnìkan ṣoṣo tí ó ń ṣe ohun ìyanu.

19Olùbùkún ni orúkọ rẹ̀ tí ó lógo títí láé;

kí gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.

Àmín àti Àmín.

20Èyí ni ìparí àdúrà Dafidi ọmọ Jese.