Saamu 71 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 71:1-24

Saamu 71

1Nínú rẹ, Olúwa, ni mo ní ààbò;

Má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.

2Gbà mí kí o sì tú mi sílẹ̀ nínú òdodo rẹ;

dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbà mí.

3Jẹ́ àpáta ààbò mi,

níbi tí èmi lè máa lọ,

pa àṣẹ láti gbà mí,

nítorí ìwọ ni àpáta àti odi agbára mi.

4Gbà mí, Ọlọ́run mi, lọ́wọ́ àwọn olùṣe búburú,

ní ọwọ́ aláìṣòdodo àti ìkà ọkùnrin.

5Nítorí ìwọ jẹ́ ìrètí mi, Olúwa Olódùmarè,

ìwọ ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi láti ìgbà èwe.

6Mo gbẹ́kẹ̀lé ọ láti ìgbà ìbí mi;

Ìwọ mú mi jáde láti inú ìyá mi wá

èmi ó máa yìn ọ́ títí láé.

7Mo di ààmì fún ọ̀pọ̀ ènìyàn,

ṣùgbọ́n ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.

8Ìyìn rẹ̀ kún ẹnu mi,

ó ń sọ ti ọlá rẹ ní ọjọ́ gbogbo.

9Má ṣe ta mí nù ní ọjọ́ ogbó mi

Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́

10Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀-òdì sí mi,

àwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀.

11Wọ́n wí pé, “Ọlọ́run ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀;

lépa rẹ̀ kí ẹ sì mu,

nítorí kò sí ẹni tí yóò gbà á.”

12Má ṣe jìnnà sí mi, Ọlọ́run;

wa kánkán, Ọlọ́run mi, láti ràn mí lọ́wọ́.

13Jẹ́ kí wọn kí ó dààmú,

kí a sì run àwọn tí ń ṣe ọ̀tá ọkàn mi

kí a sì fi ẹ̀gàn àti àbùkù

bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.

14Ṣùgbọ́n ní tèmi, ìgbà gbogbo ní ìrètí mi;

èmi ó yìn ọ́ síwájú àti síwájú sí i.

15Ẹnu mi yóò sọ nípa ti òdodo rẹ,

ti ìgbàlà rẹ, ni gbogbo ọjọ́,

lóòtítọ́, èmi kò mọ iye rẹ̀.

16Èmi ó wá láti wá kéde agbára,

Olúwa Olódùmarè;

èmi ó kéde òdodo rẹ̀ nìkan.

17Láti ìgbà èwe, Ọlọ́run ni ìwọ ti kọ́ mi

títí di òní ni mo ń sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ.

18Pẹ̀lúpẹ̀lú, nígbà tí èmi di arúgbó tán tí mo sì hewú,

Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, Ọlọ́run mi,

títí èmi ó fi ipá rẹ han ìran tí ń bọ̀,

àti agbára rẹ fún gbogbo àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn.

19Ọlọ́run, òdodo rẹ dé ọ̀run,

ìwọ tí o ti ṣe ohun ńlá

Ta ni ó dàbí rẹ, Ọlọ́run?

20Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ ti mú mi rí ìdààmú, tí ó pọ̀ tí ó sì korò,

ìwọ yóò tún sọ ayé mi jí

ìwọ yóò sì tún mú mi sọ sókè

láti ọ̀gbun ilẹ̀ wá.

Ìwọ yóò sọ ọlá mi di púpọ̀

21Ìwọ yóò fi kún ọwọ́ mi

ìwọ yóò tù mí nínú ní ha gbogbo.

22Èmi yóò fi dùùrù mi yìn

fún òtítọ́ rẹ, Ọlọ́run mi;

èmi ó kọrin ìyìn sí ọ pẹ̀lú dùùrù

ìwọ ẹni mímọ́ Israẹli.

23Ètè mi yóò kígbe fún ìyìn

nígbà tí mo bá kọrin ìyìn sí ọ:

èmi, ẹni tí o rà padà.

24Ahọ́n mi yóò sọ ti òdodo rẹ ní gbogbo ọjọ́,

fún àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára,

a sì dójúti àwọn tí ń wá ìdààmú mi.