Saamu 63 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 63:1-11

Saamu 63

Saamu ti Dafidi. Nígbà tí ó wà nínú aginjù Juda.

1Ọlọ́run, ìwọ ni Ọlọ́run mi,

nígbà gbogbo ni mo ń ṣàfẹ́rí rẹ,

òǹgbẹ rẹ ń gbẹ ọkàn mi,

ara mi fà sí ọ,

ní ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tí ń ṣàárẹ̀

níbi tí kò sí omi.

2Èmi ti rí ọ ní ibi mímọ́,

mo rí agbára àti ògo rẹ.

3Nítorí ìfẹ́ rẹ dára ju ayé lọ,

ètè mi yóò fògo fún ọ.

4Èmi ó yìn ọ́ níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè,

èmi ó gbé ọwọ́ sókè, èmi ó sì pe orúkọ rẹ.

5A ó tẹ́ ọkàn mi lọ́rùn bí ọlọ́ràá oúnjẹ;

pẹ̀lú ètè ìyìn, ẹnu mi yóò yìn ọ́.

6Nígbà tí mo rántí rẹ lórí ibùsùn mi;

èmi ń ronú rẹ títí ìṣọ́ òru.

7Nítorí ìwọ ni ìrànlọ́wọ́ mi,

mo kọrin níbi òjìji ìyẹ́ apá rẹ.

8Ọkàn mí fà sí ọ:

ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbé mi ró.

9Àwọn tí ó ń wá ọkàn mí ni a ó parun;

wọn ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé.

10Wọn ó ti ọwọ́ idà ṣubú

wọn ó sì di jíjẹ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀.

11Ṣùgbọ́n ọba yóò yọ̀ nínú Ọlọ́run

ẹni tí ó fi orúkọ Ọlọ́run búra yóò ṣògo

ṣùgbọ́n ẹnu àwọn òpùrọ́ la ó pamọ́.