Saamu 62 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 62:1-12

Saamu 62

Fún adarí orin. Fun Jedutuni. Saamu Dafidi.

1Nínú Ọlọ́run nìkan ni ọkàn mi ti rí ìsinmi;

ìgbàlà mi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá.

2Òun nìkan ní àpáta mi àti ìgbàlà mi;

Òun ni ààbò mi, a kì yóò sí mi ní ipò padà.

3Ẹ̀yin ó ti máa kọ́lú ènìyàn kan pẹ́ tó?

Gbogbo yín ni ó fẹ́ pa á,

bí ògiri tí ó fẹ́ yẹ̀, àti bí ọgbà tí ń wó lọ?

4Kìkì èrò wọn ni láti bì ṣubú

kúrò nínú ọlá rẹ̀;

inú wọn dùn sí irọ́.

Wọ́n ń fi ẹnu wọn súre,

ṣùgbọ́n wọ́n ń gégùn ún nínú ọkàn wọn. Sela.

5Nínú Ọlọ́run nìkan ni ìsinmi wà, ìwọ Ọlọ́run mi.

Ìrètí mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ.

6Òun nìkan ní àpáta àti ìgbàlà mi;

Òun ni ààbò mi, a kì yóò ṣí mi ní ipò.

7Ìgbàlà mi àti ògo mi dúró nínú Ọlọ́run;

Òun ní àpáta ńlá mi, àti ààbò mi.

8Gbẹ́kẹ̀lé ní gbogbo ìgbà, ẹ̀yin ènìyàn;

tú ọkàn rẹ jáde sí i,

nítorí Ọlọ́run ni ààbò wa.

9Nítòótọ́, asán ni àwọn ọmọ ènìyàn, èké

sì ni àwọn olóyè, wọ́n gòkè nínú ìwọ̀n,

lápapọ̀ wọ́n jẹ́ èémí.

10Má ṣe gbẹ́kẹ̀lé ìnilára,

tàbí gbéraga nínú olè jíjà,

nítòótọ́ bí ọrọ̀ rẹ̀ ń pọ̀ sí i,

má ṣe gbẹ́kẹ̀ rẹ lé wọn.

11Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kejì, ni mo

gbọ́ èyí pé, ti Ọlọ́run ni agbára

1262.12: Jr 17.10; If 2.23; 22.12.Pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa, tìrẹ ni àánú

nítorí tí ìwọ san án fún olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.