Saamu 62 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 62:1-12

Saamu 62

Fún adarí orin. Fun Jedutuni. Saamu Dafidi.

1Nínú Ọlọ́run nìkan ni ọkàn mi ti rí ìsinmi;

ìgbàlà mi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá.

2Òun nìkan ní àpáta mi àti ìgbàlà mi;

Òun ni ààbò mi, a kì yóò sí mi ní ipò padà.

3Ẹ̀yin ó ti máa kọ́lú ènìyàn kan pẹ́ tó?

Gbogbo yín ni ó fẹ́ pa á,

bí ògiri tí ó fẹ́ yẹ̀, àti bí ọgbà tí ń wó lọ?

4Kìkì èrò wọn ni láti bì ṣubú

kúrò nínú ọlá rẹ̀;

inú wọn dùn sí irọ́.

Wọ́n ń fi ẹnu wọn súre,

ṣùgbọ́n wọ́n ń gégùn ún nínú ọkàn wọn. Sela.

5Nínú Ọlọ́run nìkan ni ìsinmi wà, ìwọ Ọlọ́run mi.

Ìrètí mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ.

6Òun nìkan ní àpáta àti ìgbàlà mi;

Òun ni ààbò mi, a kì yóò ṣí mi ní ipò.

7Ìgbàlà mi àti ògo mi dúró nínú Ọlọ́run;

Òun ní àpáta ńlá mi, àti ààbò mi.

8Gbẹ́kẹ̀lé ní gbogbo ìgbà, ẹ̀yin ènìyàn;

tú ọkàn rẹ jáde sí i,

nítorí Ọlọ́run ni ààbò wa.

9Nítòótọ́, asán ni àwọn ọmọ ènìyàn, èké

sì ni àwọn olóyè, wọ́n gòkè nínú ìwọ̀n,

lápapọ̀ wọ́n jẹ́ èémí.

10Má ṣe gbẹ́kẹ̀lé ìnilára,

tàbí gbéraga nínú olè jíjà,

nítòótọ́ bí ọrọ̀ rẹ̀ ń pọ̀ sí i,

má ṣe gbẹ́kẹ̀ rẹ lé wọn.

11Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kejì, ni mo

gbọ́ èyí pé, ti Ọlọ́run ni agbára

1262.12: Jr 17.10; If 2.23; 22.12.Pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa, tìrẹ ni àánú

nítorí tí ìwọ san án fún olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.

New International Reader’s Version

Psalm 62:1-12

Psalm 62

For the director of music. For Jeduthun. A psalm of David.

1It is surely true that I find my rest in God.

He is the God who saves me.

2It is surely true that he is my rock. He is the God who saves me.

He is like a fort to me. I will always be secure.

3How long will you enemies attack me?

Will all of you throw me down?

I’m like a leaning wall.

I’m like a fence about to fall.

4Surely my enemies only want to pull me down

from my place of honor.

They take delight in telling lies.

They bless me with what they say.

But in their hearts they ask for bad things to happen to me.

5Yes, I must find my rest in God.

He is the God who gives me hope.

6It is surely true that he is my rock and the God who saves me.

He is like a fort to me, so I will always be secure.

7I depend on God to save me and to honor me.

He is my mighty rock and my place of safety.

8Trust in him at all times, you people.

Tell him all your troubles.

God is our place of safety.

9Surely ordinary people are only a breath.

Important people are not what they seem to be.

If they were weighed on a scale, they wouldn’t amount to anything.

Together they are only a breath.

10Don’t trust in money you have taken from others.

Don’t put false hope in things you have stolen.

Even if your riches grow,

don’t put your trust in them.

11God, I have heard you say two things.

One is that power belongs to you, God.

12The other is that your love, Lord, never ends.

You will reward everyone

in keeping with what they have done.