Saamu 53 – YCB & NIVUK

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 53:1-6

Saamu 53

Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí mahalati. Maskili ti Dafidi.

153.1-3: Ro 3.10-12.53.1-6: Sm 14.1-7.Aṣiwèrè wí ní ọkàn rẹ̀ pé:

“Ọlọ́run kò sí.”

Wọ́n bàjẹ́, gbogbo ọ̀nà wọn sì burú;

kò sì ṣí ẹnìkan tí ń ṣe rere.

2Ọlọ́run bojú wo ilẹ̀ láti ọ̀run

sórí àwọn ọmọ ènìyàn,

láti wò bóyá ẹnìkan wà, tí ó ní òye,

tí ó sì ń wá Ọlọ́run.

3Gbogbo ènìyàn tí ó ti yí padà,

wọ́n ti parapọ̀ di ìbàjẹ́;

kò sí ẹnìkan tí ó ń ṣe rere, kò sí ẹnìkan.

4Ṣé àwọn oníṣẹ́ búburú kò ní ìmọ̀?

Àwọn ẹni tí ń jẹ ènìyàn mi, bí ẹni jẹun

tí wọn kò sì pe Ọlọ́run?

5Níbẹ̀ ni ìwọ gbé wà ní ìbẹ̀rù ńlá

níbi tí ẹ̀rù kò gbé sí,

nítorí Ọlọ́run tí fọ́n egungun àwọn tí ó dó tì ọ́ ká;

ìwọ tí dójútì wọ́n, nítorí Ọlọ́run ti kẹ́gàn wọn.

6Ìgbàlà Israẹli ìbá jáde wá láti Sioni!

Nígbà tí Ọlọ́run bá mú ohun ìní àwọn ènìyàn rẹ̀ padà,

jẹ́ kí Jakọbu yọ̀ kí inú Israẹli sì máa dùn!

New International Version – UK

Psalms 53:1-6

Psalm 53In Hebrew texts 53:1-6 is numbered 53:2-7.

For the director of music. According to mahalath.Title: Probably a musical term A maskilTitle: Probably a literary or musical term of David.

1The fool says in his heart,

‘There is no God.’

They are corrupt, and their ways are vile;

there is no-one who does good.

2God looks down from heaven

on all mankind

to see if there are any who understand,

any who seek God.

3Everyone has turned away, all have become corrupt;

there is no-one who does good,

not even one.

4Do all these evildoers know nothing?

They devour my people as though eating bread;

they never call on God.

5But there they are, overwhelmed with dread,

where there was nothing to dread.

God scattered the bones of those who attacked you;

you put them to shame, for God despised them.

6Oh, that salvation for Israel would come out of Zion!

When God restores his people,

let Jacob rejoice and Israel be glad!