Saamu 53 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 53:1-6

Saamu 53

Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí mahalati. Maskili ti Dafidi.

153.1-3: Ro 3.10-12.53.1-6: Sm 14.1-7.Aṣiwèrè wí ní ọkàn rẹ̀ pé:

“Ọlọ́run kò sí.”

Wọ́n bàjẹ́, gbogbo ọ̀nà wọn sì burú;

kò sì ṣí ẹnìkan tí ń ṣe rere.

2Ọlọ́run bojú wo ilẹ̀ láti ọ̀run

sórí àwọn ọmọ ènìyàn,

láti wò bóyá ẹnìkan wà, tí ó ní òye,

tí ó sì ń wá Ọlọ́run.

3Gbogbo ènìyàn tí ó ti yí padà,

wọ́n ti parapọ̀ di ìbàjẹ́;

kò sí ẹnìkan tí ó ń ṣe rere, kò sí ẹnìkan.

4Ṣé àwọn oníṣẹ́ búburú kò ní ìmọ̀?

Àwọn ẹni tí ń jẹ ènìyàn mi, bí ẹni jẹun

tí wọn kò sì pe Ọlọ́run?

5Níbẹ̀ ni ìwọ gbé wà ní ìbẹ̀rù ńlá

níbi tí ẹ̀rù kò gbé sí,

nítorí Ọlọ́run tí fọ́n egungun àwọn tí ó dó tì ọ́ ká;

ìwọ tí dójútì wọ́n, nítorí Ọlọ́run ti kẹ́gàn wọn.

6Ìgbàlà Israẹli ìbá jáde wá láti Sioni!

Nígbà tí Ọlọ́run bá mú ohun ìní àwọn ènìyàn rẹ̀ padà,

jẹ́ kí Jakọbu yọ̀ kí inú Israẹli sì máa dùn!