Saamu 52 – YCB & CST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 52:1-9

Saamu 52

Fún adarí orin. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí Doegi ará Edomu tọ Saulu lọ láti sọ fún pé, “Dafidi wà ní ilé Ahimeleki.”

1Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe féfé nínú ìwà ìkà, ìwọ alágbára ọkùnrin?

Èéṣe tí ìwọ fi ń gbéraga nígbà gbogbo,

ìwọ ẹni ẹ̀gàn níwájú Ọlọ́run?

2Ahọ́n rẹ̀ ń gbìmọ̀ ìparun;

ó dàbí abẹ mímú,

ìwọ ẹni tí ń hùwà ẹ̀tàn.

3Ìwọ fẹ́ràn ibi ju ìre lọ,

àti èké ju kí ó sọ òtítọ́ lọ.

4Ìwọ fẹ́ràn ọ̀rọ̀ ìpanilára gbogbo,

ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn!

5Ọlọ́run yóò sì lù ọ́ bolẹ̀ láéláé,

yóò sì dì ọ́ mú,

yóò sì já ọ kúrò ni ibùjókòó rẹ,

yóò sì fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè. Sela.

6Àwọn olódodo yóò rí, wọn yóò sì bẹ̀rù

wọn yóò sì rẹ́rìn-ín rẹ̀, wí pé,

7“Èyí ni ọkùnrin náà ti kò fi Ọlọ́run ṣe agbára rẹ̀,

bí kò ṣe ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ rẹ̀ ni ó gbẹ́kẹ̀lé,

ó sì mu ara rẹ̀ le nínú ìwà búburú rẹ̀.”

8Ṣùgbọ́n èmi dàbí igi Olifi

tí ó gbilẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run;

Èmi gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọ́run tí kì í kùnà

láé àti láéláé.

9Èmi yóò yìn ọ títí fún ohun tí ó ti ṣe;

èmi ní ìrètí nínú orúkọ rẹ,

nítorí orúkọ rẹ dára.

Èmi yóò yìn ọ́ níwájú àwọn ènìyàn mímọ́.

Nueva Versión Internacional (Castilian)

Salmo 52:1-9

Salmo 52

Al director musical. Masquil de David, cuando Doeg el edomita fue a informarle a Saúl: «David ha ido a la casa de Ajimélec».

1¿Prepotente, por qué te jactas de tu maldad?

¡El amor de Dios es constante!

2Tu lengua, como navaja afilada,

trama destrucción y practica el engaño.

3Más que el bien, amas la maldad;

más que la verdad, amas la mentira. Selah

4Lengua embustera,

te encanta ofender con tus palabras.

5Pero Dios te arruinará para siempre;

te tomará y te arrojará de tu hogar;

¡te arrancará del mundo de los vivos! Selah

6Los justos verán esto, y temerán;

entre burlas dirán de él:

7«¡Aquí tenéis al hombre

que no buscó refugio en Dios,

sino que confió en su gran riqueza

y se afirmó en su maldad!»

8Pero yo soy como un olivo verde

que florece en la casa de Dios;

yo confío en el gran amor de Dios

eternamente y para siempre.

9En todo tiempo te alabaré por tus obras;

en ti pondré mi esperanza en presencia de tus fieles,

porque tu nombre es bueno.