Saamu 51 – YCB & CST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 51:1-19

Saamu 51

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Nígbà ti wòlíì Natani tọ wá, lẹ́yìn tí Dafidi dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè rẹ̀ pẹ̀lú Batṣeba.

1Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí

ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ̀,

gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ àánú rẹ̀

kí o sì pa gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.

2Wẹ gbogbo àìṣedéédéé mi nù kúrò

kí o sì wẹ̀ mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi!

3Nítorí mo mọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi,

nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi wà níwájú mi.

451.4: Ro 3.4.Sí ọ, ìwọ nìkan ṣoṣo, ni mo dẹ́ṣẹ̀ sí

ni mo sì ṣe búburú níwájú rẹ̀,

kí a lè dá ọ láre nígbà tí ìwọ bá ń sọ̀rọ̀,

kí o sì le wà láìlẹ́bi, nígbà tí ìwọ bá ń ṣe ìdájọ́.

5Nítòótọ́, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni a ti bí mi,

nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mí sì lóyún mi.

6Nítòótọ́ ìwọ fẹ́ òtítọ́ ní inú;

ìwọ kọ́ mi ní ọgbọ́n ní ìhà ìkọ̀kọ̀.

7Wẹ̀ mí pẹ̀lú ewé hísópù, èmi yóò sì mọ́;

fọ̀ mí, èmi yóò sì funfun ju yìnyín lọ.

8Jẹ́ kí n gbọ́ ayọ̀ àti inú dídùn;

jẹ́ kí gbogbo egungun tí ìwọ ti run kí ó máa yọ̀.

9Pa ojú rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi

kí o sì pa gbogbo àwọn àìṣedéédéé mi rẹ́.

10Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run,

kí o sì tún ẹ̀mí dídúró ṣinṣin ṣe sínú mi.

11Má ṣe jù mi nù kúrò níwájú rẹ,

kí o má ṣe gba ẹ̀mí mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.

12Mú ayọ̀ ìgbàlà rẹ tọ̀ mí wá,

kí o sì fún mi ní ẹ̀mí ìfẹ́, tí yóò mú mi dúró.

13Nígbà náà ni èmi yóò máa kọ́ àwọn olùrékọjá ní ọ̀nà rẹ,

àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò sì yí padà sí ọ.

14Gbà mí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀, Ọlọ́run,

ìwọ Ọlọ́run ìgbàlà mi,

ahọ́n mi yóò sì máa kọrin òdodo rẹ kíkan.

15Olúwa, ṣí mi ní ètè mi gbogbo,

àti ẹnu mi yóò sì máa kéde ìyìn rẹ.

16Nítorí ìwọ kò ní inú dídùn sí ẹbọ, tí èmi kò bá mú wá;

Ìwọ kò ní inú dídùn sí ọrẹ ẹbọ sísun.

17Ẹbọ Ọlọ́run ni ìròbìnújẹ́ ọkàn ìròbìnújẹ́ àti ìrora àyà.

18Ṣe rere ní dídùn inú rẹ sí Sioni,

ṣe rere; tún odi Jerusalẹmu mọ.

19Nígbà náà ni inú rẹ yóò dùn sí ẹbọ òdodo,

pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ọrẹ ẹbọ sísun,

nígbà náà ni wọn yóò fi akọ màlúù rú ẹbọ lórí pẹpẹ rẹ.

Nueva Versión Internacional (Castilian)

Salmo 51:1-19

Salmo 51

Al director musical. Salmo de David, cuando el profeta Natán fue a verlo por haber cometido David adulterio con Betsabé.

1Ten compasión de mí, oh Dios,

conforme a tu gran amor;

conforme a tu inmensa bondad,

borra mis transgresiones.

2Lávame de toda mi maldad

y límpiame de mi pecado.

3Yo reconozco mis transgresiones;

siempre tengo presente mi pecado.

4Contra ti he pecado, solo contra ti,

y he hecho lo que es malo ante tus ojos;

por eso, tu sentencia es justa,

y tu juicio, irreprochable.

5Yo sé que soy malo de nacimiento;

pecador me concibió mi madre.

6Yo sé que tú amas la verdad en lo íntimo;

en lo secreto me has enseñado sabiduría.

7Purifícame con hisopo, y quedaré limpio;

lávame, y quedaré más blanco que la nieve.

8Anúnciame gozo y alegría;

infunde gozo en estos huesos que has quebrantado.

9Aparta tu rostro de mis pecados

y borra toda mi maldad.

10Crea en mí, oh Dios, un corazón limpio,

y renueva la firmeza de mi espíritu.

11No me alejes de tu presencia

ni me quites tu santo Espíritu.

12Devuélveme la alegría de tu salvación;

que un espíritu obediente me sostenga.

13Así enseñaré a los transgresores tus caminos,

y los pecadores se volverán a ti.

14Dios mío, Dios de mi salvación,

líbrame de derramar sangre,

y mi lengua alabará tu justicia.

15Abre, Señor, mis labios,

y mi boca proclamará tu alabanza.

16Tú no te deleitas en los sacrificios

ni te complacen los holocaustos;

de lo contrario, te los ofrecería.

17El sacrificio que te agrada

es un espíritu quebrantado;

tú, oh Dios, no desprecias

al corazón quebrantado y arrepentido.

18En tu buena voluntad, haz que prospere Sión;

levanta los muros de Jerusalén.

19Entonces te agradarán los sacrificios de justicia,

los holocaustos del todo quemados,

y sobre tu altar se ofrecerán becerros.