Saamu 42 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 42:1-11

ÌWÉ KEJÌ

Saamu 42–72

Saamu 42

Fún adarí orin. Maskili ti àwọn ọmọ Kora.

1Bí àgbọ̀nrín ti ń mí hẹlẹ sí ipa odò omi,

bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń mí hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run.

2Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè.

Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?

3Oúnjẹ mi ni omijé mi

ní ọ̀sán àti ní òru,

nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́ pé,

“Ọlọ́run rẹ dà?”

4Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí,

èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi:

èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ,

èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́run

pẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn,

pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.

5Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi?

Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi?

Ìwọ ṣe ìrètí ní ti Ọlọ́run,

nítorí èmi yóò sá à máa yìn ín,

Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.

6Ọlọ́run mi, ọkàn mi ń rẹ̀wẹ̀sì nínú mi:

nítorí náà, èmi ó rántí rẹ

láti ilẹ̀ Jordani wá,

láti Hermoni láti òkè Mibsari.

7Ibú omi ń pe ibú omi

nípa híhó omi ṣíṣàn rẹ̀

gbogbo rírú omi àti bíbì omi rẹ̀

bò mí mọ́lẹ̀.

8Ní ọ̀sán ní Olúwa ran ìfẹ́ rẹ̀,

àti ni àṣálẹ́ ni orin rẹ̀ wà pẹ̀lú mi

àdúrà sí Ọlọ́run ayé mi.

9Èmi wí fún Ọlọ́run àpáta mi,

“Èéṣe tí ìwọ fi gbàgbé mi?

Èéṣe tí èmi o fi máa rìn nínú ìbànújẹ́,

nítorí ìnilára ọ̀tá?”

10Bí ẹni pé idà egungun mi ni ẹ̀gàn tí

àwọn ọ̀tá mi ń gàn mí,

Bí wọn ti ń béèrè ní gbogbo ọjọ́.

“Níbo ni Ọlọ́run rẹ wà?”

11Èéṣe tí ìwọ fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi?

Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi?

Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run,

nítorí èmi yóò sì máa yìn ín, Òun ni

Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.