Saamu 41 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 41:1-13

Saamu 41

Fún adarí orin. Saamu Dafidi.

1Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ń ro ti aláìní:

Olúwa yóò gbà á ní ìgbà ìpọ́njú.

2Olúwa yóò dáàbò bò ó yóò sì pa ọkàn rẹ̀ mọ́:

yóò bùkún fún un ní orí ilẹ̀

kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀.

3Olúwa yóò gbà á lórí àkéte àìsàn rẹ̀

yóò sì mú un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn rẹ̀.

4Ní ti èmi, mo wí pé “Olúwa, ṣàánú fún mi;

wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.

5Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi nínú àrankàn, pé

“Nígbà wo ni yóò kú, ti orúkọ rẹ̀ yóò sì run?”

6Nígbàkígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí,

wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara rẹ̀;

nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kálẹ̀.

7Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi;

èmi ni wọ́n ń gbìmọ̀ ibi sí,

8wọ́n wí pé, “Ohun búburú ni ó dì mọ́ ọn ṣinṣin

àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí,

kì yóò dìde mọ́.”

941.9: Jh 13.18.Pàápàá, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé,

ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi,

tí gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sókè sí mi.

10Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa, ṣàánú fún mi;

gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.

11Èmi mọ̀ pé inú rẹ̀ dùn sí mi,

nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.

12Bí ó ṣe tèmi ni

ìwọ dì mímú nínú ìwà òtítọ́ mi

ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú rẹ títí láé.

13Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli

láé àti láéláé.

Àmín àti Àmín.