Saamu 37 – YCB & JCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 37:1-40

Saamu 37

Ti Dafidi.

1Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú,

kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;

2nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko,

wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.

3Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere;

torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.

4Ṣe inú dídùn sí Olúwa;

òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.

5Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́;

gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.

6Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀,

àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.

7Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa,

kí o sì fi sùúrù dúró dè é;

má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn,

nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.

8Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀,

má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.

9Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò,

ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.

10Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀;

nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.

11Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.

12Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́,

wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;

13ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú,

nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.

14Ènìyàn búburú fa idà yọ,

wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn,

láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀,

láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.

15Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ,

àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.

16Ohun díẹ̀ tí olódodo ní,

sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;

17nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú,

ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.

18Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin,

àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé;

19Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi,

àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.

20Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé.

Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù;

wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.

21Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà,

ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;

22Nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.

23Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá,

o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;

24Bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá,

nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.

25Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà;

síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀,

tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.

26Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni;

a sì máa bùsi i fún ni.

27Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere;

nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.

28Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́,

kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀.

Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé,

ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.

29Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.

30Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,

ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.

31Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn;

àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.

32Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo,

Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.

33Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi,

nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.

34Dúró de Olúwa,

kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́.

Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà;

nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.

35Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà,

ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,

36ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́;

bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.

37Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin;

nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.

38Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀;

ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.

39Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa;

òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú

40Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n;

yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là,

nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.

Japanese Contemporary Bible

詩篇 37:1-40

37

1悪者をうらやんではいけません。

2しょせん、草のようにあっという間に枯れ、

消え失せる存在なのですから。

3主に信頼して人を思いやり、親切にしなさい。

そうすれば、この地に安住し、

成功を収めることもできます。

4主を喜びとしなさい。

主は心の願いをみな、かなえてくださいます。

5自分のしようとすることをみな、主にゆだねなさい。

信頼する者を、主は助けてくださいます。

6あなたの潔白は、だれの目にも明らかになります。

神は、真昼の太陽のように

まぶしい正義の光をあてて、弁護してくださいます。

7すべてを主にゆだねて、安心しなさい。

神が立ち上がるまで、忍耐して待つのです。

悪者どもの繁栄ぶりをねたんではいけません。

8怒るのをやめ、憤りを捨てなさい。

くよくよと思い悩んではいけません。

自分に害をもたらすだけです。

9悪者は滅ぼされますが、

神に信頼する者には祝福が降り注ぎます。

10もうしばらくすれば、

見ようとしても、悪者の姿は見つけられなくなります。

11一方、神の前に謙遜な人は、

ありとあらゆる祝福を受け、

心地よい平安に身をゆだねるのです。

12-13神は、ご自分を信じる人を陥れようと企む者を

笑われます。

彼らのさばかれる日が近いのをご存じだからです。

14悪者どもは貧しい者のいのちをつけねらい、

正義の人を殺そうと身構えています。

15しかし、彼らの剣は自分の心臓を突き刺し、

その武器はみな砕かれます。

16不正な手段で金持ちになるより、

わずかな持ち物に甘んじて、

神を敬って過ごすほうがまさっています。

17悪者の腕はへし折られますが、

罪を赦された人は主に守られて暮らせるからです。

18主は毎日、神を敬う人の善行をごらんになり、

永遠のほうびをお与えになるのです。

19彼らは逆境のときにも、神に守られています。

ききんの年にも飽き足りることができるのです。

20しかし、悪者は滅びます。

主に敵対する者は草のようにしおれ、

煙のようにはかないのです。

21悪者は借りても、返済できません。

しかし、正しい人は施しができるまでになります。

22主に祝福された人はこの地上を相続しますが、

のろわれた者は滅びます。

23正しい人は、主の導きに従って歩みます。

主はその一歩一歩をお喜びになるのです。

24たとえ倒れても、それで終わりではありません。

主がしっかり支えておられるからです。

25以前は若かった私も、今では年をとりました。

しかしこの間、神がご自身を愛する者を

お見捨てになったり、

神を敬う人の子どもを空腹のまま

放っておかれたりする光景を、

一度も目にしたことはありません。

26むしろ、神を敬う人は

惜しげもなく人々にふるまい、金を貸しており、

その祝福が子どもにまで及ぶのを見ました。

27永遠の住まいに行きたいと願うなら、

卑劣な悪の道を捨て、正しい生活を送りなさい。

28主は正義と公平を愛されるからです。

神はご自分の民を決してお見捨てになりません。

その人々は永遠に安全を保証されているのです。

反対に、悪の道を慕う者は滅びます。

29神を敬う人はこの地に植えられて根を張り、

永遠に住むのです。

30-31神を敬う人は正しく公平で、

善悪をわきまえているため、

すぐれた相談役を務めます。

32悪者どもは神を敬う人をつけねらい、

何とか訴える口実を見つけ、

死罪に追い込もうと目を光らせます。

33しかし、悪者どもの思いどおりになるのを、

主が見過ごされるはずがありません。

神を敬う人は、

法廷に引き出されるようなことがあっても、

有罪の判決を受けることはありません。

34主が立ち上がってくださる時を、

じっと忍耐して待ちなさい。

そして、神の道をしっかり歩んで行くのです。

やがて、神が祝福をあふれるばかりに注ぎ、

あなたの名声を高めてくださる時がきます。

しかも、あなたは悪者が滅ぼされるのを

目の当たりにするのです。

35-36この光景は私自身も目にしました。

そびえ立つレバノン杉のように、

おごり高ぶった悪者が、

次の瞬間には影も形もなくなっていたのです。

ひとみをこらして捜しましたが、

その姿は消え失せていました。

37それに引き替え、正しい人はどうでしょう。

非の打ちどころもなく高潔で、

平和を愛するその人の未来は美しく輝いています。

すばらしい晩年が待っているのです。

38しかし、悪者は滅ぼされ、子孫は根絶やしにされます。

39神を敬う人は救われます。

苦しみのとき、主は救いとなり、

とりでとなってくださるのです。

40主は、ご自分に頼る者を助け、

悪者の策略から守ってくださいます。