Saamu 34 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 34:1-22

Saamu 34

Tí Dafidi. Nígbà tí ó díbọ́n bí ẹni tí ń ṣe wèrè níwájú Abimeleki, ẹni tí ó lé e lọ, ó sì jáde lọ.

1Èmi yóò máa fi ìbùkún fún Olúwa nígbà gbogbo;

ìyìn rẹ̀ yóò máa wà ní ẹnu mi títí láé.

2Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú Olúwa;

jẹ́ kí àwọn onírẹ̀lẹ̀ gbọ́ kí inú wọn kí ó sì máa dùn.

3Gbé Olúwa ga pẹ̀lú mi;

kí ẹ sì jẹ́ kí a jọ gbé orúkọ rẹ̀ lékè.

4Èmi wá Olúwa, ó sì dá mi lóhùn;

Ó sì gbà mí kúrò nínú ìbẹ̀rù mi gbogbo.

5Wọ́n wò ó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn;

ojú kò sì tì wọ́n.

6Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, Olúwa sì gbóhùn rẹ̀;

ó sì gbà á là kúrò nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.

7Angẹli Olúwa yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká

ó sì gbà wọ́n.

8Tọ́ ọ wò kí o sì rí i wí pé Olúwa dára;

ẹni ayọ̀ ni ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ààbò nínú rẹ̀.

9Ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́,

nítorí pé kò sí àìní fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.

10Àwọn ọmọ kìnnìún a máa ṣe aláìní ebi a sì máa pa wọ́n;

ṣùgbọ́n àwọn tí ó wá Olúwa kì yóò ṣe aláìní ohun tí ó dára.

11Wá, ẹ̀yin ọmọ mi, fi etí sí mi;

èmi yóò kọ́ ọ yín ní ẹ̀rù Olúwa.

1234.12-16: 1Pt 3.10-12.Ta ni nínú yín tí ń fẹ́ ìyè, tí ó sì ń fẹ́ ọjọ́ púpọ̀;

kí ó lè gbádùn ọjọ́ rere?

13Pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi

àti ètè rẹ̀ kúrò ní ẹ̀tàn sísọ.

14Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere;

wá àlàáfíà, kí o sì lépa rẹ̀.

15Ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo;

etí i rẹ̀ sì ṣí sí ẹkún wọn.

16Ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú;

láti ké ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.

17Nígbà tí olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́,

Olúwa a máa gbọ́, a sì yọ wọ́n jáde láti inú gbogbo wàhálà wọn.

18Olúwa súnmọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn;

ó sì gba irú àwọn tí í ṣe oníròra ọkàn là.

19Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀,

ṣùgbọ́n Olúwa gbà wọ́n kúrò nínú gbogbo rẹ̀.

20Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́;

kò sí ọ̀kan tí ó dá nínú wọn.

21Ibi ni ó mú ikú ìkà wá,

àti àwọn tí ó kórìíra olódodo ni yóò jẹ̀bi.

22Olúwa ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ padà;

kò sí ọ̀kan nínú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé tí yóò jẹ̀bi.

Nova Versão Internacional

Salmos 34:1-22

Salmo 3434 O salmo 34 é um poema organizado em ordem alfabética, no hebraico.

De Davi, quando ele se fingiu de louco diante de Abimeleque—que o expulsou—e depois partiu.

1Bendirei o Senhor o tempo todo!

Os meus lábios sempre o louvarão.

2Minha alma se gloriará no Senhor;

ouçam os oprimidos e se alegrem.

3Proclamem a grandeza do Senhor comigo;

juntos exaltemos o seu nome.

4Busquei o Senhor, e ele me respondeu;

livrou-me de todos os meus temores.

5Os que olham para ele estão radiantes de alegria;

seu rosto jamais mostrará decepção.

6Este pobre homem clamou,

e o Senhor o ouviu;

e o libertou de todas as suas tribulações.

7O anjo do Senhor é sentinela ao redor

daqueles que o temem, e os livra.

8Provem e vejam como o Senhor é bom.

Como é feliz o homem que nele se refugia!

9Temam o Senhor, vocês que são os seus santos,

pois nada falta aos que o temem.

10Os leões34.10 A Septuaginta e a Versão Siríaca dizem ricos. podem passar necessidade e fome,

mas os que buscam o Senhor de nada têm falta.

11Venham, meus filhos, ouçam-me;

eu ensinarei a vocês o temor do Senhor.

12Quem de vocês quer amar a vida

e deseja ver dias felizes?

13Guarde a sua língua do mal

e os seus lábios da falsidade.

14Afaste-se do mal e faça o bem;

busque a paz com perseverança.

15Os olhos do Senhor voltam-se para os justos

e os seus ouvidos estão atentos ao seu grito de socorro;

16o rosto do Senhor volta-se contra os que praticam o mal,

para apagar da terra a memória deles.

17Os justos clamam, o Senhor os ouve

e os livra de todas as suas tribulações.

18O Senhor está perto dos que têm o coração quebrantado

e salva os de espírito abatido.

19O justo passa por muitas adversidades,

mas o Senhor o livra de todas;

20protege todos os seus ossos;

nenhum deles será quebrado.

21A desgraça matará os ímpios;34.21 Ou Os ímpios serão mortos nas suas próprias maldades;

os que odeiam o justo serão condenados.

22O Senhor redime a vida dos seus servos;

ninguém que nele se refugia será condenado.