Saamu 34
Tí Dafidi. Nígbà tí ó díbọ́n bí ẹni tí ń ṣe wèrè níwájú Abimeleki, ẹni tí ó lé e lọ, ó sì jáde lọ.
1Èmi yóò máa fi ìbùkún fún Olúwa nígbà gbogbo;
ìyìn rẹ̀ yóò máa wà ní ẹnu mi títí láé.
2Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú Olúwa;
jẹ́ kí àwọn onírẹ̀lẹ̀ gbọ́ kí inú wọn kí ó sì máa dùn.
3Gbé Olúwa ga pẹ̀lú mi;
kí ẹ sì jẹ́ kí a jọ gbé orúkọ rẹ̀ lékè.
4Èmi wá Olúwa, ó sì dá mi lóhùn;
Ó sì gbà mí kúrò nínú ìbẹ̀rù mi gbogbo.
5Wọ́n wò ó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn;
ojú kò sì tì wọ́n.
6Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, Olúwa sì gbóhùn rẹ̀;
ó sì gbà á là kúrò nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
7Angẹli Olúwa yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká
ó sì gbà wọ́n.
8Tọ́ ọ wò kí o sì rí i wí pé Olúwa dára;
ẹni ayọ̀ ni ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ààbò nínú rẹ̀.
9Ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́,
nítorí pé kò sí àìní fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
10Àwọn ọmọ kìnnìún a máa ṣe aláìní ebi a sì máa pa wọ́n;
ṣùgbọ́n àwọn tí ó wá Olúwa kì yóò ṣe aláìní ohun tí ó dára.
11Wá, ẹ̀yin ọmọ mi, fi etí sí mi;
èmi yóò kọ́ ọ yín ní ẹ̀rù Olúwa.
1234.12-16: 1Pt 3.10-12.Ta ni nínú yín tí ń fẹ́ ìyè, tí ó sì ń fẹ́ ọjọ́ púpọ̀;
kí ó lè gbádùn ọjọ́ rere?
13Pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi
àti ètè rẹ̀ kúrò ní ẹ̀tàn sísọ.
14Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere;
wá àlàáfíà, kí o sì lépa rẹ̀.
15Ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo;
etí i rẹ̀ sì ṣí sí ẹkún wọn.
16Ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú;
láti ké ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
17Nígbà tí olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́,
Olúwa a máa gbọ́, a sì yọ wọ́n jáde láti inú gbogbo wàhálà wọn.
18Olúwa súnmọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn;
ó sì gba irú àwọn tí í ṣe oníròra ọkàn là.
19Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀,
ṣùgbọ́n Olúwa gbà wọ́n kúrò nínú gbogbo rẹ̀.
20Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́;
kò sí ọ̀kan tí ó dá nínú wọn.
21Ibi ni ó mú ikú ìkà wá,
àti àwọn tí ó kórìíra olódodo ni yóò jẹ̀bi.
22Olúwa ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ padà;
kò sí ọ̀kan nínú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé tí yóò jẹ̀bi.
Salmo 3434 O salmo 34 é um poema organizado em ordem alfabética, no hebraico.
De Davi, quando ele se fingiu de louco diante de Abimeleque—que o expulsou—e depois partiu.
1Bendirei o Senhor o tempo todo!
Os meus lábios sempre o louvarão.
2Minha alma se gloriará no Senhor;
ouçam os oprimidos e se alegrem.
3Proclamem a grandeza do Senhor comigo;
juntos exaltemos o seu nome.
4Busquei o Senhor, e ele me respondeu;
livrou-me de todos os meus temores.
5Os que olham para ele estão radiantes de alegria;
seu rosto jamais mostrará decepção.
6Este pobre homem clamou,
e o Senhor o ouviu;
e o libertou de todas as suas tribulações.
7O anjo do Senhor é sentinela ao redor
daqueles que o temem, e os livra.
8Provem e vejam como o Senhor é bom.
Como é feliz o homem que nele se refugia!
9Temam o Senhor, vocês que são os seus santos,
pois nada falta aos que o temem.
10Os leões34.10 A Septuaginta e a Versão Siríaca dizem ricos. podem passar necessidade e fome,
mas os que buscam o Senhor de nada têm falta.
11Venham, meus filhos, ouçam-me;
eu ensinarei a vocês o temor do Senhor.
12Quem de vocês quer amar a vida
e deseja ver dias felizes?
13Guarde a sua língua do mal
e os seus lábios da falsidade.
14Afaste-se do mal e faça o bem;
busque a paz com perseverança.
15Os olhos do Senhor voltam-se para os justos
e os seus ouvidos estão atentos ao seu grito de socorro;
16o rosto do Senhor volta-se contra os que praticam o mal,
para apagar da terra a memória deles.
17Os justos clamam, o Senhor os ouve
e os livra de todas as suas tribulações.
18O Senhor está perto dos que têm o coração quebrantado
e salva os de espírito abatido.
19O justo passa por muitas adversidades,
mas o Senhor o livra de todas;
20protege todos os seus ossos;
nenhum deles será quebrado.
21A desgraça matará os ímpios;34.21 Ou Os ímpios serão mortos nas suas próprias maldades;
os que odeiam o justo serão condenados.
22O Senhor redime a vida dos seus servos;
ninguém que nele se refugia será condenado.