Saamu 3 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 3:1-8

Saamu 3

Saamu ti Dafidi. Nígbà ti ó sá fún ọmọ rẹ̀ Absalomu.

1Olúwa, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí!

Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó!

2Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé

“Ọlọ́run kò nígbà á là.” Sela.

3Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, Olúwa;

ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè.

4Olúwa ni mo kígbe sókè sí,

ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. Sela.

5Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn;

mo sì tún padà jí, nítorí Olúwa ni ó ń gbé mi ró.

6Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹgbẹ̀rún ènìyàn

tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká.

7Dìde, Olúwa!

Gbà mí, Ọlọ́run mi!

Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n;

kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú.

8Láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìgbàlà ti wá.

Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. Sela.

New International Reader’s Version

Psalm 3:1-8

Psalm 3

A psalm of David when he ran away from his son Absalom.

1Lord, I have so many enemies!

So many people are rising up against me!

2Many are saying about me,

“God will not save him.”

3Lord, you are like a shield that keeps me safe.

You bring me honor. You help me win the battle.

4I call out to the Lord.

He answers me from his holy mountain.

5I lie down and sleep.

I wake up again, because the Lord takes care of me.

6I won’t be afraid even though tens of thousands

attack me on every side.

7Lord, rise up!

My God, save me!

Strike all my enemies in the face.

Break the teeth of sinful people.

8Lord, you are the one who saves.

May your blessing be on your people.