Saamu 3 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 3:1-8

Saamu 3

Saamu ti Dafidi. Nígbà ti ó sá fún ọmọ rẹ̀ Absalomu.

1Olúwa, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí!

Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó!

2Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé

“Ọlọ́run kò nígbà á là.” Sela.

3Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, Olúwa;

ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè.

4Olúwa ni mo kígbe sókè sí,

ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. Sela.

5Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn;

mo sì tún padà jí, nítorí Olúwa ni ó ń gbé mi ró.

6Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹgbẹ̀rún ènìyàn

tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká.

7Dìde, Olúwa!

Gbà mí, Ọlọ́run mi!

Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n;

kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú.

8Láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìgbàlà ti wá.

Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. Sela.