Saamu 136 – YCB & KJV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 136:1-26

Saamu 136

1Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

2Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run àwọn ọlọ́run:

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

3Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa àwọn olúwa,

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

4Fún Òun nìkan tí ń ṣiṣẹ́ ìyanu ńlá;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

5Fún ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

6136.6: Gẹ 1.2.Fún ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lórí omi;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

7136.7-9: Gẹ 1.16.Fún ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

8Òòrùn láti jẹ ọba ọ̀sán;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

9Òṣùpá àti ìràwọ̀ láti jẹ ọba òru;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

10136.10: Ek 12.29.Fún ẹni tí ó kọlu Ejibiti lára àwọn àkọ́bí wọn;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

11136.11: Ek 12.51.Ó sì mú Israẹli jáde kúrò láàrín wọn;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

12Pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

13136.13-15: Ek 14.21-29.Fún ẹni tí ó pín Òkun pupa ní ìyà;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

14Ó sì mú Israẹli kọjá láàrín rẹ̀

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

15Ṣùgbọ́n ó bi Farao àti ogun rẹ̀ ṣubú nínú Òkun pupa;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

16Fún ẹni tí ó sin àwọn ènìyàn rẹ̀ la aginjù já

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

17Fún ẹni tí ó kọlu àwọn ọba ńlá;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

18Ó sì pa àwọn ọba olókìkí

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

19Sihoni, ọba àwọn ará Amori

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

20Àti Ogu, ọba Baṣani;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

21Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

22Ìní fún Israẹli, ìránṣẹ́ rẹ̀,

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

23Ẹni tí ó rántí wa ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ wa;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

24Ó sì dá wa ní ìdè lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

25Ẹni tí ó fi oúnjẹ fún àwọn ẹ̀dá gbogbo

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

26Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

King James Version

Psalms 136:1-26

1O give thanks unto the LORD; for he is good: for his mercy endureth for ever.

2O give thanks unto the God of gods: for his mercy endureth for ever.

3O give thanks to the Lord of lords: for his mercy endureth for ever.

4To him who alone doeth great wonders: for his mercy endureth for ever.

5To him that by wisdom made the heavens: for his mercy endureth for ever.

6To him that stretched out the earth above the waters: for his mercy endureth for ever.

7To him that made great lights: for his mercy endureth for ever:

8The sun to rule by day: for his mercy endureth for ever:136.8 to rule…: Heb. for the rulings by day

9The moon and stars to rule by night: for his mercy endureth for ever.

10To him that smote Egypt in their firstborn: for his mercy endureth for ever:

11And brought out Israel from among them: for his mercy endureth for ever:

12With a strong hand, and with a stretched out arm: for his mercy endureth for ever.

13To him which divided the Red sea into parts: for his mercy endureth for ever:

14And made Israel to pass through the midst of it: for his mercy endureth for ever:

15But overthrew Pharaoh and his host in the Red sea: for his mercy endureth for ever.136.15 overthrew: Heb. shaked off

16To him which led his people through the wilderness: for his mercy endureth for ever.

17To him which smote great kings: for his mercy endureth for ever:

18And slew famous kings: for his mercy endureth for ever:

19Sihon king of the Amorites: for his mercy endureth for ever:

20And Og the king of Bashan: for his mercy endureth for ever:

21And gave their land for an heritage: for his mercy endureth for ever:

22Even an heritage unto Israel his servant: for his mercy endureth for ever.

23Who remembered us in our low estate: for his mercy endureth for ever:

24And hath redeemed us from our enemies: for his mercy endureth for ever.

25Who giveth food to all flesh: for his mercy endureth for ever.

26O give thanks unto the God of heaven: for his mercy endureth for ever.