Òwe 1 – YCB & KJV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 1:1-33

Èròǹgbà àti kókó-ọ̀rọ̀

1Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.

2Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́,

Láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.

3Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo,

àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;

4láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀,

ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.

5Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀,

sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.

6Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe,

àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.

7Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀,

ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.

Ọ̀rọ̀ ìyànjú láti ṣàfẹ́rí ọgbọ́n

8Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ,

má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.

9Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ

àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.

10Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́,

má ṣe gbà fún wọn.

11Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa;

jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan,

jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;

12Jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú,

àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò;

13A ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí

a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa;

14Da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa,

a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà”

15Ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ,

má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn;

16Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀,

wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.

17Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀,

ní ojú ẹyẹ!

18Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn.

Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà

19Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́;

yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.

Ìkìlọ̀ láti má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀

201.20,21: Òw 8.1-3.Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó

ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;

21Láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde

Ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:

22“Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó?

Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó?

Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?

23Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni,

Ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín

kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.

24Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè

kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,

25Níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi,

tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,

26Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín;

èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.

27Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle,

Nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà,

nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.

28“Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn;

wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.

29Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀

tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.

30Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi

tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,

31Wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn

wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún

32Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n

ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;

33Ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu

yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”

King James Version

Proverbs 1:1-33

1The proverbs of Solomon the son of David, king of Israel; 2To know wisdom and instruction; to perceive the words of understanding; 3To receive the instruction of wisdom, justice, and judgment, and equity;1.3 equity: Heb. equities 4To give subtilty to the simple, to the young man knowledge and discretion.1.4 discretion: or, advisement 5A wise man will hear, and will increase learning; and a man of understanding shall attain unto wise counsels: 6To understand a proverb, and the interpretation; the words of the wise, and their dark sayings.1.6 the interpretation: or, an eloquent speech

7¶ The fear of the LORD is the beginning of knowledge: but fools despise wisdom and instruction.1.7 the beginning: or, the principal part 8My son, hear the instruction of thy father, and forsake not the law of thy mother: 9For they shall be an ornament of grace unto thy head, and chains about thy neck.1.9 an…: Heb. an adding

10¶ My son, if sinners entice thee, consent thou not. 11If they say, Come with us, let us lay wait for blood, let us lurk privily for the innocent without cause: 12Let us swallow them up alive as the grave; and whole, as those that go down into the pit: 13We shall find all precious substance, we shall fill our houses with spoil: 14Cast in thy lot among us; let us all have one purse: 15My son, walk not thou in the way with them; refrain thy foot from their path: 16For their feet run to evil, and make haste to shed blood. 17Surely in vain the net is spread in the sight of any bird.1.17 in the…: Heb. in the eyes of every thing that hath a wing 18And they lay wait for their own blood; they lurk privily for their own lives. 19So are the ways of every one that is greedy of gain; which taketh away the life of the owners thereof.

20¶ Wisdom crieth without; she uttereth her voice in the streets:1.20 Wisdom: Heb. Wisdoms, that is, Excellent wisdom 21She crieth in the chief place of concourse, in the openings of the gates: in the city she uttereth her words, saying, 22How long, ye simple ones, will ye love simplicity? and the scorners delight in their scorning, and fools hate knowledge? 23Turn you at my reproof: behold, I will pour out my spirit unto you, I will make known my words unto you.

24¶ Because I have called, and ye refused; I have stretched out my hand, and no man regarded; 25But ye have set at nought all my counsel, and would none of my reproof: 26I also will laugh at your calamity; I will mock when your fear cometh; 27When your fear cometh as desolation, and your destruction cometh as a whirlwind; when distress and anguish cometh upon you. 28Then shall they call upon me, but I will not answer; they shall seek me early, but they shall not find me: 29For that they hated knowledge, and did not choose the fear of the LORD: 30They would none of my counsel: they despised all my reproof. 31Therefore shall they eat of the fruit of their own way, and be filled with their own devices. 32For the turning away of the simple shall slay them, and the prosperity of fools shall destroy them.1.32 turning…: or, ease of the simple 33But whoso hearkeneth unto me shall dwell safely, and shall be quiet from fear of evil.