Saamu 135 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 135:1-21

Saamu 135

1Ẹ yin Olúwa.

Ẹ yin orúkọ Olúwa;

ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Olúwa.

2Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa,

nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.

3Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun;

ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn.

4Nítorí tí Olúwa ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀;

àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀.

5Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi,

àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.

6Olúwa ṣe ohunkóhun tí ó wù ú,

ní ọ̀run àti ní ayé,

ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.

7Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá:

ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò:

ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá.

8Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti,

àti ti ènìyàn àti ti ẹranko.

9Ẹni tí ó rán iṣẹ́ ààmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti,

sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.

10Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀,

tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.

11Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu,

ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani:

12Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,

ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀.

13Olúwa orúkọ rẹ dúró láéláé;

ìrántí rẹ Olúwa, láti ìrandíran.

14135.14: Hb 10.30.Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀,

yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.

15Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà,

iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.

16Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀;

wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.

17Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀;

bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn

18Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn:

gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.

19Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa,

ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún Olúwa.

20Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún Olúwa;

ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, fi ìbùkún fún Olúwa.

21Olùbùkún ni Olúwa, láti Sioni wá,

tí ń gbé Jerusalẹmu.

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

O Livro

Salmos 135:1-21

Salmo 135

1Louvem o Senhor!

Que o seu nome seja honrado!

Louvem-no todos os que o servem.

2Louvem-no, vocês que estão presentes no templo do Senhor,

nos átrios do templo do nosso Deus.

3Louvem o Senhor, porque é infinitamente bom.

Cantem louvores ao poder do seu nome maravilhoso.

4Porque o Senhor escolheu o povo de Jacob e Israel

para serem a sua propriedade preciosa.

5Eu sei que o Senhor é grande,

muito superior ao que os homens consideram deuses.

6Tudo o que quis, o Senhor fez,

tanto nos céus como na Terra,

como nos mares e até nas maiores profundidades.

7É ele quem faz as águas condensarem em nevoeiros,

das partes mais diversas da Terra;

faz os relâmpagos que trazem a chuva;

faz surgir os ventos dos seus reservatórios.

8Foi também ele quem tirou a vida

ao filho mais velho das famílias do Egito,

e até aos próprios animais;

9quem realizou grandes milagres e maravilhas,

contra Faraó e os seus súbditos, nessa terra.

10Abateu muitas nações

e aniquilou poderosos reis;

11Siom, rei dos amorreus, e Ogue, rei de Basã,

e todos os reis de Canaã.

12E deu a terra deles a Israel, seu povo,

para que a possuísse.

13A força do teu nome permanecerá para sempre, Senhor;

a tua fama será conhecida por todas as gerações.

14O Senhor defenderá o seu povo

e terá compaixão dos que o servem.

15Os ídolos que os povos pagãos adoram

não são mais do que meros objetos de prata e de ouro,

mandados fazer por seres humanos.

16Têm boca, mas não falam;

têm olhos, mas não são capazes de ver.

17Têm ouvidos, mas não ouvem;

têm boca e nem sequer respiram.

18Tornar-se-ão iguais a eles aqueles que os mandam fazer,

aqueles que neles confiam!

19Ó povo de Israel,

louva a grandeza do teu Senhor!

E vocês, os sacerdotes da descendência de Aarão,

deem glória ao Senhor!

20Também os sacerdotes levitas

louvem o Senhor!

Todos aqueles que o temem e confiam nele,

louvem-no!

21Bendito seja o Senhor, Deus de Sião,

que está em Jerusalém!

Louvem o Senhor!