Saamu 122 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 122:1-9

Saamu 122

Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi.

1Inú mi dùn nígbà tí wọ́n wí fún mi pé

Ẹ jẹ́ kí á lọ sílé Olúwa.

2Ẹsẹ̀ wa yóò dúró ní ẹnu ibodè rẹ,

ìwọ Jerusalẹmu.

3Jerusalẹmu, ìwọ tí a kọ́ bí ìlú

tí o fi ara mọ́ra pọ̀ ṣọ̀kan

4Níbi tí àwọn ẹ̀yà máa ń gòkè lọ,

àwọn ẹ̀yà Olúwa,

ẹ̀rí fún Israẹli, láti

máa dúpẹ́ fún orúkọ Olúwa.

5Nítorí ibẹ̀ ni a gbé ìtẹ́ ìdájọ́ kalẹ̀,

àwọn ìtẹ́ ilé Dafidi.

6Gbàdúrà fún àlàáfíà Jerusalẹmu;

àwọn tí ó fẹ́ ọ yóò ṣe rere.

7Kí àlàáfíà kí ó wà nínú odi rẹ̀,

àti ìre nínú ààfin rẹ̀.

8Nítorí àwọn ọkùnrin àti àwọn ẹgbẹ́ mi

èmi yóò wí nísinsin yìí pé,

kí àlàáfíà kí ó wà nínú rẹ̀;

9Nítorí ilé Olúwa Ọlọ́run wa,

èmi yóò máa wá ìre rẹ̀.