Saamu 123 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 123:1-4

Saamu 123

Orin fún ìgòkè.

1Ìwọ ní mo gbé ojú mí sókè sí,

ìwọ tí ń gbé inú ọ̀run

2Kíyèsi, bí ojú àwọn

ìránṣẹ́kùnrin ti máa ń wo ọwọ́ àwọn baba wọn,

àti bí ojú ìránṣẹ́bìnrin ti máa ń wo ọwọ́ ìyá rẹ̀

bẹ́ẹ̀ ni ojú wa ń wo Olúwa Ọlọ́run wa,

títí yóò fi ṣàánú fún wa.

3Olúwa, ṣàánú fún wa, ṣàánú fún wa;

nítorí tí a kún fún ẹ̀gàn púpọ̀púpọ̀.

4Ọkàn wa kún púpọ̀

fún ẹ̀gàn àwọn onírera,

àti fún ẹ̀gàn àwọn agbéraga.