Rutu 4 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Rutu 4:1-22

Boasi gbé Rutu ní ìyàwó

1Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.

2Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀, 3ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa. 4Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.”

Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”

5Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”

6Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”

74.7: De 25.8-10.Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.

8Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnrarẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.

9Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi. 10Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”

11Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu. 12Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”

Èyí ni ìran Dafidi

13Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan. 14Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli. 15Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”

16Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀. 17Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.

18Èyí ni ìran Peresi:

Peresi ni baba Hesroni,

19Hesroni ni baba Ramu,

Ramu ni baba Amminadabu

20Amminadabu ni baba Nahiṣoni,

Nahiṣoni ni baba Salmoni,

21Salmoni ni baba Boasi,

Boasi ni baba Obedi,

22Obedi ní baba Jese,

Jese ni baba Dafidi.

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Рут 4:1-22

Боаз женится на Рут

1А Боаз тем временем направился к городским воротам4:1 Ворота города были центром всей общественной жизни, около них проходили и судебные разбирательства. и сел там. Когда родственник, о котором он говорил, проходил мимо, Боаз сказал:

– Сверни сюда, мой друг, и присядь.

Тот свернул и сел.

2Боаз взял десять человек из старейшин города и сказал им:

– Сядьте здесь. – И они сели.

3После этого он сказал тому родственнику:

– Наоми, которая вернулась из Моава, продаёт участок земли, что принадлежал нашему родичу Эли-Малику. 4Я подумал, что должен довести это до твоего сведения и предложить тебе купить его в присутствии тех, кто сидит здесь, и в присутствии старейшин моего народа. Но если ты не купишь, скажи мне, чтобы я знал. Ведь у тебя первоочередное право сделать это, а я – за тобой.

– Я выкуплю его, – сказал он.

5Тогда Боаз сказал:

– В тот день, когда купишь землю у Наоми, ты также должен будешь жениться на моавитянке Рут, вдове покойного, чтобы, когда у вас родится сын, земля осталась за семьёй покойного.

6Но родственник сказал:

– В таком случае я не могу выкупить этот участок, потому что я подвергну опасности своё собственное имение. Выкупай лучше сам, а я не могу этого сделать.

7(В прежние времена в Исроиле, чтобы выкупить или передать права на собственность, один из участников сделки снимал свою сандалию и отдавал её другому. Такой в Исроиле был обычай узаконивать сделку.)

8Родственник сказал Боазу:

– Покупай сам. – И снял свою сандалию.

9Тогда Боаз объявил старейшинам и всему народу:

– Сегодня вы свидетели того, что я купил у Наоми всё, что принадлежало Эли-Малику, Килеону и Махлону. 10Ещё я приобрёл моавитянку Рут, вдову Махлона, себе в жёны, чтобы сохранить землю за семьёй покойного, чтобы его имя не исчезло среди его родичей и не было забыто в стенах его родного города. Вы сегодня свидетели этого!

11Тогда старейшины и все, кто был у ворот, сказали:

– Мы свидетели. Пусть Вечный сделает плодовитой женщину, которая входит в твой дом, подобно Рахиле и Лии, которые вместе возвели дом Исроила4:11 См. Нач. 29:31–30:24; 35:16-20.. Приобретай богатство в Ефрафе и славься в Вифлееме. 12Пусть через потомство, которое Вечный даст тебе от этой молодой женщины, твой род уподобится роду Фареца, которого Фамарь родила Иуде4:12 История рождения Фареца могла быть здесь упомянута по трём причинам: 1) он появился на свет, как наследник умершего Ира, сына Иуды (см. Нач. 38); 2) Боаз был прямым потомком Фареца (см. 4:18-21); 3) потомки Фареца поселились в Вифлееме (см. 1 Лет. 2:5, 18-19, 50-54)..

Родословие царя Довуда

(1 Лет. 2:5-15; Мат. 1:3-6; Лк. 3:31-33)

13Так Боаз взял Рут, и она стала его женой. Он лёг с ней, и Вечный дал ей зачать, и она родила сына.

14Женщины говорили Наоми:

– Хвала Вечному! Он не оставил тебя сегодня без наследника, который будет заботиться о тебе. Пусть мальчик прославится в Исроиле! 15Он обновит твою жизнь и обеспечит тебя в старости. Ведь его родила твоя сноха, которая любит тебя, и которая для тебя лучше семи сыновей.

16И Наоми взяла младенца, носила его в объятиях и нянчила его. 17Женщины, которые жили там, говорили:

– У Наоми родился сын.

Они назвали его Овид. Он стал отцом Есея, отца Довуда.

18И вот родословие Фареца:

Фарец был отцом Хецрона,

19Хецрон – отцом Рама,

Рам – отцом Аминадава,

20Аминадав – отцом Нахшона,

Нахшон – отцом Салмона,

21Салмон – отцом Боаза,

Боаз – отцом Овида,

22Овид – отцом Есея,

а Есей – отцом Довуда.