Nehemiah 5 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 5:1-19

Nehemiah ran àwọn aláìní lọ́wọ́

1Nísinsin yìí àwọn ènìyàn àti àwọn ìyàwó wọn kígbe ńlá sókè sí àwọn Júù arákùnrin wọn. 2Àwọn kan ń wí pé, “Àwa àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa pọ̀; kí àwa kí ó le è jẹ, kí a sì wà láààyè, a gbọdọ̀ rí oúnjẹ.”

3Àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ti fi oko wa ọgbà àjàrà wa àti ilé wa dógò kí àwa kí ó lè rí oúnjẹ ní àkókò ìyàn.”

4Síbẹ̀ àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ní láti yá owó láti san ìṣákọ́lẹ̀ fún ọba lórí àwọn oko wa àti àwọn ọgbà àjàrà wa. 5Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a jẹ́ ẹran-ara kan àti ẹ̀jẹ̀ kan gẹ́gẹ́ bí àwọn ará ìlú wa tí àwọn ọmọkùnrin wa sì dára bí í tiwọn, síbẹ̀ àwa ní láti fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa sí oko ẹrú. Díẹ̀ nínú àwọn ọmọbìnrin wa ti wà lóko ẹrú náà, ṣùgbọ́n àwa kò ní agbára, nítorí àwọn oko àti ọgbà àjàrà wa ti di ti ẹlòmíràn.”

6Èmi bínú gidigidi nígbà tí mo gbọ́ igbe wọn àti àwọn ẹ̀sùn wọ̀nyí. 7Mo rò wọ́n wò ní ọkàn mi mo sì fi ẹ̀sùn kan ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè. Mo sọ fún wọn pé, ẹ̀yin ń gba owó èlé lọ́wọ́ àwọn ará ìlú u yín! Nítorí náà mo pe àpéjọ ńlá láti bá wọn wí. 8Mo sì wí fún wọn pé: “Níbi tí àwa ní agbára mọ, àwa ti ra àwọn Júù arákùnrin wa tí a ti tà fún àwọn tí kì í ṣe Júù padà. Nísinsin yìí ẹ̀yìn ń ta àwọn arákùnrin yín, tí àwa sì tún ní láti rà wọ́n padà!” Wọ́n dákẹ́, nítorí wọn kò rí ohunkóhun sọ.

9Nítorí náà, mo tẹ̀síwájú pé, “Ohun tí ẹ̀ ń ṣe kò dára. Kò ha yẹ kí ẹ máa rìn nínú ìbẹ̀rù Ọlọ́run bí, láti yẹra fún ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn tí í ṣe ọ̀tá wa? 10Èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi, pẹ̀lú ń yá àwọn ènìyàn lówó àti oúnjẹ. Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí a dáwọ́ owó èlé gbígbà yìí dúró! 11Ẹ fún wọn ní oko wọn, ọgbà àjàrà wọn, ọgbà olifi wọn àti ilé e wọn pẹ̀lú owó èlé tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn ìdá ọgọ́rùn-ún owó, oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn padà kíákíá.”

12Wọ́n wí pé, “Àwa yóò dá a padà. Àwa kì yóò sì béèrè ohunkóhun lọ́wọ́ wọn mọ́. Àwa yóò ṣe bí o ti wí.”

Nígbà náà mo pe àwọn àlùfáà, mo sì mú kí àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè búra láti jẹ́ kí wọ́n ṣe ohun tí wọ́n ti ṣe ìlérí. 13Mo sì gbọn ìṣẹ́tí aṣọ mi, mo wí pé, “Báyìí ni kí Ọlọ́run gbọn olúkúlùkù ènìyàn tí kò bá pa ìlérí yìí mọ́ jáde kúrò ní ilẹ̀ ìní i rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni kí a gbọn irú ẹni bẹ́ẹ̀ jáde kí ó sì ṣófo!”

Gbogbo ìjọ ènìyàn sì wí pé “Àmín,” wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa. Àwọn ènìyàn náà sì ṣe bí wọ́n ti ṣe ìlérí.

14Síwájú sí í, láti ogún ọdún ọba Artasasta, nígbà tí a ti yàn mí láti jẹ́ baálẹ̀ wọn ní ilẹ̀ Juda, títí di ọdún kejìlélọ́gbọ̀n ìjọba rẹ̀—ọdún méjìlá, èmi àti àwọn arákùnrin mi kò jẹ oúnjẹ baálẹ̀. 15Ṣùgbọ́n àwọn baálẹ̀ ìṣáájú—tí ó ti wà ṣáájú mi—gbe àjàgà wúwo lé àwọn ènìyàn lórí yàtọ̀ fún oúnjẹ àti wáìnì wọ́n sì tún gba ogójì ṣékélì fàdákà lọ́wọ́ wọn. Kódà àwọn ìránṣẹ́ wọn tún jẹ gàba lórí wọn. Ṣùgbọ́n èmi kò ṣe bẹ́ẹ̀ nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run. 16Dípò bẹ́ẹ̀, mo fi ara mi jì fún iṣẹ́ lórí odi yìí. Gbogbo àwọn ènìyàn mi péjọ síbẹ̀ fún iṣẹ́ náà; a kò sì gba ilẹ̀ kankan.

17Síwájú sí í, àádọ́jọ (150) àwọn Júù àti àwọn ìjòyè jẹun lórí tábìlì mi, àti pẹ̀lú àwọn tí wọ́n wá bá wa láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká. 18Ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ni a máa ń pèsè màlúù kan, ààyò àgùntàn mẹ́fà àti adìyẹ fún mi àti lẹ́ẹ̀kan ní ọjọ́ mẹ́wàá ni wọ́n máa ń pèsè onírúurú wáìnì tí ó pọ̀ fún mi. Fún gbogbo èyí, èmi kò béèrè oúnjẹ baálẹ̀, nítorí ohun ti a ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí pọ̀ jọjọ.

19Rántí mi, Ọlọ́run mi, fún rere, nítorí fún gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún àwọn ènìyàn yìí.

Nouă Traducere În Limba Română

Neemia 5:1-19

Criza socială și economică

1Cei din popor și soțiile lor au avut o mare plângere împotriva fraților lor iudei. 2Erau unii care ziceau:

– Noi, fiii și fiicele noastre suntem mulți. Să ni se dea grâne, ca să avem ce mânca și să trăim.

3Alții ziceau:

– Ne punem garanție ogoarele, viile și casele, ca să avem grâne în timpul foametei.

4Mai erau încă unii care ziceau:

– A trebuit să împrumutăm argint, dându‑ne ogoarele și viile în schimbul birului imperial. 5Deși suntem carne din carnea fraților noștri, iar fiii noștri sunt ca și fiii lor, iată că suntem pe cale să ne dăm fiii și fiicele în robie. Câteva din fetele noastre au și fost luate în robie. Suntem fără putere, iar ogoarele și viile noastre aparțin altora!

6M‑am mâniat foarte tare când le‑am auzit plângerea și cuvintele acestea.

7După ce m‑am gândit, i‑am mustrat pe nobili și pe dregători, zicându‑le:

– Voi împrumutați cu dobândă pe frații voștri?!

Am strâns o mare adunare împotriva lor 8și le‑am zis:

– Noi, după puterile noastre, am răscumpărat pe frații noștri iudei, care fuseseră vânduți neamurilor. Iar acum voi vă vindeți frații, ca apoi să ne fie dați chiar nouă de vânzare?

Ei tăceau, neavând ce să răspundă.

9Atunci eu am zis:

– Ce faceți voi nu este bine. N‑ar trebui să umblați în teamă de Dumnezeul nostru, ca să nu fiți de rușinea neamurilor, a dușmanilor noștri? 10Atât eu, cât și frații și slujitorii mei le‑am împrumutat argint și grâne. Să le iertăm, vă rog, datoria aceasta! 11Vă rog, dați‑le înapoi astăzi ogoarele, viile, măslinii și casele, precum și a suta parte din argintul, din grânele, din mustul și din uleiul pe care le‑ați cerut de la ei ca dobândă.

12Ei au răspuns:

– Le vom da înapoi și nu vom mai cere nimic de la ei. Vom face întocmai precum ai zis.

Atunci am chemat preoții și i‑am pus să jure înaintea lor că vor face precum au promis. 13Mi‑am scuturat mantaua și am zis:

– Așa să scuture Dumnezeu din familia lui și din proprietatea lui pe orice om care nu se va ține de cuvânt! Așa să fie scuturat și lăsat fără nimic!

Toată adunarea a răspuns:

– Amin!

Și L‑au lăudat pe Domnul. Poporul a făcut întocmai cum a promis.

14Din ziua în care am fost numit guvernatorul lor în țara lui Iuda, adică din al douăzecilea an al împăratului Artaxerxes și până în al treizeci și doilea an al său14 martie-aprilie 445 î.Cr. – aprilie 433–aprilie 432 î.Cr., deci timp de doisprezece ani, nici eu, nici frații mei nu am trăit din veniturile de guvernator. 15Înainte de mine, cei dintâi guvernatori împovărau poporul, luând de la ei pâine și vin, în afară de cei patruzeci de șecheli15 Aproximativ 0,5 kg. de argint. Chiar și slujitorii lor asupreau poporul. Eu însă nu am făcut așa, din teamă de Dumnezeu. 16Ba încă, am stăruit în lucrarea de restaurare a acestui zid și nu mi‑am cumpărat ogoare. De altfel, toți slujitorii mei erau adunați acolo pentru lucrare. 17Mai mult, aveam la masa mea o sută cincizeci de bărbați dintre iudei și dintre dregători, în afară de cei care veneau dintre neamurile dimprejur. 18În fiecare zi mi se pregătea un bou, șase oi alese și păsări, iar la fiecare zece zile se aducea vin din belșug, de toate felurile. Cu toate acestea, eu nu am căutat să primesc plată ca guvernator, căci lucrarea apăsa greu asupra acestui popor. 19Adu‑Ți aminte de mine, Dumnezeul meu, spre bine, pentru tot ce am făcut pentru acest popor!