Malaki 3 – YCB & JCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Malaki 3:1-18

Rírán Mesiah náà

13.1: Mt 11.10; Mk 1.2; Lk 1.17,76; 7.27.“Wò ó, Èmi yóò ran ìránṣẹ́ mi, yóò tún ọ̀nà ṣe ṣáájú mi. Nígbà náà ni Olúwa, tí ẹ̀yin ń wa, yóò dé ni òjijì sí tẹmpili rẹ̀; àní oníṣẹ́ májẹ̀mú náà, tí inú yín dùn sí, yóò dé,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

23.2: If 6.17.Ṣùgbọ́n ta ni o lè fi ara da ọjọ́ dídé rẹ̀? Ta ni yóò sì dúró nígbà tí ó bá fi ara hàn? Nítorí òun yóò dàbí iná ẹni tí ń da fàdákà àti bi ọṣẹ alágbàfọ̀: 3Òun yóò sì jókòó bí ẹni tí n yọ́, tí ó sì ń da fàdákà; yóò wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, yóò sì tún wọn dàbí wúrà àti fàdákà, kí wọn bá a lè mú ọrẹ òdodo wá fún Olúwa, 4nígbà náà ni ọrẹ Juda àti ti Jerusalẹmu yóò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ àtijọ́, àti gẹ́gẹ́ bí ọdún ìgbàanì.

5“Èmi ó sì súnmọ́ yin fún ìdájọ́. Èmi yóò sì yára ṣe ẹlẹ́rìí sí àwọn oṣó, sí àwọn panṣágà, sí àwọn abúra èké, àti àwọn tí ó fi ọ̀yà alágbàṣe pọn wọn lójú, àti àwọn tí ó ni àwọn opó àti àwọn aláìní baba lára, àti sí ẹni tí kò jẹ́ kí àjèjì rí ìdájọ́ òdodo gbà, tí wọn kò sì bẹ̀rù mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

Jíja Ọlọ́run ni olè

6“Èmi Olúwa kò yípadà. Nítorí náà ni a kò ṣe run ẹ̀yin ọmọ Jakọbu. 7Láti ọjọ́ àwọn baba ńlá yín wá ni ẹ̀yin tilẹ̀ ti kọ ẹ̀yìn sí ìlànà mi, tí ẹ kò sì pa wọ́n mọ́. Ẹ padà wá sí ọ̀dọ̀ mi, Èmi yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa yóò ṣe padà?’

8“Ènìyàn yóò ha ja Ọlọ́run ni olè bí? Síbẹ̀ ẹ̀yin ti jà mí ní olè.

“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe jà ọ́ ní olè?’

“Nípa ìdámẹ́wàá àti ọrẹ. 9Ríré ni a ó fi yín ré: gbogbo orílẹ̀-èdè yìí, nítorí ẹ̀yin ti jà mi lólè. 10Ẹ mú gbogbo ìdámẹ́wàá wá sí ilé ìṣúra, kí oúnjẹ bá à lè wà ní ilé mi, ẹ fi èyí dán mi wò,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “kí ẹ sì wò bí èmi kò bá ní sí àwọn fèrèsé ọ̀run fún yin, kí èmi sì tú ìbùkún àkúnwọ́sílẹ̀ jáde fún yín, tó bẹ́ẹ̀ tí kì yóò sì ààyè láti gbà á. 11Èmi yóò sì bá kòkòrò ajẹnirun wí nítorí yín, òun kò sì ni run èso ilẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni àjàrà inú oko yín kò ní rẹ̀ dànù,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. 12“Nígbà náà ni gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì pè yín ni alábùkún fún, nítorí tiyín yóò jẹ́ ilẹ̀ tí ó wu ni,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

13“Ẹ̀yin ti sọ ọ̀rọ̀ líle sí mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

“Síbẹ̀ ẹ̀yin béèrè pé, ‘Ọ̀rọ̀ kín ni àwa sọ sí ọ?’

14“Ẹ̀yin ti wí pé, ‘Asán ni láti sin Ọlọ́run. Kí ni àwa jẹ ní èrè, nígbà tí àwa ti pa ìlànà rẹ mọ́, tí àwa sì ń rìn kiri bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ní iwájú Olúwa àwọn ọmọ-ogun? 15Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí àwa pé agbéraga ni alábùkún fún Ní òtítọ́ ni àwọn ti ń ṣe búburú ń gbèrú sí i, kódà àwọn ti ó dán Ọlọ́run wò ni a dá sí.’ ”

16Nígbà náà ni àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa ń ba ara wọn sọ̀rọ̀, Olúwa sì tẹ́tí sí i, ó sì gbọ́. A sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀, fún àwọn tí o bẹ̀rù Olúwa, tiwọn sì bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ̀.

17“Wọn yóò sì jẹ́ tèmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ni ọjọ́ náà, tí èmi ó dá; èmi yóò sì da wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí máa ń dá ọmọ rẹ̀ tí yóò sìn ín sí. 18Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìyàtọ̀, ìyàtọ̀ láàrín olódodo àti ẹni búburú, láàrín ẹni tí ń sìn Ọlọ́run, àti ẹni tí kò sìn ín.

Japanese Contemporary Bible

マラキ書 3:1-18

3

1「聞きなさい。

わたしはわたしが行く前に使者を遣わして、

道を備えさせる。

そののち、あなたがたが探し求めている主が、

突如として神殿にやって来る。

神が約束したその使者は、

あなたがたに大きな喜びをもたらす。

必ず彼は来る。」

全能の主は語ります。

2「だが彼が現れる時、

だれが生きていられるだろう。

彼が来ることに、だれが耐ええよう。

彼は燃えさかる火のようであり、

真っ黒に汚れた上着を、

真っ白にすることができるからだ。

3彼は銀を精錬する人のように、腰を据えて、

不純物が燃え尽きていくのを、目を凝らして見守る。

神に仕えるレビ人をきよめ、金や銀のように精錬して、

きよい心で神の働きができるようにする。

4その時、主はまた以前のように、

ユダとエルサレムの人々が携えて来るささげ物を

喜んで受ける。

5その時、わたしのさばきは速やかに、

確実に行われる。

罪のない人を欺く悪者に、

不品行な者と偽り者に、

雇い人を不当な賃金で虐げる者に、

未亡人や孤児を苦しめる者に、

外国人をだます者に、

わたしを恐れない者に、

わたしはただちに向かう。」

と主は語ります。

神のものを盗む

6「わたしは主であり、決して変わることがない。

あなたがたは滅ぼし尽くされてはいない。

わたしのあわれみは永遠に変わらないからだ。

7あなたがたは最初からわたしの律法を軽んじてきたが、

まだわたしのもとに帰ることができる。」

主は語ります。

「さあ、帰って来なさい。

そうすれば、あなたがたを赦そう。

しかし、あなたがたは言う。

『私たちは背いたことなどありません』と。

8人は神のものを盗めるだろうか。できるわけがない。

ところがあなたがたは、わたしのものを盗んでいる。

『何のことですか。

いつ神のものを盗みましたか。』

あなたがたは、わたしに納めるべき収入の十分の一と

ささげ物を盗んだ。

9それであなたがたは、

神の恐ろしいのろいによって、のろわれているのだ。

あなたがたの民全体が、

わたしのものを盗んでいるからだ。

10収入の十分の一をすべて倉に携えて来なさい。

そうすれば、

わたしの神殿には食べ物が十分あるようになる。

あなたがたが十分の一をささげれば、

わたしはあなたがたのために天の窓を開いて、

受け止めることができないほどの

祝福をあふれるばかりに注ごう。

試してみなさい。わたしは、そのことを証明しよう。

11わたしが穀物を害虫や病害から守るから、

あなたがたの収穫は多くなる。

ぶどうが熟す前にしぼんでしまうこともない。」

主は語ります。

12「すべての国々の民は、

あなたがたを祝福された者と言う。

あなたがたが幸福に輝く国となるからだ。」

これが全能の主の約束です。

高慢な態度で神に語るイスラエル

13あなたがたのわたしに対する態度は、

なんと高慢で横柄なことか。」

と主は言います。

「ところが、あなたがたは言う。

『何のことでしょう。

言ってはならないことを言ったでしょうか。』

14-15聞きなさい。あなたがたはこう言った。

『神を礼拝したり、

神に従ったりするのは愚かなことだ。

律法を守っても、罪を悲しんでも、

何の良いことがあるだろう。

これからは、「高ぶる者は幸いだ」と言おう。

悪を働く者が栄え、

神に罰せられるようなことをしても、

罰を免れて平気でいるからだ』と。」

忠実な残りの者

16その時、神を恐れる者たちが、

互いに主のことを語り合っていました。

主は記憶の書を作成して、

主を恐れ、

主について考えることを喜ぶ者たちの名前を

記しました。

17全能の主はこう語ります。

「わたしが自分の宝石を仕上げるその日、

彼らはわたしのものとなる。

人が忠実に務めをはたす子を扱うように、

わたしも彼らを扱おう。

18その時あなたがたは、正しい人と神に逆らう人、

また神に仕える者と仕えない者との

違いを見ることになる。」