Malaki 2 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Malaki 2:1-17

Ìkìlọ̀ fún àwọn àlùfáà

1“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin àlùfáà, òfin yìí ní fún yín. 2Bí ẹ̀yin kò bá ni gbọ́, bí ẹ̀yin kò bá ní fi í sí àyà láti fi ọ̀wọ̀ fún orúkọ mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí; èmi yóò sì ran ègún sí orí yín, èmi yóò sì fi ìbùkún yín ré. Nítòótọ́ mó ti fi ré ná, nítorí pé, ẹ̀yin kò fi sí ọkàn yín láti bu ọlá fún mi.

3“Nítorí tiyín èmí yóò ba àwọn ọmọ yín wí, èmi ó sì fi ìgbẹ́ rẹ́ yín lójú, àní àwọn ìgbẹ́ ọrẹ ọwọ́ yín wọ̀nyí, a ó sì kó yín lọ pẹ̀lú rẹ̀. 4Ẹ̀yin ó sì mọ̀ pé, èmi ni ó ti rán òfin yìí sí yín, kí májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi lè tẹ̀síwájú” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. 5“Májẹ̀mú mi wà pẹ̀lú rẹ̀, májẹ̀mú ti ìyè àti àlàáfíà wà pẹ̀lú rẹ̀; mo sì fi wọn fún un, nítorí bíbẹ̀rù tí ó bẹ̀rù mi, tí ẹ̀rù orúkọ mi sì bà á. 6Òfin òtítọ́ wà ni ẹnu rẹ̀, a kò sì rí irọ́ ni ètè rẹ̀: ó ba mi rìn ní àlàáfíà àti ni ìdúró ṣinṣin, ó sì yí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.

7“Nítorí ètè àlùfáà ní òye láti máa pa ìmọ̀ mọ́, kí àwọn ènìyàn lè máa wá ìtọ́ni ni ẹnu rẹ̀: nítorí òun ni ìránṣẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun. 8Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yapa kúrò ní ọ̀nà náà; ẹ̀yin sì ti fi ìkọ́ni yín mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kọsẹ̀; ẹ̀yin ti ba májẹ̀mú tí mo da pẹ̀lú Lefi jẹ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. 9“Nítorí náà ni èmi pẹ̀lú ṣe sọ yín di ẹ̀gàn, àti ẹni àìkàsí níwájú gbogbo ènìyàn, nítorí ẹ̀yin kò tẹ̀lé ọ̀nà mi, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ń ṣe ojúsàájú nínú òfin.”

10Baba kan náà kí gbogbo wa ha ní? Ọlọ́run kan náà kọ́ ni ó dá wa bí? Nítorí kín ni àwa ha ṣe sọ májẹ̀mú àwọn baba wa di aláìmọ nípa híhu ìwà àrékérekè olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀?

11Juda ti ń hùwà àrékérekè, a sì ti hùwà ìríra ní Israẹli àti ni Jerusalẹmu: nítorí Juda tí sọ ìwà mímọ́ Olúwa di aláìmọ́, èyí tí ó fẹ́, nípa gbígbé ọmọbìnrin ọlọ́run àjèjì ni ìyàwó. 12Ní ti ẹni tí ó ṣe èyí, ẹni tí ó wù kí ó jẹ, kí Olúwa kí ó gé e kúrò nínú àgọ́ Jakọbu, bí ó tilẹ̀ mú ẹbọ ọrẹ wá fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

13Èyí ni ohun mìíràn tí ẹ̀yin sì túnṣe: Ẹ̀yin fi omijé bo pẹpẹ Olúwa mọ́lẹ̀. Ẹ̀yin sọkún, ẹ̀yin sì ba ara jẹ́ nítorí tì Òun kò ka ọrẹ yín sí mọ́, tàbí kí ó fi inú dídùn gba nǹkan yìí lọ́wọ́ yín. 14Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, “Nítorí kín ní?” Nítorí Olúwa ti ṣe ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti láàrín aya èwe rẹ, ẹni tí ìwọ ti ń hùwà ẹ̀tàn sí i: bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkejì rẹ ni òun jẹ́, àti aya májẹ̀mú rẹ.

15Ọlọ́run kò ha ti ṣe wọ́n ní ọ̀kan? Ni ara àti ni ẹ̀mí tirẹ̀ ni. Èéṣe tí Ọlọ́run da yín lọ́kàn? Kí òun bá à lè wá irú-ọmọ bí ti Ọlọ́run. Nítorí náà, ẹ tọ́jú ẹ̀mí yín, ẹ má sì ṣe hùwà ẹ̀tàn sí aya èwe yín.

16“Ọkùnrin tí ó bá kórìíra, tí ó sì kọ ìyàwó rẹ̀,” Ṣe ìwà ipá sí ẹni tí ó yẹ kí ó dá ààbò bò, ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.

Nítorí náà, ẹ ṣọ́ ẹ̀mí yín, kí ẹ má ṣe hùwà ẹ̀tàn.

Ọjọ́ ìdájọ́

17Ẹ̀yin ti fi ọ̀rọ̀ yín dá Olúwa ní agara.

Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, “Nínú kín ni àwa fi dá a ní agara?”

Nígbà tí ẹ̀yìn wí pé, “Gbogbo ẹni tí ó ṣe ibi, rere ni níwájú Olúwa, inú rẹ̀ sì dùn sí wọn,” tàbí “Níbo ni Ọlọ́run ìdájọ́ gbé wà?”

La Bible du Semeur

Malachie 2:1-17

L’avertissement aux prêtres

1Maintenant, c’est à vous, prêtres, que s’adresse cet avertissement. 2Si vous n’écoutez pas, si vous ne prenez pas à cœur de m’honorer, dit l’Eternel, le Seigneur des armées célestes, alors j’enverrai la malédiction contre vous. Et vos bénédictions, j’en ferai des malédictions. Oui, j’en fais des malédictions car aucun, parmi vous, ne prend à cœur de m’honorer.

3Je vais détruire votre postérité2.3 Au lieu de je vais détruire votre postérité, les versions anciennes ont : je vous raccourcirai le bras, ce qui, en hébreu, ne suppose qu’une différence minime. et vous jeter à la figure les excréments des bêtes que vous offrez en sacrifice lors de vos fêtes, et puis l’on vous emportera au dehors, avec eux. 4Et vous reconnaîtrez que je vous ai donné cet avertissement afin que mon alliance avec Lévi subsiste, déclare l’Eternel, le Seigneur des armées célestes2.4 Voir Nb 3.12-13 ; Né 13.29.. 5J’ai conclu mon alliance avec lui pour lui accorder la vie et le bien-être. Je les lui ai donnés pour qu’il me révère, et il m’a révéré, il tremblait devant moi. 6Sa bouche dispensait un enseignement vrai, et l’on ne trouvait sur ses lèvres aucune fausseté. Il vivait avec moi dans la paix et avec droiture, il a détourné de leurs fautes un grand nombre de gens. 7Car le prêtre doit s’attacher à la connaissance, c’est vers lui que l’on vient pour recevoir l’enseignement. Il est un messager du Seigneur des armées célestes. 8Mais vous vous êtes écartés du bon chemin : par votre enseignement, vous avez fait tomber beaucoup de gens dans le péché. Oui, vous avez rompu l’alliance conclue avec Lévi, déclare l’Eternel, le Seigneur des armées célestes. 9Alors, de mon côté, je vous ai livrés au mépris et au dédain de tout le peuple, puisque vous, vous ne suivez pas les voies que j’ai prescrites et que vous avez montré de la partialité quand vous donnez vos instructions.

Les mariages mixtes

10Ne sommes-nous pas tous enfants d’un père unique ? N’avons-nous pas été créés par un seul Dieu ? Comment donc pouvons-nous agir avec traîtrise chacun envers son compatriote et profaner ainsi l’alliance conclue avec nos pères ? 11Le peuple de Juda a été infidèle, et l’on a perpétré une abomination en Israël et à Jérusalem : Juda a profané le sanctuaire de l’Eternel, le lieu qu’il affectionne : des Judéens ont épousé des étrangères adorant d’autres dieux2.11 Ces mariages étaient interdits par la Loi (Ex 34.15-16 ; Dt 7.3-4 ; 1 R 11.1-6 ; Jos 23.12-13). Esdras et Néhémie ont tous deux eu à faire face à ce problème (Esd 9.1-2 ; Né 13.23-29).. 12Que l’Eternel retranche à ceux qui agissent ainsi, enfants et descendance2.12 L’hébreu dit, littéralement : veilleur et répondant, expression qui a reçu de nombreuses interprétations. On y a vu une allusion au nouveau-né qui s’éveille et à l’enfant qui répond, ou au fils et au petit-fils, ou à la sentinelle et au soldat qui lui répond, ou à la vie des nomades qui veillent et se répondent la nuit autour des tentes, ou au disciple et au maître. En modifiant légèrement le premier terme, on a traduit témoin et répondant en y voyant l’idée d’un soutien juridique. Pour d’autres, l’expression évoquerait la totalité. L’idée d’une privation de descendance est celle qui semble correspondre le mieux au contexte., et tout membre des familles de Jacob2.12 C’est-à-dire des familles israélites, qui descendent de Jacob. qui serait susceptible de présenter l’offrande à l’Eternel, le Seigneur des armées célestes.

Les divorces

13Voici une autre faute que vous avez commise : vous inondez de larmes l’autel de l’Eternel, vous le couvrez de pleurs et de gémissements, parce que l’Eternel ne fait plus aucun cas de toutes vos offrandes et qu’il n’agrée plus de recevoir de vous ce que vous présentez2.13 Pour les v. 13-16, voir Mt 5.31-32 ; 19.3-9.. 14Vous demandez : Pourquoi en est-il ainsi ?

Parce que l’Eternel a été le témoin2.14 Le mariage est une alliance (voir Pr 2.17 ; Ez 16.8) et les alliances sont conclues devant témoins (cf. Dt 30.19 où Dieu prend les cieux et la terre à témoin ; 1 S 20.23 ; Es 8.1-2). entre chacun de vous et la femme que vous avez épousée lorsque vous étiez jeunes2.14 Littéralement : la femme de ta jeunesse, c’est-à-dire celle que tu as aimée et épousée quand tu étais jeune. et que vous avez trahie. Elle était pourtant ta compagne, avec qui tu avais conclu une alliance. 15Un homme en qui subsiste un reste de bon sens ne ferait pas cela !

Mais vous me répliquez : Alors qu’a fait cet homme-là – Abraham – dont nous avons l’exemple ?

Eh bien, il cherchait une descendance qui lui vienne de Dieu2.15 Traduction difficile. Le nom Abraham n’est pas dans l’hébreu qui est obscur, mais le passage semble faire allusion à Abraham qui a renvoyé Agar et l’enfant qu’il avait eu d’elle (Gn 16). Autre traduction : Un homme en qui subsiste un reste de bon sens ne ferait pas cela ! Car que recherche un tel homme ? Une postérité conforme à la volonté de Dieu. Les traductions suivantes ont aussi été proposées pour ce verset mais paraissent moins plausibles : même cet homme unique (Abraham) n’a pas agi ainsi, bien qu’il ne restait en lui qu’un souffle de vie. Et pourtant que cherchait-il ? Une postérité qui lui vienne de Dieu. Ou, en modifiant légèrement le texte hébreu : un homme en qui subsiste un brin de bon sens ne ferait pas une chose pareille. Ou alors que chercherait-il ? Une postérité accordée par Dieu ? Ou encore, en adoptant une autre petite modification : Dieu n’a-t-il pas fait un seul être, chair possédant souffle de vie ? Et que cherche cet être unique ? Une postérité de Dieu (voir Gn 2.7, 24).. Restez donc dans votre bon sens, et ne trahissez pas la femme de votre jeunesse.

16Car renvoyer sa femme par haine, déclare l’Eternel, Dieu d’Israël, c’est comme maculer de sang son propre vêtement2.16 Autre traduction : Car je hais la répudiation, déclare l’Eternel, Dieu d’Israël, et celui qui couvre de violence son propre vêtement… en commettant un acte de violence, déclare l’Eternel, le Seigneur des armées célestes.

Restez donc dans votre bon sens et n’agissez pas en traîtres !

Dieu fera justice

17Vous lassez l’Eternel par vos discours, et puis vous demandez : En quoi te lassons-nous ?

C’est parce que vous dites : Quiconque fait le mal est bien vu de l’Eternel. Il a plaisir à ces gens-là.

Ou bien encore : Où est le Dieu de la justice ?