Luku 24 – YCB & SZ-PL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Luku 24:1-53

Àjíǹde náà

124.1-9: Mt 28.1-8; Mk 16.1-7; Jh 20.1,11-13.Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ ọ̀sẹ̀, àwọn obìnrin wá sí ibojì, wọ́n sì mú ìkunra olóòórùn dídùn ti wọ́n tí pèsè sílẹ̀ wá. 2Òkúta ti yí kúrò ní ẹnu ibojì. 3Nígbà tí wọ́n sì wọ inú rẹ̀, wọn kò rí òkú Jesu Olúwa. 4Bí wọ́n ti dààmú kiri níhà ibẹ̀, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin méjì aláṣọ dídán dúró tì wọ́n: 5Nígbà tí ẹ̀rù ń bà wọ́n, tí wọ́n sì dojúbolẹ̀, àwọn angẹli náà bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá alààyè láàrín àwọn òkú? 624.6: Lk 9.22; 13.32-33.Kò sí níhìn-ín yìí, ṣùgbọ́n ó jíǹde; ẹ rántí bí ó ti wí fún yín nígbà tí ó wà ní Galili. 7Pé, ‘A ó fi ọmọ ènìyàn lé àwọn ènìyàn ẹlẹ́ṣẹ̀ lọ́wọ́, a ó sì kàn án mọ́ àgbélébùú, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.’ ” 8Wọ́n sì rántí ọ̀rọ̀ rẹ̀.

9Wọ́n sì padà ti ibojì wá, wọ́n sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún àwọn mọ́kànlá, àti fún gbogbo àwọn ìyókù. 1024.10: Mk 16.1; Lk 8.1-3; Jh 20.2.Maria Magdalene, àti Joanna, àti Maria ìyá Jakọbu, àti àwọn mìíràn pẹ̀lú wọn sì ni àwọn tí ó ròyìn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn aposteli. 11Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sì dàbí ìsọkúsọ lójú wọn, wọn kò sì gbà wọ́n gbọ́. 12Nígbà náà ni Peteru dìde, ó súré lọ sí ibojì; nígbà tí ó sì bẹ̀rẹ̀, ó rí aṣọ àlà lọ́tọ̀ fúnrawọn, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀, ẹnu yà á sí ohun tí ó ṣe.

Ní ojú ọnà sí Emmausi

13Sì kíyèsi i, àwọn méjì nínú wọn ń lọ ní ọjọ́ náà sí ìletò kan tí a ń pè ní Emmausi, tí ó jìnnà sí Jerusalẹmu níwọ̀n ọgọ́ta ibùsọ̀. 14Wọ́n ń bá ara wọn sọ̀rọ̀ gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ó ṣẹlẹ̀. 15Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń bá ara wọn sọ̀rọ̀, tí wọ́n sì ń bá ara wọn jíròrò, Jesu tìkára rẹ̀ súnmọ́ wọn, ó sì ń bá wọn rìn lọ. 1624.16: Jh 20.14; 21.4.Ṣùgbọ́n a rú wọn lójú, kí wọn má le mọ̀ ọ́n.

17Ó sì bi wọ́n pé, “Ọ̀rọ̀ kín ni ẹ̀yin ń bá ara yín sọ, bí ẹ̀yin ti ń rìn?”

Wọ́n sì dúró jẹ́, wọ́n fajúro. 18Ọ̀kan nínú wọn, tí a ń pè ní Kileopa, sì dáhùn wí fún un pé, “Àlejò sá à ni ìwọ ní Jerusalẹmu, tí ìwọ kò sì mọ ohun tí ó ṣẹ̀ níbẹ̀ ní ọjọ́ wọ̀nyí?”

1924.19: Mt 21.11; Lk 7.16; 13.33; Ap 3.22.Ó sì bi wọ́n pé, “Kín ni?”

Wọ́n sì wí fún un pé, “Ní ti Jesu ti Nasareti, ẹni tí ó jẹ́ wòlíì, tí ó pọ̀ ní ìṣe àti ní ọrọ̀ níwájú Ọlọ́run àti gbogbo ènìyàn, 20Àti bí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn alàgbà wa ti fi òun lé wọn lọ́wọ́ láti dá a lẹ́bi ikú, àti bí wọ́n ti kàn án mọ́ àgbélébùú. 21Bẹ́ẹ̀ ni òun ni àwa ti ní ìrètí pé, òun ni ìbá dá Israẹli ní ìdè. Àti pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, òní ni ó di ọjọ́ kẹta tí nǹkan wọ̀nyí ti ṣẹlẹ̀. 22Àwọn obìnrin kan pẹ̀lú nínú ẹgbẹ́ wa, tí wọ́n lọ si ibojì ní kùtùkùtù, sì wá yà wá lẹ́nu: 23Nígbà tí wọn kò sì rí òkú rẹ̀, wọ́n wá wí pé, àwọn rí ìran àwọn angẹli tí wọ́n wí pé, ó wà láààyè. 2424.24: Jh 20.3-10.Àti àwọn kan tí wọ́n wà pẹ̀lú wa lọ sí ibojì, wọ́n sì rí i gẹ́gẹ́ bí àwọn obìnrin náà ti wí: ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ ni wọn kò rí.”

25Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin tí òye kò yé, tí ẹ sì yigbì ní àyà láti gba gbogbo èyí tí àwọn wòlíì ti wí gbọ́: 26Kò ha yẹ kí Kristi ó jìyà nǹkan wọ̀nyí kí ó sì wọ inú ògo rẹ̀ lọ.” 2724.27: Lk 24.44-45; Ap 28.23; 1Pt 1.11.Ó sì bẹ̀rẹ̀ láti Mose àti gbogbo àwọn wòlíì wá, ó sì túmọ̀ nǹkan fún wọn nínú ìwé mímọ́ gbogbo nípa ti ara rẹ̀.

2824.28: Mk 6.48.Wọ́n sì súnmọ́ ìletò tí wọ́n ń lọ: ó sì ṣe bí ẹni pé yóò lọ sí iwájú. 29Wọ́n sì rọ̀ ọ́, pé, “Bá wa dúró: nítorí ó di ọjọ́ alẹ́, ọjọ́ sì kọjá tán.” Ó sì wọlé lọ, ó bá wọn dúró.

3024.30: Lk 9.16; 22.19.Ó sì ṣe, bí ó ti bá wọn jókòó ti oúnjẹ, ó mú àkàrà, ó súre sí i, ó sì bù ú, ó sì fi fún wọn. 31Ojú wọn sì là, wọ́n sì mọ̀ ọ́n; ó sì nù mọ́ wọn ní ojú 32Wọ́n sì bá ara wọn sọ pé, “Ọkàn wa kò ha gbiná nínú wa, nígbà tí ó ń bá wa sọ̀rọ̀ tí ó sì ń túmọ̀ ìwé mímọ́ fún wa!”

33Wọ́n sì dìde ní wákàtí kan náà, wọ́n padà lọ sí Jerusalẹmu, wọ́n sì bá àwọn mọ́kànlá péjọ, àti àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ wọn, 3424.34: 1Kọ 15.5.Wọn si wí pé, “Olúwa jíǹde nítòótọ́, ó sì ti fi ara hàn fún Simoni!” 35Àwọn náà sì ròyìn nǹkan tí ó ṣe ní ọ̀nà, àti bí ó ti di mí mọ̀ fún wọn ní bíbu àkàrà.

Jesu fi ara han àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀

3624.36-43: Jh 20.19-20,27; Jh 21.5,9-13; 1Kọ 15.5; Ap 10.40-41.Bí wọ́n sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí Jesu tìkára rẹ̀ dúró láàrín wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín.”

37Ṣùgbọ́n àyà fò wọ́n, wọ́n sì wárìrì, wọ́n ṣe bí àwọn rí ẹ̀mí kan. 38Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ara yín kò lélẹ̀? Èé sì ti ṣe tí èròkerò fi ń sọ nínú ọkàn yín? 3924.39: 1Jh 1.1.Ẹ wo ọwọ́ mi àti ẹsẹ̀ mi, pé èmi tìkára mi ni! Ẹ dì mímú kí ẹ wò ó nítorí tí iwin kò ní ẹran àti egungun lára, bí ẹ̀yin ti rí tí èmi ní.”

40Nígbà tí ó sì wí bẹ́ẹ̀ tan, ó fi ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ hàn wọ́n. 41Nígbà tí wọn kò sì tí ì gbàgbọ́ fún ayọ̀, àti fún ìyanu, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ní ohunkóhun jíjẹ níhìn-ín yìí?” 42Wọ́n sì fún un ní ẹja tí a fi oyin sè. 43Ó sì gbà á, ó jẹ ẹ́ lójú wọn.

4424.44: Lk 24.26-27; Ap 28.23.Ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ tí mo sọ fún yín, nígbà tí èmí ti wà pẹ̀lú yín pé: A ní láti mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ nínú òfin Mose, àti nínú ìwé àwọn wòlíì, àti nínú Saamu, nípasẹ̀ mi.”

45Nígbà náà ni ó ṣí wọn ní iyè, kí ìwé mímọ́ lè yé wọn. 4624.46: Ho 6.2; 1Kọ 15.3-4.Ó sì wí fún wọn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni a ti kọ̀wé rẹ̀, pé: Kí Kristi jìyà, àti kí ó sì jíǹde ní ọjọ́ kẹta kúrò nínú òkú: 4724.47: Ap 1.4-8; Mt 28.19.Àti pé kí a wàásù ìrònúpìwàdà àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ lórúkọ rẹ̀, ní orílẹ̀-èdè gbogbo, bẹ̀rẹ̀ láti Jerusalẹmu lọ. 48Ẹ̀yin sì ni ẹlẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí. 4924.49: Ap 2.1-4; Jh 14.26; 20.21-23.Èmi yóò rán ohun tí Baba mi ṣe ìlérí sí yín: ṣùgbọ́n ẹ jókòó ní ìlú Jerusalẹmu, títí a ó fífi agbára wọ̀ yín, láti òkè ọ̀run wá.”

Ìgòkè re ọ̀run

50Ó sì mú wọn jáde lọ títí wọ́n fẹ́rẹ̀ dé Betani, nígbà tí ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè, ó súre fún wọn. 5124.51: Ap 1.9-11.Ó sì ṣe, bí ó ti ń súre fún wọn, ó yà kúrò lọ́dọ̀ wọn, a sì gbé e lọ sí ọ̀run. 5224.52-53: Ap 1.12-14.Wọ́n sì foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì padà lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú ayọ̀ púpọ̀: 53Wọ́n sì wà ní tẹmpili nígbà gbogbo, wọ́n ń fi ìyìn, àti ìbùkún fún Ọlọ́run.

Słowo Życia

Łukasza 24:1-53

Zmartwychwstanie

1Dopiero w niedzielę, wczesnym ranem, zaniosły do grobu przygotowane olejki. 2Zobaczyły, że głaz zamykający wejście jest odsunięty. 3Weszły więc do wnętrza, ale nie znalazły ciała Jezusa. 4Stały oszołomione, gdy nagle obok nich zjawili się dwaj mężczyźni, ubrani w lśniące szaty. 5Przerażone, pokłoniły się im nisko. Oni zaś zapytali:

—Dlaczego szukacie w grobie Tego, który żyje? 6Nie ma Go tutaj. Powstał z martwych! Przypomnijcie sobie, jak wam mówił, będąc jeszcze w Galilei, 7że Syn Człowieczy zostanie wydany w ręce grzesznych ludzi i zabity przez nich, ale trzeciego dnia zmartwychwstanie.

8Wtedy przypomniały sobie te słowa. 9Wróciły do Jerozolimy i opowiedziały o wszystkim jedenastu apostołom i pozostałym uczniom. 10A były to: Maria z Magdali, Joanna, Maria (matka Jakuba) oraz kilka innych kobiet. 11Słuchający sądzili jednak, że to jakaś zmyślona historia, i nie uwierzyli im. 12Mimo to, Piotr pobiegł jednak do grobowca. Zajrzał do środka i zobaczył same płótna. Wrócił więc do domu, zdziwiony tym, co zaszło.

W drodze do Emaus

13Jeszcze tego samego dnia dwaj uczniowie Jezusa szli do wioski Emaus, odległej o jedenaście kilometrów od Jerozolimy, 14i rozmawiali o ostatnich wydarzeniach. 15Gdy tak żywo dyskutowali, sam Jezus podszedł i przyłączył się do nich. 16Oni jednak nie rozpoznali Go.

17—O czym rozmawiacie?—zapytał.

Wtedy ze smutku przystanęli 18i jeden z nich, Kleofas, powiedział:

—Jesteś chyba jedyną osobą w całej Jerozolimie, która nie słyszała o wydarzeniach z ostatnich kilku dni.

19—A o czym nie wiem?—zapytał Jezus.

—O tym, co się stało z Jezusem z Nazaretu—odrzekli. —Był On prorokiem, potężnym w czynie i słowie, cieszącym się uznaniem Boga i ludzi. 20Nasi najwyżsi kapłani i przywódcy religijni wydali Go jednak Rzymianom, którzy skazali Go na śmierć i ukrzyżowali. 21A my mieliśmy nadzieję, że to właśnie On jest Mesjaszem, mającym wyzwolić Izrael. Dziś mija już trzeci dzień od tych wydarzeń. 22Na dodatek kilka kobiet wprawiło nas w osłupienie. Powiedziały, że były o świcie przy grobowcu, 23ale nie znalazły Jego ciała. Ponadto widziały tam aniołów twierdzących, że Jezus żyje. 24Niektórzy z nas pobiegli tam zaraz i zastali wszystko tak, jak powiedziały kobiety: ciała rzeczywiście nie było.

25Wtedy Jezus rzekł im:

—Jacy jesteście niemądrzy! Tak trudno uwierzyć wam w to, co prorocy powiedzieli w Piśmie! 26Przecież Mesjasz miał to wszystko wycierpieć, zanim zostanie otoczony chwałą!

27I zaczynając od pism Mojżesza i proroków, wyjaśniał im wszystkie fragmenty Pisma, które mówiły o Nim jako Mesjaszu. 28Gdy doszli do Emaus, Jezus dał do zrozumienia, że idzie dalej. 29Oni jednak nalegali:

—Zostań z nami na noc. Jest już późno i robi się ciemno.

Wszedł więc z nimi do domu. 30A gdy zasiedli do kolacji, wziął chleb, podziękował za niego Bogu, połamał go na kawałki i podał im. 31Wtedy przejrzeli na oczy i rozpoznali Go, ale On zniknął. 32Zaczęli więc mówić jeden do drugiego:

—Czy serce nie biło nam mocniej, gdy podczas drogi rozmawiał z nami i wyjaśniał Pismo?

33Jeszcze tej samej godziny wyruszyli z powrotem do Jerozolimy. Tam spotkali zebranych jedenastu apostołów i pozostałych uczniów, 34którzy potwierdzili, że Jezus rzeczywiście zmartwychwstał i że ukazał się Piotrowi. 35Wówczas ci dwaj opowiedzieli im o swoim spotkaniu z Jezusem i o tym, jak rozpoznali Go podczas łamania chleba.

Jezus ukazuje się uczniom

36Gdy jeszcze mówili, sam Jezus nagle stanął pośród nich i powiedział:

—Pokój wam!

37Wszyscy się bardzo przestraszyli, sądząc, że widzą ducha.

38—Czemu jesteście tacy przerażeni?—zapytał. —Dlaczego wątpicie, że to jestem Ja? 39Zobaczcie rany na moich rękach i nogach! Przecież to Ja, we własnej osobie! Dotknijcie Mnie, a przekonacie się, że nie jestem duchem. Duch przecież nie ma ciała ani kości, a Ja mam!

40Mówiąc to, pokazał im swoje ręce i nogi. 41Uczniowie byli tak szczęśliwi i zdziwieni, że aż nie mogli uwierzyć w to, co widzieli. Wtedy Jezus zapytał ich:

—Czy macie tu coś do jedzenia?

42Podali Mu więc kawałek pieczonej ryby, 43a On zjadł ją na ich oczach. 44Następnie powiedział do uczniów:

—Gdy jeszcze przed ukrzyżowaniem byłem z wami, mówiłem, że musi się spełnić to, co jest o Mnie napisane w Prawie Mojżesza, pismach proroków i w Psalmach.

45Wtedy rozjaśnił ich umysły, by to wszystko zrozumieli. 46I dodał:

—Napisane jest, że Mesjasz będzie cierpiał, że umrze i trzeciego dnia powstanie z martwych. 47Wszystkie narody, począwszy od Jerozolimy, będą w Jego imieniu wzywane do opamiętania i przyjęcia odpuszczenia grzechów. 48Wy jesteście świadkami spełnienia się tych proroctw. 49Już niedługo ześlę wam to, co obiecał mój Ojciec. Na razie pozostańcie tu, w mieście, aż napełni was moc z nieba.

Wniebowstąpienie

50Potem wyprowadził uczniów z miasta w stronę Betanii. Wzniósł ręce i pobłogosławił ich. 51Czyniąc to, zaczął unosić się w górę i tak odszedł do nieba. 52Oni zaś oddali Mu pokłon i pełni radości powrócili do Jerozolimy, 53gdzie przez cały czas przebywali w świątyni i wielbili Boga.