Jobu 5 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 5:1-27

Ìjìyà jẹ́ èso àìṣòdodo

1“Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn?

Tàbí ta ni nínú àwọn ènìyàn mímọ́ tí ìwọ ó yípadà sí?

2Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye,

ìrunú a sì pa òpè ènìyàn.

3Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀,

ṣùgbọ́n lójúkan náà mo fi ibùjókòó rẹ̀ bú.

4Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu,

a sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lójú ibodè,

bẹ́ẹ̀ ni kò sí aláàbò kan.

5Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ,

tí wọ́n sì wọ inú ẹ̀gún lọ kó,

àwọn ìgárá ọlọ́ṣà sì gbé ohun ìní wọn mì.

6Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni,

tí ìyọnu kò ti ilẹ̀ jáde wá.

7Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà,

gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.

8“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀,

ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi yóò máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.

9Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí,

ohun ìyanu láìní iye.

10Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé

tí ó sì ń rán omi sínú ilẹ̀kílẹ̀.

11Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè

kí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.

125.12-13: 1Kọ 3.19.Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po,

bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdáwọ́lé wọn ṣẹ.

13Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn,

àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tì ṣubú ní ògèdèǹgbé.

14Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán;

wọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru ni.

15Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà,

lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.

16Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà,

àìṣòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.

17“Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí,

nítorí náà, má ṣe gan ìbáwí Olódùmarè.

18Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura,

ó sá lọ́gbẹ́, a sì fi ọwọ́ rẹ̀ di ojú ọgbẹ̀ náà jiná.

19Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà,

àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ

20Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú

àti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.

21A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n,

bẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.

22Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn,

bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.

23Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀,

àwọn ẹranko igbó yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.

24Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà,

ìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò ṣìnà.

25Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀

àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko igbó.

26Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́,

bí síírí ọkà tí ó gbó tí á sì kó ní ìgbà ìkórè rẹ̀.

27“Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí!

Gbà á gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ìre ara rẹ ni.”

Akuapem Twi Contemporary Bible

Hiob 5:1-27

1“Wobɛfrɛ a frɛ, na hena na obegye wo so?

Akronkronfo no mu hena nkyɛn na wobɛkɔ?

2Ahisɛm kum ɔkwasea,

na anibere kum atetekwaa.

3Mʼankasa mahu ɔkwasea a ɔrefefɛw,

nanso mpofirim, wɔdomee ne fi.

4Ne mma ne bammɔ ntam kwan ware,

wɔdwerɛw wɔn wɔ asennii a wonni ɔkamafo.

5Nea ɔkɔm de no no di ne nnɔbae,

na ɔfa fi nsɔe mu mpo,

na nea osukɔm de no no pere di nʼahode akyi.

6Ahokyere mpue mmfi dɔte mu

na ɔhaw nso mfifi mmfi fam.

7Nanso wɔwo nnipa to ɔhaw mu

mpɛn dodow a gyaframa turuw kɔ soro no.

8“Nanso sɛ ɛyɛ me a, anka meguan atoa Onyankopɔn;

na mede mʼasɛm ato nʼanim.

9Ɔyɛ anwonwade a wontumi nhwehwɛ mu,

ne nsɛnkyerɛnne a wontumi nkan ne dodow.

10Ɔtɔ osu gu asase so;

na ɔde kɔ wuram.

11Ɔde ahobrɛasefo si nea ɛkorɔn,

na ɔma wɔn a wodi awerɛhow nya asomdwoe.

12Ɔsɛe aniferefo nhyehyɛe,

ma wɔn nsa si fam.

13Ɔkyere anyansafo wɔ wɔn anifere mu,

na ɔbɔ anitewfo nhyehyɛe gu.

14Sum duru wɔn awia ketee;

na wɔkeka wɔ owigyinae mu te sɛ anadwo.

15Ogye ahiafo fi afoa a ɛhyɛ wɔn anom;

ogye wɔn fi ahoɔdenfo nkyehama mu.

16Enti ahiafo wɔ anidaso,

na ntɛnkyew ka nʼano to mu.

17“Nhyira ne onipa a Onyankopɔn teɛ no,

enti mmu Otumfo nteɛteɛ no animtiaa.

18Efisɛ ɔno na opira na ɔno ara akyekyere;

opira nanso ne nsa sa yare.

19Obegye wo afi ɔhaw ahorow asia mu;

ason so no, bɔne biara renka wo.

20Ɔkɔm ba a, obegye wo afi owu mu,

na ɔko mu nso, obegye wo afi afoa ano.

21Wɔbɛbɔ wo ho ban afi ntwirii ho

na sɛ ɔsɛe ba a ɛnsɛ sɛ wusuro.

22Wobɛserew ɔsɛe ne ɔkɔm;

na ɛnsɛ sɛ wusuro asase so mmoa.

23Wo ne afuw so abo bɛyɛ apam,

na emu nkekaboa nso ne wo bɛtena asomdwoe mu.

24Wubehu sɛ wo ntamadan wɔ bammɔ;

na sɛ wosese wʼahode a wubehu sɛ hwee nyeraa ɛ.

25Wubehu sɛ wo mma bɛyɛ bebree;

na wʼase bɛfɛe sɛ asase so sare.

26Wode ahoɔden bɛkɔ ɔda mu,

te sɛ afiafi a wɔaboa ano wɔ otwabere mu.

27“Yɛahwehwɛ eyi mu, na ɛyɛ nokware

ɛno nti tie na fa toto wʼabrabɔ ho.”