Jobu 4 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 4:1-21

Ọ̀rọ̀ Elifasi: Ọlọ́run kì í fi ìyà jẹ olódodo

1Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé:

2“Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́?

Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?

3Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn,

ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.

4Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró,

ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.

5Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́;

ara rẹ kò lélẹ̀.

6Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ

àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?

7“Èmi bẹ̀ ọ́ rántí: Ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀?

Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?

8Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀,

tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.

9Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé,

nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.

10Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún

àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.

11Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ,

àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.

12“Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi,

etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.

13Ní ìrò inú lójú ìran òru,

nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.

14Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì

tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.

15Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi,

irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.

16Ó dúró jẹ́ẹ́,

ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀,

àwòrán kan hàn níwájú mi,

ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé:

17‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run,

ènìyàn ha le mọ́ ju Ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?

18Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,

nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.

19Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀,

ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀

tí yóò di rírun kòkòrò.

20A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́

wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.

21A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí?

Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’

Akuapem Twi Contemporary Bible

Hiob 4:1-21

Elifas Mmuae A Edi Kan

1Na Temanni Elifas buaa Hiob se,

2“Sɛ obi pɛ sɛ ɔne wo kasa a, worennya ntoboase ana?

Hena na wobetumi aka nʼano ato mu?

3Dwene sɛnea wakyerɛkyerɛ nnipa bebree,

sɛnea woahyɛ nsa a emu ayɛ mmerɛw no den.

4Wo nsɛm ahyɛ wɔn a wɔahintiw no den;

woahyɛ nkotodwe a ayɛ mmerɛw mu den.

5Na afei a ɔhaw aba no, wʼaba mu abu;

adwira wo, na wo werɛ ahow.

6So ɛnsɛ sɛ wo nyamesuro yɛ wʼahotoso

na wʼakwan a ɛho nni asɛm no yɛ wʼanidaso ana?

7“Dwene ho: Wɔasɛe obi a ne ho nni asɛm pɛn ana?

Ɛhefa na wɔsɛee obi a ɔyɛ pɛ?

8Sɛnea mahu no, wɔn a wofuntum bɔne

ne wɔn a wodua ɔhaw no twa so aba.

9Onyankopɔn home ano, wɔsɛe;

nʼabufuw turuw a wɔyera.

10Gyata betumi abobɔ mu na wɔaworo so,

nanso wɔabubu gyata akɛse no se.

11Gyata annya hanam a owu,

na gyatabere mma no bɔ hwete.

12“Wɔbɛkaa kokoamsɛm bi kyerɛɛ me

na mʼaso tee no sɛ asomsɛm.

13Wɔ anadwo daeso basabasa mu,

bere a nnipa adeda nnahɔɔ no,

14ehu ne nketenkete kyeree me

ɛmaa me nnompe nyinaa wosowee.

15Honhom bi twaa mʼani so,

na me ho nwi sɔre gyinae.

16Egyinae,

nanso, manhu nʼabɔsu.

Biribi begyinaa mʼanim,

na metee nne bɔkɔɔ bi a ɛrebisa se,

17‘Onipa desani betumi ateɛ asen Onyankopɔn?

Na mpo ɔhoɔdenfo betumi ayɛ kronkron asen ne Yɛfo ana?

18Sɛ Onyankopɔn ntumi mfa ne ho nto nʼankasa asomfo so,

sɛ ɔka nʼabɔfo mfomso kyerɛ wɔn a,

19na nkantom wɔn a wɔtete dɔte afi mu,

wɔn a wɔn fapem sisi mfutuma mu

na wɔdwerɛw wɔn ntɛm so sen abubummaba!

20Efi anɔpahema kosi anwummere wobubu wɔn mu nketenkete;

na wɔyera korakora a obiara nhu wɔn bio.

21So wommiamia wɔn ntamadan ahama mu,

a ɛno nti wowuwu a wonni nyansa ana?’