Jobu 41 – YCB & CCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 41:1-34

Ọlọ́run ń tẹ̀síwájú láti pe Jobu níjà

1“Ǹjẹ́ ìwọ le è fi ìwọ̀ fa Lefitani jáde?

Tàbí ìwọ lè fi okùn so ahọ́n rẹ̀ mọ́lẹ̀?

2Ìwọ lè fi okùn bọ̀ ọ́ ní í mú,

tàbí fi ìwọ̀ ẹ̀gún gun ní ẹ̀rẹ̀kẹ́?

3Òun ha jẹ́ bẹ ẹ̀bẹ̀ fún àánú lọ́dọ̀

rẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ bí òun ha bá ọ sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́?

4Òun ha bá ọ dá májẹ̀mú bí?

Ìwọ ó ha máa mú ṣe ẹrú láéláé bí?

5Ìwọ ha lè ba sáré bí ẹni pé ẹyẹ ni,

tàbí ìwọ ó dè é fún àwọn ọmọbìnrin ìránṣẹ́ rẹ̀?

6Ẹgbẹ́ àwọn apẹja yóò ha máa tà á bí?

Wọn ó ha pín láàrín àwọn oníṣòwò?

7Ìwọ ha lè fi ọ̀kọ̀-irin gun awọ rẹ̀,

tàbí orí rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ìpẹja.

8Fi ọwọ́ rẹ lé e lára,

ìwọ ó rántí ìjà náà, ìwọ kì yóò sì ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.

9Kíyèsi, ìgbìyànjú láti mú un ní asán;

ní kìkì ìrí rẹ̀ ara kì yóò ha rọ̀ ọ́ wẹ̀sì?

10Kò sí ẹni aláyà lílé tí ó lè ru sókè;

Ǹjẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú mi.

11Ta ni ó kọ́kọ́ ṣe fún mi, tí èmi ìbá fi san án fún un?

Ohunkóhun ti ń bẹ lábẹ́ ọ̀run gbogbo, tèmi ni.

12“Èmi kì yóò fi ẹ̀yà ara Lefitani,

tàbí ipá rẹ, tàbí ìhámọ́ra rẹ tí ó ní ẹwà pamọ́.

13Ta ni yóò lè rídìí aṣọ àpáta rẹ̀?

Tàbí ta ni ó lè súnmọ́ ọ̀nà méjì eyín rẹ̀?

14Ta ni ó lè ṣí ìlẹ̀kùn iwájú rẹ̀?

Àyíká ẹ̀yin rẹ ni ìbẹ̀rù ńlá.

15Ìpẹ́ lílé ní ìgbéraga rẹ̀;

ó pàdé pọ̀ tímọ́tímọ́ bí ààmì èdìdì.

16Èkínní fi ara mọ́ èkejì tó bẹ́ẹ̀

tí afẹ́fẹ́ kò lè wọ àárín wọn.

17Èkínní fi ara mọ́ èkejì rẹ̀;

wọ́n lè wọ́n pọ̀ tí a kò lè mọ̀ wọ́n.

18Nípa sí sin rẹ̀ ìmọ́lẹ̀ á mọ́,

ojú rẹ̀ a sì dàbí ìpéǹpéjú òwúrọ̀.

19Láti ẹnu rẹ ni ọ̀wọ́-iná ti jáde wá,

ìpẹ́pẹ́ iná a sì ta jáde.

20Láti ihò imú rẹ ni èéfín ti jáde wá,

bí ẹni pé láti inú ìkòkò tí a fẹ́ iná ìfèéfèé lábẹ́ rẹ̀.

21Èémí rẹ̀ tiná bọ ẹ̀yin iná,

ọ̀wọ́-iná sì ti ẹnu rẹ̀ jáde.

22Ní ọrùn rẹ̀ ní agbára kù sí,

àti ìbànújẹ́ àyà sì padà di ayọ̀ níwájú rẹ̀.

23Jabajaba ẹran rẹ̀ dìjọ pọ̀,

wọ́n múra gírí fún ara wọn, a kò lè sí wọn ní ipò.

24Àyà rẹ̀ dúró gbagidi bí òkúta,

àní, ó le bi ìyá ọlọ.

25Nígbà tí ó bá gbé ara rẹ̀ sókè, àwọn alágbára bẹ̀rù;

nítorí ìbẹ̀rù ńlá, wọ́n dààmú.

26Ọ̀kọ̀ tàbí idà, tàbí ọfà,

ẹni tí ó ṣá a kò lè rán an.

27Ó ká irin sí ibi koríko gbígbẹ

àti idẹ si bi igi híhù.

28Ọfà kò lè mú un sá;

òkúta kànnakánná lọ́dọ̀ rẹ̀ dàbí àgékù koríko.

29Ó ka ẹṣin sí bí àgékù ìdì koríko;

ó rẹ́rìn-ín sí mímì ọ̀kọ̀.

30Òkúta mímú ń bẹ nísàlẹ̀ abẹ́ rẹ̀,

ó sì tẹ́ ohun mímú ṣóńṣó sórí ẹrẹ̀.

31Ó mú ibú omi hó bí ìkòkò;

ó sọ̀ agbami Òkun dàbí kólòbó ìkunra.

32Ó mú ipa ọ̀nà tan lẹ́yìn rẹ̀;

ènìyàn a máa ka ibú sí ewú arúgbó.

33Lórí ilẹ̀ ayé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀,

tí a dá láìní ìbẹ̀rù.

34Ó bojú wo ohun gíga gbogbo,

ó sì nìkan jásí ọba lórí gbogbo àwọn ọmọ ìgbéraga.”

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

约伯记 41:1-34

1“你岂能用鱼钩钓鳄鱼,

用绳索绑住它的舌头?

2你岂能用绳子穿它的鼻子,

用钩子穿它的腮骨?

3它岂会向你连连求饶,

对你说柔和的话?

4它岂肯与你立约,

一生做你的奴隶?

5你岂能拿它当小鸟玩耍,

或拴起来给幼女取乐?

6渔夫们岂能把它当货物出售,

卖给商人?

7你岂能在它皮上戳满长矛,

头上插满鱼叉?

8你动手碰碰它,

就知道有何恶战,绝不会再碰。

9企图捕捉它的都会失望,

人看到它就会心惊胆战。

10再凶猛的人也不敢惹它。

这样,谁能在我面前站立得住?

11谁给过我什么,要我偿还?

天下万物都是我的。

12“论到它的四肢、大力和姣美的身体,

我不能缄默不言。

13谁能剥去它的外皮?

谁能给它戴上辔头?

14谁能打开它的口?

它的牙齿令人恐惧。

15它的脊背覆着行行鳞甲,

牢牢地密封在一起,

16紧密无间,

连气也透不进去。

17鳞甲彼此相连相扣,

无法分开。

18它打喷嚏时,水光四射;

它的眼睛发出晨光;

19口中喷出火炬,

迸出火星;

20鼻孔冒烟,

如沸腾的锅和燃烧的芦苇;

21呼气可点燃煤炭,

口中喷出火焰;

22颈项强而有力,

恐惧在它前面开路;

23身上的皱褶紧密相连,

牢牢地密封在一起;

24心坚如石,

硬如磨石。

25它一站起来,勇士都害怕,

见它冲来,他们慌忙退缩。

26刀剑挡不住它,

长矛、标枪、尖戟也无能为力。

27它视铁如干草,

视铜如朽木。

28利箭吓不跑它,

弹石在它看来只是碎秸;

29棍棒无异于秸秆,

它嗤笑投来的标枪。

30它腹部有锋利的瓦片,

在淤泥上留下道道耙痕。

31它使深渊如锅翻腾,

大海如油锅滚动。

32它游过后留下一道波光,

使深渊仿佛披上银发。

33地上没有动物能与它相比,

像它那样无所畏惧。

34它藐视群雄,

在高傲的百兽中称王。”