Jobu 16 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 16:1-22

Ìdáhùn Jobu fún Elifasi

1Ìgbà náà ní Jobu dáhùn, ó sì wí pé:

2“Èmi ti gbọ́ irú ohun púpọ̀ bẹ́ẹ̀ rí

ayọnilẹ́nu onítùnú ènìyàn ní gbogbo yín.

3Ọ̀rọ̀ asán lè ni òpin?

Tàbí kí ni ó gbó ọ láyà tí ìwọ fi dáhùn?

4Èmi pẹ̀lú le sọ bí ẹ̀yin;

bí ọkàn yín bá wà ní ipò ọkàn mi,

èmi le sọ ọ̀rọ̀ dáradára púpọ̀ sí yín ní ọrùn,

èmi a sì mi orí mi sí i yín.

5Èmi ìbá fi ọ̀rọ̀ ẹnu mi gbà yín ni

ìyànjú, àti ṣíṣí ètè mi ìbá sì tu ìbìnújẹ́ yín.

6“Bí èmi tilẹ̀ sọ̀rọ̀, ìbìnújẹ́ mi kò lọ;

bí mo sì tilẹ̀ dákẹ́, níbo ni ìtùnú mí ko kúrò?

7Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó dá mi lágara;

Ìwọ Ọlọ́run mú gbogbo ẹgbẹ́ mi takété.

8Ìwọ fi ìhunjọ kùn mí lára, èyí tí o jẹ́rìí tì mí;

àti rírù tí ó hàn lára mi, ó jẹ́rìí tì mí ní ojú.

9Ọlọ́run fi i ìbínú rẹ̀ fà mí ya, ó sì gbóguntì mí;

ó pa eyín rẹ̀ keke sí mi,

ọ̀tá mi sì gbójú rẹ̀ sí mi.

10Wọ́n ti fi ẹnu wọn yẹ̀yẹ́ mi;

Wọ́n gbá mi ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ ni ìgbá ẹ̀gàn;

Wọ́n kó ara wọn pọ̀ sí mi.

11Ọlọ́run ti fi mí lé ọwọ́ ẹni

búburú, ó sì mú mi ṣubú sí ọwọ́ ènìyàn ìkà.

12Mo ti jókòó jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n ó fà mí já;

ó sì dì mí ni ọrùn mú, ó sì gbọ̀n mí túútúú,

ó sì gbé mi kalẹ̀ láti ṣe ààmì ìtafàsí rẹ̀;

13àwọn tafàtafà rẹ̀ dúró yí mi káàkiri.

Ó là mí láyà pẹ̀rẹ̀, kò si dá sí,

ó sì tú òróòro ara mi dà sílẹ̀.

14Ìbàjẹ́ lórí ìbàjẹ́ ní ó fi bà mí jẹ́;

ó súré kọlù mi bí jagunjagun.

15“Mo rán aṣọ ọ̀fọ̀ bò ara mi,

mo sì rẹ̀ ìwo mi sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.

16Ojú mi ti pọ́n fún ẹkún,

òjìji ikú sì ṣẹ́ sí ìpéǹpéjú mi.

17Kì í ṣe nítorí àìṣòótọ́ kan ní ọwọ́

mi; àdúrà mi sì mọ́ pẹ̀lú.

18“Háà! Ilẹ̀ ayé, ìwọ má ṣe bò ẹ̀jẹ̀ mi,

kí ẹkún mi má ṣe wà ní ipò kan.

19Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi i, ẹlẹ́rìí mi ń bẹ ní ọ̀run,

ẹ̀rí mi sì ń bẹ lókè ọ̀run.

20Àwọn ọ̀rẹ́ mi ń fi mí ṣẹ̀sín,

ṣùgbọ́n ojú mi ń da omijé sọ́dọ̀ Ọlọ́run;

21Ìbá ṣe pé ẹnìkan le è máa ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì lọ́dọ̀ Ọlọ́run,

bí ènìyàn kan ti í ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì rẹ̀.

22“Nítorí nígbà tí iye ọdún díẹ̀ rékọjá tán,

nígbà náà ni èmi ó lọ sí ibi tí èmi kì yóò padà bọ̀.

New International Version

Job 16:1-22

Job

1Then Job replied:

2“I have heard many things like these;

you are miserable comforters, all of you!

3Will your long-winded speeches never end?

What ails you that you keep on arguing?

4I also could speak like you,

if you were in my place;

I could make fine speeches against you

and shake my head at you.

5But my mouth would encourage you;

comfort from my lips would bring you relief.

6“Yet if I speak, my pain is not relieved;

and if I refrain, it does not go away.

7Surely, God, you have worn me out;

you have devastated my entire household.

8You have shriveled me up—and it has become a witness;

my gauntness rises up and testifies against me.

9God assails me and tears me in his anger

and gnashes his teeth at me;

my opponent fastens on me his piercing eyes.

10People open their mouths to jeer at me;

they strike my cheek in scorn

and unite together against me.

11God has turned me over to the ungodly

and thrown me into the clutches of the wicked.

12All was well with me, but he shattered me;

he seized me by the neck and crushed me.

He has made me his target;

13his archers surround me.

Without pity, he pierces my kidneys

and spills my gall on the ground.

14Again and again he bursts upon me;

he rushes at me like a warrior.

15“I have sewed sackcloth over my skin

and buried my brow in the dust.

16My face is red with weeping,

dark shadows ring my eyes;

17yet my hands have been free of violence

and my prayer is pure.

18“Earth, do not cover my blood;

may my cry never be laid to rest!

19Even now my witness is in heaven;

my advocate is on high.

20My intercessor is my friend16:20 Or My friends treat me with scorn

as my eyes pour out tears to God;

21on behalf of a man he pleads with God

as one pleads for a friend.

22“Only a few years will pass

before I take the path of no return.